撒母耳记下 9 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

撒母耳记下 9:1-13

大卫恩待米非波设

1大卫问:“扫罗一家还有什么人吗?我要因为和约拿单的情义而恩待他。” 2有人就去叫扫罗家一个名叫洗巴的仆人来见大卫,王问他:“你就是洗巴吗?”他说:“仆人正是洗巴。” 3王说:“扫罗家中还有什么人?我要以上帝的慈爱来待他。”洗巴答道:“约拿单还有一个儿子,是双脚残废的。” 4王说:“他在哪里?”洗巴答道:“他住在罗·底巴,在亚米利的儿子玛吉家里。” 5于是,大卫王派人去罗·底巴把他从亚米利的儿子玛吉家里接来。 6扫罗的孙子、约拿单的儿子米非波设来到大卫面前,向他俯伏叩拜。大卫说:“米非波设!”米非波设答道:“仆人在这里。” 7大卫说:“你不用害怕,我要因为和你父亲约拿单的情义而恩待你。我要把你祖父扫罗所有的田地归还给你,你要常与我同席吃饭。” 8米非波设再次叩拜,说:“仆人算什么?不过像一条死狗罢了,你竟这样眷顾我!”

9王又把扫罗的仆人洗巴召来,对他说:“我已把扫罗全家的产业都赐给了你主人的孙子米非波设10你和你的儿子及仆人要为米非波设种田,把出产拿来供养他。他还要常常与我同席吃饭。”洗巴有十五个儿子,二十个仆人。 11洗巴对王说:“仆人必遵行我主我王的一切吩咐。”于是,米非波设像王子一样常与大卫同席吃饭。 12米非波设有一个小儿子名叫米迦洗巴家中的人都做了米非波设的仆人。 13从此,双脚残废的米非波设就住在耶路撒冷,常常与王同席吃饭。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

2 Samuẹli 9:1-13

Dafidi àti Mefiboṣeti

1Dafidi sì béèrè pé, ọ̀kan nínú àwọn ẹni tí ń ṣe ìdílé Saulu kù síbẹ̀ bí? Kí èmi lè ṣe oore fún un nítorí Jonatani.

2Ìránṣẹ́ kan sì ti wà ní ìdílé Saulu, orúkọ rẹ̀ sí ń jẹ́ Ṣiba, wọ́n sì pè é wá sọ́dọ̀ Dafidi, ọba sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ìwọ ni Ṣiba bí?”

Ó sì dáhùn wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni.”

3Ọba sì wí pé, “Kò ha sí ọ̀kan nínú ìdílé Saulu síbẹ̀, kí èmi ṣe oore Ọlọ́run fún un?”

Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Jonatani ní ọmọ kan síbẹ̀ tó ya arọ.”

4Ọba sì wí fún un pé, “Níbo ni ó gbé wà?”

Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Wò ó, òun wà ní ilé Makiri, ọmọ Ammieli, ní Lo-Debari.”

5Dafidi ọba sì ránṣẹ́, ó sì mú un láti ilé Makiri ọmọ Ammieli láti Lo-Debari wá.

6Mefiboṣeti ọmọ Jonatani ọmọ Saulu sì tọ Dafidi wá, ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì bú ọlá fún un.

Dafidi sì wí pé, “Mefiboṣeti!”

Òun sì dáhùn wí pé, “Wò ó, ìránṣẹ́ rẹ!”

7Dafidi sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù, nítorí pé nítòótọ́ èmi ó ṣe oore fún ọ nítorí Jonatani baba rẹ, èmi ó sì tún fi gbogbo ilé Saulu baba rẹ fún ọ, ìwọ ó sì máa bá mi jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ mi.”

8Mefiboṣeti sì tẹríba, ó sì wí pé, “Kí ni ìránṣẹ́ rẹ jásí, tí ìwọ ó fi máa wo òkú ajá bí èmi.”

9Ọba sì pe Ṣiba ìránṣẹ́ Saulu, ó sì wí fún un pé, “Gbogbo nǹkan tí í ṣe ti Saulu, àti gbogbo èyí tí í ṣe ti ìdílé rẹ̀ ni èmi fi fún ọmọ olúwa rẹ. 10Ìwọ, àti àwọn ọmọ rẹ, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ ni yóò sì máa ro ilẹ̀ náà fún un, ìwọ ni yóò sì máa mú ìkórè wá, ọmọ olúwa rẹ yóò sì máa rí oúnjẹ jẹ, ṣùgbọ́n Mefiboṣeti ọmọ olúwa rẹ yóò sì máa bá mi jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ mi.” (Ṣiba sì ní ọmọ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àti ogún ìránṣẹ́kùnrin.)

11Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí olúwa mi ọba ti pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ náà ni ìránṣẹ́ rẹ ó ṣe.” Ọba sì wí pé, “Ní ti Mefiboṣeti, yóò máa jẹun ní ibi oúnjẹ mi, gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ọba.”

12Mefiboṣeti sì ní ọmọ kékeré kan, orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mika. Gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilé Ṣiba ni ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún Mefiboṣeti. 13Mefiboṣeti sì ń gbé ní Jerusalẹmu, òun a sì máa jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ ọba; òun sì yarọ ní ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì.