መዝሙር 119 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

መዝሙር 119:1-176

መዝሙር 119119 የዚህ መዝሙር የግጥም ስንኞች መነሻ ወይም መነሻና መድረሻ ሆህያት ቍልቍል ሲነበቡ ትርጕም ዐዘል ናቸው። እያንዳንዱ ስንኝ ተመሳሳይ በሆነ በዕብራይስጥ ፊደል ይጀምራል።

ውዳሴ ለሕገ እግዚአብሔር

א አሌፍ

1መንገዳቸው ነቀፋ የሌለበት፣

በእግዚአብሔርም ሕግ የሚሄዱ የተባረኩ ናቸው።

2ምስክርነቱን የሚጠብቁ፣

በፍጹምም ልብ የሚሹት የተባረኩ ናቸው፤

3ዐመፅን አያደርጉም፤

ነገር ግን በመንገዱ ይሄዳሉ።

4ጠንቅቀን እንጠብቃት ዘንድ፣

አንተ ሥርዐትን አዝዘሃል።

5ሥርዐትህን እጠብቅ ዘንድ፣

ምነው መንገዴ ጽኑ በሆነልኝ ኖሮ!

6ወደ ትእዛዞችህ ስመለከት፣

በዚያን ጊዜ አላፍርም።

7የጽድቅ ፍርድህን ስማር፣

በቅን ልብ ምስጋና አቀርብልሃለሁ።

8ሥርዐትህን እጠብቃለሁ፤

ፈጽመህ አትተወኝ።

ב ቤት

9ጕልማሳ መንገዱን እንዴት ያነጻል?

በቃልህ መሠረት በመኖር ነው።

10በሙሉ ልቤ ፈለግሁህ፤

ከትእዛዞችህ ፈቀቅ እንዳልል አድርገኝ።

11አንተን እንዳልበድል፣

ቃልህን በልቤ ሰወርሁ።

12እግዚአብሔር ሆይ፤ አንተ ቡሩክ ነህ፤

ሥርዐትህን አስተምረኝ።

13ከአንደበትህ የሚወጣውን ደንብ ሁሉ፣

በከንፈሬ እናገራለሁ።

14ሰው በሀብቱ ብዛት ደስ እንደሚለው፣

ምስክርነትህን በመከተል ደስ ይለኛል።

15ድንጋጌህን አሰላስላለሁ፤

ልቤን በመንገድህ ላይ ጥያለሁ።

16በሥርዐትህ ደስ ይለኛል፤

ቃልህንም አልዘነጋም።

ג ጊሜል

17ሕያው እንድሆን፣ ቃልህንም እንድጠብቅ፣

ለአገልጋይህ መልካም አድርግ።

18ከሕግህ ድንቅ ነገርን እንዳይ፣

ዐይኖቼን ክፈት።

19እኔ በምድር ላይ መጻተኛ ነኝ፤

ትእዛዞችህን ከእኔ አትሰውር።

20ዘወትር ደንብህን በመናፈቅ፣

ነፍሴ እጅግ ዛለች።

21ከትእዛዞችህ የሳቱትን፣

እብሪተኞችንና ርጉሞችን ትገሥጻለህ።

22ምስክርነትህን ጠብቄአለሁና፣

ስድብንና ንቀትን ከእኔ አርቅ።

23ገዦች ተቀምጠው ቢዶልቱብኝ እንኳ፣

አገልጋይህ ሥርዐትህን ያሰላስላል።

24ምስክርነትህ ለእኔ ደስታዬ ነው፤

መካሪዬም ነው።

ד ዳሌት

25ነፍሴ ከዐፈር ተጣበቀች፤

እንደ ቃልህ መልሰህ ሕያው አድርገኝ።

26ስለ መንገዴ ገልጬ ነገርሁህ፤ አንተም መለስህልኝ፤

ሥርዐትህን አስተምረኝ።

27የድንጋጌህን መንገድ እንዳስተውል አድርገኝ፤

እኔም ድንቅ ሥራህን አሰላስላለሁ።

28ነፍሴ በሐዘን ተዝለፈለፈች፤

እንደ ቃልህ አበርታኝ።

29የሽንገላን መንገድ ከእኔ አርቅ፤

ሕግህን በጸጋህ ስጠኝ።

30የእውነትን መንገድ መርጫለሁ፤

ሕግህንም ፊት ለፊቴ አድርጌአለሁ።

31እግዚአብሔር ሆይ፤ ከምስክርነትህ ጋር ተጣብቄአለሁ፤

አሳልፈህ ለውርደት አትስጠኝ።

32ልቤን አስፍተህልኛልና፣

በትእዛዞችህ መንገድ እሮጣለሁ።

ה ሄ

33እግዚአብሔር ሆይ፤ የሥርዐትህን መንገድ አስተምረኝ፤

እኔም እስከ መጨረሻው እጠብቀዋለሁ።

34ሕግህን እንድጠብቅ፣ በፍጹም ልቤም እንድታዘዘው፣ ማስተዋልን ስጠኝ።

35በእርሷ ደስ ይለኛልና፣

በትእዛዝህ መንገድ ምራኝ።

36ከራስ ጥቅም ይልቅ፣

ልቤን ወደ ምስክርነትህ አዘንብል።

37ከንቱ ነገር ከማየት ዐይኖቼን መልስ፤

በራስህ መንገድ119፥37 አንዳንድ ትርጕሞች እንደ ቃልህ ይላሉ። እንደ ገና ሕያው አድርገኝ።

38ትፈራ ዘንድ፣

ለአገልጋይህ የገባኸውን ቃል ፈጽም።

39የምፈራውን መዋረድ ከእኔ አርቅ፤

ደንብህ መልካም ነውና።

40እነሆ፤ ድንጋጌህን ናፈቅሁ፤

በጽድቅህ ሕያው አድርገኝ።

ו ዋው

41እግዚአብሔር ሆይ፤ ምሕረትህ ወደ እኔ ይምጣ፤

ማዳንህም እንደ ቃልህ ይላክልኝ።

42በቃልህ ታምኛለሁና፣

ለሚሰድቡኝ መልስ እሰጣለሁ።

43ሕግህን ተስፋ አድርጌአለሁና፣

የእውነትን ቃል ከአፌ ፈጽመህ አታርቅ።

44ከዘላለም እስከ ዘላለም፣

ሕግህን ዘወትር እጠብቃለሁ።

45ሥርዐትህን እሻለሁና፣

እንደ ልቤ ወዲያ ወዲህ እመላለሳለሁ።

46ምስክርነትህን በነገሥታት ፊት እናገራለሁ፤

ይህን በማድረግም ዕፍረት አይሰማኝም።

47እኔ እወድደዋለሁና፣

በትእዛዝህ ደስ ይለኛል።

48እጆቼን ወደምወዳቸው119፥48 ወይም ለምወድዳቸው ትእዛዞችህ አነሣለሁ፤

ሥርዐትህንም አሰላስላለሁ።

ז ዛይን

49ለአገልጋይህ የገባኸውን ቃል ዐስብ፤

በዚያ ተስፋ ሰጥተኸዋልና።

50ቃልህ ሕያው ያደርገኛልና፣

ይህች በመከራዬ መጽናኛዬ ናት።

51እብሪተኞች እጅግ ተሣለቁብኝ፤

እኔ ግን ከሕግህ ንቅንቅ አልልም።

52እግዚአብሔር ሆይ፤ ከጥንት የነበረውን ድንጋጌህን አሰብሁ፤ በዚህም ተጽናናሁ።

53ሕግህን ከተዉ ክፉዎች የተነሣ፣

ቍጣ ወረረኝ።

54በእንግድነቴ አገር፣

ሥርዐትህ መዝሙሬ ናት።

55እግዚአብሔር ሆይ፤ ስምህን በሌሊት ዐስባለሁ፤

ሕግህንም እጠብቃለሁ።

56ሥርዐትህን እከተላለሁ፤

ይህችም ተግባሬ ሆነች።

ח ኼት

57እግዚአብሔር ዕድል ፈንታዬ ነው፤

ቃልህን ለመታዘዝ ቈርጫለሁ።

58በፍጹም ልቤ ፊትህን ፈለግሁ፤

እንደ ቃልህ ቸርነትህን አሳየኝ።

59መንገዴን ቃኘሁ፤

አካሄዴንም ወደ ምስክርህ አቀናሁ።

60ትእዛዝህን ለመጠበቅ፣

ቸኰልሁ፤ አልዘገየሁምም።

61የክፉዎች ገመድ ተተበተበብኝ፤ እኔ ግን ሕግህን አልረሳሁም።

62ስለ ጻድቅ ሥርዐትህ፣

በእኩለ ሌሊት ላመሰግንህ እነሣለሁ።

63እኔ ለሚፈሩህ ሁሉ፣

ሥርዐትህንም ለሚጠብቁ ባልንጀራ ነኝ።

64እግዚአብሔር ሆይ፤ ምድር በምሕረትህ ተሞላች፤

ሥርዐትህን አስተምረኝ።

ט ቴት

65እግዚአብሔር ሆይ፤ እንደ ቃልህ፣

ለአገልጋይህ በጎ ውለሃል።

66በትእዛዞችህ አምናለሁና፣

በጎ ማስተዋልንና ዕውቀትን አስተምረኝ።

67እንዲያው ሳይቸግረኝ መንገድ ስቼ ሄድሁ፤

አሁን ግን ቃልህን እጠብቃለሁ።

68አንተ መልካም ነህ፤ የምታደርገው መልካም ነው፤

እንግዲህ ሥርዐትህን አስተምረኝ።

69እብሪተኞች ስሜን በሐሰት አጠፉ፤

እኔ ግን ትእዛዝህን በፍጹም ልብ እጠብቃለሁ።

70ልባቸው የሠባና የደነደነ ነው፤

እኔ ግን በሕግህ ደስ ይለኛል።

71ሥርዐትህን እማር ዘንድ፣

በመከራ ውስጥ ማለፌ መልካም ሆነልኝ።

72ከአእላፋት ብርና ወርቅ ይልቅ፣

ከአፍህ የሚወጣው ሕግ ይሻለኛል።

י ዮድ

73እጆችህ ሠሩኝ፤ አበጃጁኝም፤

ትእዛዞችህን እንድማር ማስተዋልን ስጠኝ።

74ቃልህን ተስፋ አድርጌአለሁና፣

የሚፈሩህ እኔን አይተው ደስ ይበላቸው።

75እግዚአብሔር ሆይ፤ ፍርድህ የጽድቅ ፍርድ፣

ያስጨነቅኸኝም በታማኝነት እንደ ሆነ ዐወቅሁ።

76ለአገልጋይህ በገባኸው ቃል መሠረት፣

ምሕረትህ ለመጽናናት ትሁነኝ።

77ሕግህ ደስታዬ ነውና፣

በሕይወት እኖር ዘንድ ቸርነትህ ትምጣልኝ።

78እብሪተኞች ያለ ምክንያት በደል አድርሰውብኛልና ይፈሩ፤

እኔ ግን ትእዛዞችህን አሰላስላለሁ።

79አንተን የሚፈሩህ፣

ምስክርነትህንም የሚያውቁ ወደ እኔ ይመለሱ።

80እኔ እንዳላፍር፣ ልቤ በሥርዐትህ ፍጹም ይሁን።

כ ካፍ

81ነፍሴ ማዳንህን እጅግ ናፈቀች፤

ቃልህንም ተስፋ አደርጋለሁ።

82“መቼ ታጽናናኛለህ?” እያልሁ፣

ዐይኖቼ ቃልህን በመጠባበቅ ደከሙ።

83ጢስ የጠጣ የወይን አቍማዳ ብመስልም፣

ሥርዐትህን አልረሳሁም።

84የባሪያህ ዕድሜ ስንት ቢሆን ነው?

ታዲያ፣ በሚያሳድዱኝ ላይ የምትፈርደው መቼ ይሆን?

85በሕግህ መሠረት የማይሄዱ እብሪተኞች

ማጥመጃ ጕድጓድ ቈፈሩልኝ።

86ትእዛዞችህ ሁሉ አስተማማኝ ናቸው፤

ሰዎች ያለ ምክንያት አሳድደውኛልና ርዳኝ።

87ከምድር ላይ ሊያስወግዱኝ ጥቂት ቀራቸው፤

እኔ ግን ትእዛዞችህን አልተውሁም።

88እንደ ምሕረትህ መልሰህ ሕያው አድርገኝ፤

እኔም የአፍህን ምስክርነት እጠብቃለሁ።

ל ላሜድ

89እግዚአብሔር ሆይ፤ ቃልህ በሰማይ፣

ለዘላለም ጸንቶ ይኖራል።

90ታማኝነትህ ከትውልድ እስከ ትውልድ ሁሉ ይኖራል፤

ምድርን መሠረትሃት፤ እርሷም ጸንታ ትኖራለች።

91ሁሉም አገልጋይህ ነውና፣

በሕግህ መሠረት እስከ ዛሬ ድረስ ጸንተው ይኖራሉ።

92ሕግህ ደስታዬ ባይሆን ኖሮ፣

በመከራዬ ወቅት በጠፋሁ ነበር።

93በእርሱ ሕያው አድርገኸኛልና፣

ትእዛዝህን ከቶ አልረሳም።

94እኔ የአንተ ነኝ፤ እባክህ አድነኝ፤

ሕግህንም ፈልጌአለሁና።

95ክፉዎች ሊያጠፉኝ አድብተዋል፤

እኔ ግን ምስክርነትህን አሰላስላለሁ።

96ለፍጹምነት ሁሉ ዳርቻ እንዳለው አየሁ፤

ትእዛዝህ ግን እጅግ ሰፊ ነው።

מ ሜም

97አቤቱ፤ ሕግህን ምንኛ ወደድሁ!

ቀኑን ሙሉ አሰላስለዋለሁ።

98ትእዛዞችህ ምንጊዜም ስለማይለዩኝ፣

ከጠላቶቼ ይልቅ አስተዋይ አደረጉኝ።

99ምስክርነትህን አሰላስላለሁና፣

ከአስተማሪዎቼ ሁሉ የላቀ አስተዋይ ልብ አገኘሁ።

100መመሪያህን ተከትዬ እሄዳለሁና፣

ከሽማግሌዎች ይልቅ አስተዋይ ሆንሁ።

101ቃልህን እጠብቅ ዘንድ፣

እግሬን ከክፉ መንገድ ሁሉ ከለከልሁ።

102አንተው ራስህ አስተምረኸኛልና፣

ከድንጋጌህ ዘወር አላልሁም።

103ቃልህ ለምላሴ ምንኛ ጣፋጭ ነው!

ለአፌም ከማር ወለላ ይልቅ ጣዕም አለው።

104ከመመሪያህ ማስተዋልን አገኘሁ፤

ስለዚህ የሐሰትን መንገድ ሁሉ ጠላሁ።

נ ኑን

105ሕግህ ለእግሬ መብራት፣

ለመንገዴም ብርሃን ነው።

106የጽድቅ ሕግህን ለመጠበቅ፤

ምያለሁ፤ ይህንኑ አጸናለሁ።

107እጅግ ተቸግሬአለሁ፤

እግዚአብሔር ሆይ፤ እንደ ቃልህ መልሰህ ሕያው አድርገኝ።

108እግዚአብሔር ሆይ፤ ፈቅጄ ያቀረብሁትን የአፌን የምስጋና መሥዋዕት ተቀበል፤

ሕግህንም አስተምረኝ።

109ነፍሴ ዘወትር አደጋ ላይ ናት፤

ሕግህን ግን አልረሳሁም።

110ክፉዎች ወጥመድ ዘረጉብኝ፤

እኔ ግን መመሪያህን አልተላለፍሁም።

111ምስክርነትህ የዘላለም ውርሴ ናት፤

ልቤ በዚህ ሐሤት ያደርጋልና።

112ትእዛዝህን ለዘላለም፣ እስከ ወዲያኛው ለመፈጸም፣

ልቤን ወደዚያው አዘነበልሁ።

ס ሳሜክ

113መንታ ልብ ያላቸውን ጠላሁ፤

ሕግህን ግን ወደድሁ።

114አንተ መጠጊያዬና ጋሻዬ ነህ፤

ቃልህን በተስፋ እጠብቃለሁ።

115የአምላኬን ትእዛዞች እጠብቅ ዘንድ፣

እናንት ክፉ አድራጊዎች ከእኔ ራቁ።

116እንደ ቃልህ ደግፈኝ፤ እኔም ሕያው እሆናለሁ፤

ተስፋዬም መና ቀርቶ አልፈር።

117ያለ ሥጋት እቀመጥ ዘንድ ደግፈህ ያዘኝ፤

ሥርዐትህንም ዘወትር እመለከታለሁ።

118መሠሪነታቸው በከንቱ ነውና፣

ከሥርዐትህ ውጭ የሚሄዱትን ሁሉ ወዲያ አስወገድሃቸው።

119የምድርን ክፉዎች ሁሉ እንደ ጥራጊ አስወገድሃቸው፤

ስለዚህ ምስክርህን ወደድሁ።

120ሥጋዬ አንተን በመፍራት ይንቀጠቀጣል፤

ፍርድህንም እፈራለሁ።

ע ዐዪን

121ፍትሕና ጽድቅ ያለበትን ሠርቻለሁ፤

ለሚጨቍኑኝ አሳልፈህ አትስጠኝ።

122ለባሪያህ በጎነት ዋስትና ሁን፤

እብሪተኞች እንዲጨቍኑኝ አትፍቀድላቸው።

123ዐይኖቼ ማዳንህን፣

የጽድቅ ቃልህን በመጠባበቅ ደከሙ።

124ለባሪያህ እንደ ምሕረትህ መጠን አድርግ፤

ሥርዐትህንም አስተምረኝ።

125እኔ ባሪያህ ነኝ፤

ምስክርነትህን ዐውቅ ዘንድ ማስተዋልን ስጠኝ።

126እግዚአብሔር ሆይ፤

ሕግህ እየተጣሰ ነውና፣

ጊዜው አንተ የምትሠራበት ነው።

127ስለዚህ ከወርቅ፣ ከንጹሕ ወርቅ ይልቅ፣

ትእዛዞችህን ወደድሁ።

128መመሪያህ ሙሉ በሙሉ ልክ ነው አልሁ፤

ስለዚህ የሐሰትን መንገድ ሁሉ ጠላሁ።

פ ፔ

129ምስክርነትህ ሁሉ ድንቅ ነው፤

ስለዚህ ነፍሴ ትጠብቀዋለች።

130የቃልህ ትርጓሜ ያበራል፤

አላዋቂዎችንም አስተዋዮች ያደርጋል።

131ትእዛዝህን ናፍቄአለሁና፣

አፌን ከፈትሁ፤ አለከለክሁም።

132ስምህን ለሚወድዱ ማድረግ ልማድህ እንደ ሆነ ሁሉ፣

ወደ እኔ ተመልሰህ ምሕረት አድርግልኝ።

133አካሄዴን እንደ ቃልህ ቀና አድርግልኝ፤

ኀጢአትም በላዬ እንዲሠለጥን አትፍቀድ።

134ትእዛዝህን መጠበቅ እንድችል፣

ከሰዎች ጥቃት ታደገኝ።

135በባሪያህ ላይ ፊትህን አብራ፤

ሥርዐትህንም አስተምረኝ።

136ሕግህ ባለመከበሩ፤

እንባዬ እንደ ውሃ ይፈስሳል።

צ ጻዴ

137እግዚአብሔር ሆይ፤ አንተ ጻድቅ ነህ፤

ፍርድህም ትክክል ነው።

138ምስክርነትህን በጽድቅ አዘዝህ፤

እጅግ አስተማማኝም ነው።

139ጠላቶቼ ቃልህን ዘንግተዋልና፣

ቅናት አሳረረኝ።

140ቃልህ እጅግ የነጠረ ነው፤

ባሪያህም ወደደው።

141እኔ ታናሽና የተናቅሁ ነኝ፤

ነገር ግን መመሪያህን አልዘነጋሁም።

142ጽድቅህ ዘላለማዊ ጽድቅ ነው፤

ሕግህም እውነት ነው።

143መከራና ሥቃይ ደርሶብኛል፤

ነገር ግን ትእዛዝህ ደስታዬ ነው።

144ምስክርነትህ ለዘላለም የጽድቅ ምስክርነት ነው፤

በሕይወት እኖር ዘንድ ማስተዋልን ስጠኝ።

ק ቆፍ

145እግዚአብሔር ሆይ፤ በፍጹም ልቤ እጮኻለሁና መልስልኝ፤

ሥርዐትህንም እጠብቃለሁ።

146ወደ አንተ እጣራለሁና አድነኝ፤

ምስክርነትህንም እጠብቃለሁ።

147ትረዳኝ ዘንድ ጎሕ ሳይቀድድ ተነሥቼ እጮኻለሁ፤

ቃልህንም ተስፋ አደርጋለሁ።

148ቃልህን አሰላስል ዘንድ፣

ዐይኔ ሌሊቱን ሙሉ ሳይከደን ያድራል።

149እንደ ቸርነትህ መጠን ድምፄን ስማ፤

እግዚአብሔር ሆይ፤ እንደ ሕግህ መልሰህ ሕያው አድርገኝ።

150ደባ የሚያውጠነጥኑ ወደ እኔ ቀርበዋል፤

ከሕግህ ግን የራቁ ናቸው።

151እግዚአብሔር ሆይ፤ አንተ ግን ቅርብ ነህ፤

ትእዛዞችህም ሁሉ እውነት ናቸው።

152ለዘላለም እንደ መሠረትሃቸው፣

ከጥንት ምስክርነትህ ተረድቻለሁ።

ר ሬሽ

153ሕግህን አልረሳሁምና፣ ሥቃዬን ተመልከት፤ ታደገኝም።

154ተሟገትልኝ፤ አድነኝም፤

እንደ ቃልህም ሕያው አድርገኝ።

155ሥርዐትህን ስለማይሹ፣

ድነት ከክፉዎች የራቀ ነው።

156እግዚአብሔር ሆይ፤ ርኅራኄህ ታላቅ ነው፤

እንደ ሕግህ ሕያው አድርገኝ።

157የሚያሳድዱኝ ጠላቶቼ ብዙዎች ናቸው፤

እኔ ግን ከምስክርህ ዘወር አላልሁም።

158ቃልህን አይጠብቁምና፣

ከዳተኞችን አይቼ አርቃቸዋለሁ።

159መመሪያህን እንዴት እንደምወድድ ተመልከት፤

እግዚአብሔር ሆይ፤ እንደ ምሕረትህ ሕያው አድርገኝ።

160ቃልህ በሙሉ እውነት ነው፤

ጻድቅ የሆነው ሕግህም ዘላለማዊ ነው።

ש ሲን እና ሺን

161ገዦች ያለ ምክንያት አሳደዱኝ፤

ልቤ ግን ከቃልህ የተነሣ እጅግ ፈራ።

162ትልቅ ምርኮ እንዳገኘ ሰው፣

በቃልህ ደስ አለኝ።

163ሐሰትን እጠላለሁ፤ እጸየፋለሁ፤

ሕግህን ግን ወደድሁ።

164ጻድቅ ስለ ሆነው ሕግህ፣

በቀን ሰባት ጊዜ አመሰግንሃለሁ።

165ሕግህን የሚወድዱ ብዙ ሰላም አላቸው፤

ዕንቅፋትም የለባቸውም።

166እግዚአብሔር ሆይ፤ ማዳንህን ተስፋ አደርጋለሁ፤

ትእዛዝህንም እፈጽማለሁ።

167ነፍሴ ምስክርነትህን ትጠብቃለች፤

እጅግ እወድደዋለሁና።

168መንገዴ ሁሉ በፊትህ ግልጽ ነውና፣

ሕግህንና ምስክርነትህን እጠብቃለሁ።

ת ታው

169እግዚአብሔር ሆይ፤ ጩኸቴ ከፊትህ ይድረስ፤

እንደ ቃልህም ማስተዋልን ስጠኝ።

170ልመናዬ ከፊትህ ይድረስ፤

እንደ ቃልህም ታደገኝ።

171ሥርዐትህን አስተምረኸኛልና፣

ከንፈሮቼ ምስጋናን አፈለቁ።

172ትእዛዞችህ ሁሉ የጽድቅ ትእዛዞች ናቸውና፣

አንደበቴ ስለ ቃልህ ይዘምር።

173ትእዛዝህን መርጫለሁና፣

እጅህ እኔን ለመርዳት ዝግጁ ይሁን።

174እግዚአብሔር ሆይ፤ ማዳንህን ናፈቅሁ፤

ሕግህም ደስታዬ ነው።

175አመሰግንህ ዘንድ በሕይወት ልኑር፤

ሕግህም ይርዳኝ።

176እንደ ጠፋ በግ ተቅበዘበዝሁ፤

ትእዛዞችህን አልረሳሁምና፣

ባሪያህን ፈልገው።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 119:1-176

Saamu 119

1Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀,

ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.

2Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́

tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.

3Wọn kò ṣe ohun tí kò dára;

wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.

4Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀

kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.

5Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin

láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!

6Nígbà náà, ojú kò ní tì mí

nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.

7Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin

bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.

8Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀,

má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.

9Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́?

Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.

10Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi

má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.

11Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi

kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.

12Ìyìn ni fún Olúwa;

kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.

13Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò

gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.

14Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ,

bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.

15Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ

èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.

16Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ;

èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.

17Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè;

èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.

18La ojú mi kí èmi lè ríran rí

ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.

19Àlejò ní èmi jẹ́ láyé,

má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.

20Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà

nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.

21Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún

tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.

22Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi,

nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.

23Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀,

wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi,

ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.

24Òfin rẹ ni dídùn inú mi;

àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.

25Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀;

ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.

26Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn;

kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.

27Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ:

nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.

28Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́;

fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.

29Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn

fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.

30Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́

èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.

31Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa

má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.

32Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ,

nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.

33Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ;

nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.

34Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́

èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.

35Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí,

nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.

36Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ

kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.

37Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán:

pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.

38Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ,

nítorí òfin rẹ dára.

39Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù

nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.

40Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ!

Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.

41Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa,

ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.

42Nígbà náà ni èmi yóò dá

ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn,

nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.

43Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi

nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.

44Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo

láé àti láéláé.

45Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira,

nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.

46Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba

ojú kì yóò sì tì mí,

47nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ

nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.

48Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn,

èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.

49Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ,

nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.

50Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí:

ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.

51Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró,

ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.

52Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa,

èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.

53Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú,

tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.

54Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi

níbikíbi tí èmi ń gbé.

55Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa,

èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́

56nítorí tí mo

gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.

57Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa:

èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.

58Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi:

fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.

59Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi

èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.

60Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra

láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.

61Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn,

èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.

62Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ

nítorí òfin òdodo rẹ.

63Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ,

sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.

64Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa,

kọ́ mi ní òfin rẹ.

65Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ

gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.

66Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere,

nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.

67Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà,

ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.

68Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni;

kọ́ mi ní ìlànà rẹ.

69Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí,

èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.

70Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú,

ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.

71Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú

nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.

72Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ

ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.

73Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí;

fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.

74Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi,

nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.

75Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni,

àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.

76Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi,

gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.

77Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè,

nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.

78Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga

nítorí wọn pa mí lára láìnídìí

ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.

79Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi,

àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.

80Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ,

kí ojú kí ó má ṣe tì mí.

81Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ,

ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.

82Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ;

èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”

83Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín,

èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.

84Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó?

Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn

tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?

85Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi,

tí ó lòdì sí òfin rẹ.

86Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé;

ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.

87Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé,

ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.

88Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ,

èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.

89Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni;

ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.

90Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran;

ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.

91Òfin rẹ dúró di òní

nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.

92Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi,

èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.

93Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé,

nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.

94Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ

èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.

95Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run,

ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.

96Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin;

ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.

97Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó!

Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀

ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.

98Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ,

nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.

99Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ,

nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.

100Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ,

nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.

101Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi

nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.

102Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ,

nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.

103Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó,

ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!

104Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ;

nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.

105Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi

àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.

106Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn

wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.

107A pọ́n mi lójú gidigidi;

Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ

108Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi,

kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.

109Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo,

èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.

110Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi,

ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.

111Òfin rẹ ni ogún mi láéláé;

àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.

112Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́

láé dé òpin.

113Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì,

ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.

114Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi;

èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.

115Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú,

kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!

116Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ,

kí èmi kí ó lè yè

Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.

117Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu;

nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.

118Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ,

nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.

119Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́;

nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.

120Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀:

èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.

121Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́:

má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.

122Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú:

má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.

123Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ,

fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.

124Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ

kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.

125Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye

kí èmi lè ní òye òfin rẹ

126Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa;

nítorí òfin rẹ ti fọ́.

127Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ

ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,

128nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀,

èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.

129Òfin rẹ̀ ìyanu ni:

nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.

130Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá;

ó fi òye fún àwọn òpè.

131Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ,

nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.

132Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi,

bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn

tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.

133Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ,

má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.

134Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn,

kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.

135Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára

kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.

136Omijé sàn jáde ní ojú mi,

nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.

137Olódodo ni ìwọ Olúwa

ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.

138Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo:

wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.

139Ìtara mi ti pa mí run,

nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.

140Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá

ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.

141Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn

èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.

142Òdodo rẹ wà títí láé

òtítọ́ ni òfin rẹ̀.

143Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi,

ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.

144Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé;

fún mi ní òye kí èmi lè yè.

145Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi:

dá mi lóhùn Olúwa,

èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.

146Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí

èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.

147Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́;

èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.

148Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru,

nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.

149Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ:

pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.

150Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí,

ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.

151Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa,

àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.

152Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ

tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.

153Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí,

nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.

154Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà;

pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.

155Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú

nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.

156Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa;

pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.

157Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi,

ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.

158Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́

nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.

159Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ;

pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.

160Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ;

gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.

161Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí,

ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.

162Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ

bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.

163Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe

ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.

164Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́

nítorí òfin òdodo rẹ.

165Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ,

kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.

166Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa,

èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.

167Èmi gba òfin rẹ gbọ́,

nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.

168Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ,

nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.

169Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa;

fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.

170Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ;

gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.

171Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde,

nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.

172Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ,

nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.

173Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́,

nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.

174Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa,

àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.

175Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́,

kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.

176Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù.

Wá ìránṣẹ́ rẹ,

nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.