腓立比书 3 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible 2022 (Simplified)

腓立比书 3:1-21

认识基督最宝贵

1此外,弟兄姊妹,你们要靠主喜乐!我再把这些事写给你们,对我来说并不麻烦,对你们却是保障。 2你们要提防那些犬类,提防那些作恶的人,提防那些鼓吹必须受割礼3:2 “割礼”参见创世记17章;希腊文用夸张的字眼描述割礼,有讽刺之意。才能得救的人。 3因为真正受割礼的人是我们这些靠着上帝的灵敬拜、以基督耶稣为荣、不倚靠自身条件的人。 4其实我也可以靠自身的条件。如果别人觉得可以靠自身的条件,我更可以。 5我出生后第八天就受了割礼,我是以色列人,属于便雅悯支派,是地地道道的希伯来人。论守律法,我是法利赛人; 6论热心,我曾经迫害教会;论律法要求的义,我是无可指责的。 7但是为了基督,我从前以为有价值的,现在认为毫无价值。 8不但如此,我看万事都毫无价值,因为认识我主基督耶稣是最宝贵的。我为祂失去了一切,我把失去的一切视为粪土,好得到基督, 9与祂联合。我并非拥有源于律法的义,而是拥有信靠基督而得的义。这义从上帝而来,以信为基础。 10我渴望认识基督和祂复活的大能,与祂一同受苦,甚至到死的地步3:10 “甚至到死的地步”或译“效法祂的死”。11这样我无论如何都可以从死里复活。

直奔标竿

12这并不是说我已经得到了或者纯全了,我还要竭力追求,或许可以达到基督耶稣要我达到的目标。 13弟兄姊妹,我并非以为自己已经得到了,我只专注一件事,就是忘记背后,努力向前, 14直奔目标,要赢得上帝借着基督耶稣从天上呼召我去得的奖赏。 15我们中间成熟的基督徒都应该有这样的看法。即使你们有什么不同看法,上帝也必让你们明白。 16然而,我们长进到什么程度,就照着什么程度去行。

17弟兄姊妹,你们要一同效法我,也要向那些以我们为榜样的人学习。 18我已经多次告诉你们,现在又流着泪提醒你们:有许多人行事为人与基督的十字架为敌。 19他们的神就是自己的肚腹,他们以自己的羞耻为荣,只想着地上的事,他们的结局是灭亡。 20我们却是天上的国民,热切等候从天降临的救主,就是主耶稣基督。 21那时,祂要以降服万物的大能将我们这卑贱的躯体改变成像祂那样荣耀的身体。

Yoruba Contemporary Bible

Filipi 3:1-21

Kò sí ìgbẹ́kẹ̀lé ẹlẹ́ran ara

1Ní àkótán ará, ẹ máa yọ̀ nínú Olúwa wa. Kì í ṣe ìnira fún mi láti kọ̀wé ohun kan náà sí yín, ṣùgbọ́n fún yín ó jẹ́ ohun ààbò. 2Ẹ kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn ajá, ẹ kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn oníṣẹ́ búburú, ẹ sì kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn onílà. 33.3: Ro 2.28-29; Ga 6.14-15.Nítorí àwa ni onílà, tí ń sin Ọlọ́run nípa ti Ẹ̀mí, àwa sì ń ṣògo nínú Kristi Jesu, àwa kò sí ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ẹran-ara. 43.4-7: Ap 8.3; 22.3-21; 23.6; 26.4-23; Ro 11.1; 2Kọ 11.18-31.Bí èmi tìkára mi pẹ̀lú ti ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ara.

Bí ẹnikẹ́ni bá rò pé òun ni ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ara, tèmi tilẹ̀ pọ̀: 5Ẹni tí a kọ nílà ní ọjọ́ kẹjọ, láti inú kùkùté Israẹli wá, láti inú ẹ̀yà Benjamini, Heberu láti inú Heberu wá; nítorí, ní ti òfin Farisi ni èmi; 6Ní ti ìtara, èmi ń ṣe inúnibíni sí ìjọ; ní ti òdodo tí ó wà nínú òfin, mo jẹ́ aláìlẹ́gàn.

