Masomphenya a Obadiya
1Masomphenya a Obadiya.
Ambuye Yehova akunena kwa Edomu kuti,
Tamva uthenga wochokera kwa Yehova:
Nthumwi yatumidwa kupita kwa anthu a mitundu kukanena kuti,
“Konzekani, tiyeni tikachite nkhondo ndi Edomu.”
2“Taona, ndidzakuchepetsani pakati pa anthu a mitundu ina;
udzanyozedwa kwambiri.
3Kudzikuza kwa mtima wako kwakusocheretsa,
iwe amene umakhala mʼmapanga a mʼmatanthwe
ndipo umamanga nyumba zako pa mapiri ataliatali,
iwe amene umanena mu mtima mwako kuti,
‘Ndani anganditsitse pansi?’
4Koma ngakhale umawuluka ngati chiwombankhanga
ndi kumanga chisa chako pakati pa nyenyezi,
ndidzakutsitsa pansi kuchokera kumeneko,”
akutero Yehova.
5“Anthu akuba akanabwera kwa iwe,
kapena anthu olanda zinthu akanafika usiku,
aa, tsoka lanji limene likukudikira iwe!
Kodi akanangotengako zimene akuzifuna zokha?
Ngati anthu othyola mphesa akanafika,
kodi akanakusiyiraniko mphesa pangʼono pokha?
6Koma Esau adzalandidwa zinthu zonse,
chuma chake chobisika chidzabedwa!
7Anthu onse ogwirizana nawo adzakupirikitsira kumalire;
abwenzi ako adzakunyenga ndi kukugonjetsa;
amene amadya chakudya chako adzakutchera msampha,
koma iwe sudzazindikira zimenezi.”
8Yehova akunena kuti, “Tsiku limenelo,
kodi sindidzawononga anthu onse anzeru a ku Edomu,
anthu odziwa zinthu mʼmapiri a Esau?
9Ankhondo ako, iwe Temani, adzachita mantha,
ndipo aliyense amene ali mʼphiri la Esau
adzaphedwa pa nkhondo.
10Chifukwa cha nkhanza zimene unachitira mʼbale wako Yakobo,
udzakhala wamanyazi;
adzakuwononga mpaka muyaya.
11Pamene adani
ankamulanda chuma chake
pamene alendo analowa pa zipata zake
ndi kuchita maere pa Yerusalemu,
pa tsikulo iwe unali ngati mmodzi wa iwo.
12Iwe sunayenera kunyoza mʼbale wako
pa nthawi ya tsoka lake,
kapena kunyogodola Ayuda
chifukwa cha chiwonongeko chawo,
kapena kuwaseka pa nthawi ya
mavuto awo.
13Iwe sunayenera kudutsa pa zipata za anthu anga
pa nthawi ya masautso awo,
kapena kuwanyogodola
pa tsiku la tsoka lawo,
kapena kulanda chuma chawo
pa nthawi ya masautso awo.
14Sunayenera kudikirira pamphambano ya misewu
kuti uphe Ayuda othawa,
kapena kuwapereka kwa adani awo Ayuda opulumuka
pa nthawi ya mavuto awo.”
15“Tsiku la Yehova layandikira
limene adzaweruza mitundu yonse ya anthu.
Adzakuchitira zomwe unawachitira ena;
zochita zako zidzakubwerera wekha.
16Iwe unamwa pa phiri langa loyera,
koteronso mitundu ina yonse idzamwa kosalekeza;
iwo adzamwa ndi kudzandira
ndipo adzayiwalika pa mbiri ya dziko lapansi.
17Koma pa Phiri la Ziyoni padzakhala chipulumutso;
phirilo lidzakhala lopatulika,
ndipo nyumba ya Yakobo
idzalandira cholowa chake.
18Nyumba ya Yakobo idzasanduka moto
ndipo nyumba ya Yosefe idzasanduka lawi la moto;
nyumba ya Esau idzasanduka chiputu,
ndipo adzayitenthe pa moto ndi kuyipsereza.
Sipadzakhala anthu opulumuka
kuchokera mʼnyumba ya Esau.”
Yehova wayankhula.
19Anthu ochokera ku Negevi adzakhala
ku mapiri a Esau,
ndipo anthu ochokera mʼmbali mwa mapiri
adzatenga dziko la Afilisti.
Adzakhala mʼminda ya Efereimu ndi Samariya,
ndipo Benjamini adzatenga Giliyadi.
20Aisraeli amene ali ku ukapolo
adzalandira dziko la Kanaani mpaka ku Zarefati;
a ku Yerusalemu amene ali ku ukapolo ku Sefaradi
adzalandira mizinda ya ku Negevi.
21Opulumukawo adzapita ku Phiri la Ziyoni
ndipo adzalamulira mapiri a Esau.
Koma ufumuwo udzakhala wa Yehova.
1Ìran ti Ọbadiah.
1-21: Isa 34; 63.1-6; Jr 49.7-22; El 25.12-14; 35; Am 1.11-12; Ml 1.2-5.Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu.
Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá:
A sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé,
“Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”
2“Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí;
ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọpọ̀,
3Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ,
ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta,
tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga,
ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé,
‘ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’
4Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì,
bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀,
láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,”
ni Olúwa wí.
5“Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá,
bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru,
Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́:
wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́?
Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá,
wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?
6Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau,
tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.
7Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ
ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ:
Àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ;
àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́,
ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”
8Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà,
Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run,
àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?
9A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, Ìwọ Temani,
gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau
ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.
10Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ,
ìtìjú yóò bò ọ,
a ó sì pa ọ run títí láé.
11Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan,
ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ,
tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ
tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu,
ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.
12Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ,
ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀
ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda,
ní ọjọ́ ìparun wọn
ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀
ní ọjọ́ wàhálà wọn.
13Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ,
ní ọjọ́ àjálù wọn.
Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀
nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn.
Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó,
ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
14Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà
láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò.
Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú
wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
15“Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé
lórí gbogbo àwọn kèfèrí.
Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà;
ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.
16Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi
bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí
Wọn yóò mu wọn yóò sì mu àmutẹ́rùn
wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò wà rí
17Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni
Wọn yóò sì jẹ́ mímọ́
àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn
18Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná
àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná
ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko
wọn yóò fi iná sí i,
wọn yóò jo run.
Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.”
Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
19Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau,
àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni
ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní.
Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria;
Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.
20Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani
yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati;
àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi
yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní
21Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá
láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau.
Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.