7Ṣùgbọ́n ohunkóhun tí ó ti jásí èrè fún mi, àwọn ni mo ti kà sí òfo nítorí Kristi. 8Nítòótọ́ láìṣe àní àní mo sì ka ohun gbogbo sí òfo nítorí ìtayọ ìmọ̀ Kristi Jesu Olúwa mi; nítorí ẹni ti mo ti ṣòfò ohun gbogbo, mo si kà wọn sí ohun tí kò ní èrè, kí èmi lè jèrè Kristi, 9Kí a sì lè bá mi nínú rẹ̀, láìní òdodo tí èmi tìkára mi, tí ó ti inú òfin wá, ṣùgbọ́n èyí tí ó ti inú ìgbàgbọ́ wá nínú Kristi, òdodo láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run nípasẹ̀ ìgbàgbọ́; 10Èmi mọ̀ ọ́n, àti agbára àjíǹde rẹ̀, àti láti jẹ́ alábápín nínú ìyà rẹ̀ nígbà tí mo bá fi ara mọ́ ọn nínú ikú rẹ̀; 11nípasẹ̀ bẹ́ẹ̀ kí èmi lè ní àjíǹde kúrò nínú òkú.

12Kì í ṣe pé ọwọ́ mi ti tẹ̀ ẹ́ ná, tàbí mo ti di pípé: ṣùgbọ́n èmi ń lépa sí i, bí ọwọ́ mi yóò lè tẹ èrè náà nítorí èyí tí a ti dì mímú pẹ̀lú, láti ọ̀dọ̀ Kristi Jesu wá. 13Ará, èmi kò kara mi sí ẹni ti ọwọ́ rẹ̀ ti tẹ̀ ẹ́ ná: Ṣùgbọ́n ohun kan yìí ni èmi ń ṣe, èmi ń gbàgbé àwọn nǹkan tí ó ti kọjá. Lẹ́yìn náà mo ń nàgà wo àwọn nǹkan tí ó wà níwájú. 14Èmi ń lépa láti dé òpin eré ìje náà fún èrè ìpè gíga Ọlọ́run nínú Kristi Jesu.

15Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí àwa tí a dàgbà nípa ti ẹ̀mí ni èrò yìí; bí ẹ̀yin bá sì ní èrò mìíràn nínú ohunkóhun, èyí náà pẹ̀lú ni Ọlọ́run yóò fihàn yín. 16Kìkì pé, ki a ma gbe ìgbé ayé gẹ́gẹ́ bi èyí ti a ri gba.

173.17: 1Kọ 4.15-17.Ará, ẹ jùmọ̀ ṣe àfarawé mi, ẹ ṣe àkíyèsí àwọn tí ń rìn bẹ́ẹ̀, àní bí ẹ ti ní wa fún àpẹẹrẹ. 18Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ní ń rìn, nípasẹ̀ àwọn ẹni tí mo ti ń wí fún yín nígbàkúgbà, àní, tí mo sì ń sọkún bí mo ti ń wí fún yín nísinsin yìí, pé, ọ̀tá àgbélébùú Kristi ni wọ́n: 19Ìgbẹ̀yìn wọn ni ìparun, ikùn wọn sì ni Ọlọ́run wọn, wọ́n sì ń ṣògo nínú ìtìjú wọn, àwọn ẹni tí ń tọ́jú ohun ti ayé. 20Nítorí ìlú ìbílẹ̀ wá ń bẹ̀ ní ọ̀run: láti ibi ti àwa pẹ̀lú gbé ń fojúsọ́nà fún Olùgbàlà, Jesu Kristi Olúwa. 213.21: 1Kọ 15.35-58; Kl 3.4.Ẹni tí yóò sọ ara ìrẹ̀lẹ̀ wa di ọ̀tún kí ó lè bá ara ògo rẹ̀ mu, nípa agbára tí ó mú kí ó ṣe é ṣe fún un láti tẹ orí ohun gbogbo bá fún ara rẹ̀.