1屡教不改、顽固不化者,
必突然灭亡,无可挽救。
2义人增多,万众欢腾;
恶人得势,万民叹息。
3爱慕智慧的使父亲欢欣,
结交妓女的必耗尽钱财。
4君王秉公行义,国家安定;
他若收受贿赂,国必倾倒。
5奉承邻舍,等于设网罗绊他。
6恶人被自己的罪缠住,
义人却常常欢喜歌唱。
7义人关心穷人的冤屈,
恶人对此漠不关心。
8狂徒煽动全城,
智者平息众怒。
9智者跟愚人对簿公堂,
愚人会怒骂嬉笑不止。
10嗜杀之徒憎恶纯全无过的人,
但正直的人保护他们29:10 “但正直的人保护他们”或译“索取正直人的性命”。。
11愚人尽发其怒,
智者忍气含怒。
12君王若听谗言,
臣仆必成奸徒。
13贫穷人和欺压者有共同点:
他们的眼睛都是耶和华所赐。
14君王若秉公审判穷人,
他的王位必永远坚立。
15管教之杖使孩子得智慧,
放纵的子女让母亲蒙羞。
16恶人当道,罪恶泛滥;
义人必得见他们败亡。
17好好管教儿子,
他会带给你平安和喜乐。
18百姓无神谕便任意妄为,
但遵守律法的人必蒙福。
19管教仆人不能单靠言语,
因为他虽明白却不服从。
20言语急躁的人,
还不如愚人有希望。
21主人若从小就娇惯仆人,
他终必成为主人的麻烦。
22愤怒的人挑起纷争,
暴躁的人多有过犯。
23骄傲的人必遭贬抑,
谦卑的人必得尊荣。
24与盗贼为伍是憎恶自己,
他即使发誓也不敢作证。
25惧怕人的必自陷网罗,
信靠耶和华的必安稳。
26许多人讨君王的欢心,
但正义伸张靠耶和华。
27为非作歹,义人厌恶;
行为正直,恶人憎恨。
1Ẹni tí ó sì ń ṣorí kunkun lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìbáwí
yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.
2Nígbà tí olódodo bá ń gbilẹ̀, àwọn ènìyàn a yọ̀
nígbà tí ènìyàn búburú ń ṣàkóso, àwọn ènìyàn ń kórìíra.
3Ènìyàn tí ó fẹ́ràn ọgbọ́n mú kí baba rẹ̀ láyọ̀
ṣùgbọ́n ẹni ti ń bá panṣágà kẹ́gbẹ́ ba ọrọ̀ ọ rẹ̀ jẹ́.
4Nípa ìdájọ́ òdodo ni ọba fi í mú ìlú tòrò nini,
ṣùgbọ́n èyí tí ń ṣe ojúkòkòrò àbẹ̀tẹ́lẹ̀ fà á lulẹ̀.
5Ẹnikẹ́ni tí ó bá tan aládùúgbò rẹ̀
ó ń dẹ àwọ̀n de ẹsẹ̀ ẹ rẹ̀.
6Ẹ̀ṣẹ̀ ènìyàn ibi ni ó jẹ́ ìdẹ̀kùn rẹ̀
ṣùgbọ́n olódodo le è kọrin kí ó sì máa yọ̀.
7Olódodo ń máa ro ọ̀rọ̀ tálákà,
ṣùgbọ́n ènìyàn búburú kò sú sí i láti rò ó.
8Àwọn ẹlẹ́yà a máa ru ìlú sókè,
ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn máa ń mú ìbínú kúrò.
9Bí ọlọ́gbọ́n ènìyàn bá lọ sí ilé ẹjọ́ pẹ̀lú aláìgbọ́n
aláìgbọ́n a máa bínú a sì máa jà, kò sì ní sí àlàáfíà.
10Àwọn tí ó ń tàjẹ̀ sílẹ̀ kò rí ẹni dídúró ṣinṣin
wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa olódodo.
11Aláìgbọ́n ènìyàn fi gbogbo ẹnu rẹ̀ bínú
ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa kó ìbínú rẹ̀ ní ìjánu.
12Bí olórí bá fetí sí irọ́,
gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ a di ènìyàn búburú lójú rẹ̀.
13Tálákà ènìyàn àti aninilára jọ ní àbùdá yìí,
Olúwa jẹ́ kí ojú àwọn méjèèjì máa ríran.
14Bí ọba kan bá ń ṣe ìdájọ́ tálákà pẹ̀lú òtítọ́
ìtẹ́ ìjọba rẹ yóò fìdímúlẹ̀ nígbà gbogbo.
15Ọ̀pá ìbániwí ń fún ni ní ọgbọ́n
ṣùgbọ́n ọmọ tí a fi sílẹ̀ fúnrarẹ̀ a dójútì ìyá rẹ̀.
16Nígbà tí ènìyàn búburú ń gbilẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀ṣẹ̀ ń gbilẹ̀
ṣùgbọ́n olódodo yóò rí ìṣubú wọn.
17Bá ọmọ rẹ wí, yóò sì fún ọ ní àlàáfíà
yóò sì mú inú dídùn wá sí inú ọkàn rẹ.
18Níbi tí kò ti sí ìfihàn, àwọn ènìyàn a gbé ìgbé ayé àìbìkítà,
ṣùgbọ́n ìbùkún ní fún àwọn tí ń pa òfin mọ́.
19A kò le fi ọ̀rọ̀ lásán kìlọ̀ fún ìránṣẹ́
bí ó tilẹ̀ yé e, kò ní kọbi ara sí i.
20Ǹjẹ́ ó rí ènìyàn tí ń kánjú sọ̀rọ̀?
Ìrètí wà fún aláìgbọ́n jù ú lọ.
21Bí ènìyàn kan bá kẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ lákẹ̀ẹ́jù láti kékeré
yóò mú ìbànújẹ́ wá ní ìgbẹ̀yìn.
22Oníbìínú ènìyàn a ru ìjà sókè,
onínú-fùfù ènìyàn a sì máa dá ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀.
23Ìgbéraga ènìyàn a máa sọ ọ́ di ẹni ilẹ̀
ṣùgbọ́n onírẹ̀lẹ̀ ènìyàn a máa gba iyì kún iyì.
24Ẹni tí ó ń kó ẹgbẹ́, olè kórìíra ọkàn ara rẹ̀,
ó ń gbọ́ èpè olóhun kò sì le è fọhùn.
25Ìbẹ̀rù ènìyàn kan yóò sì di ìdẹ̀kùn
ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bẹ̀rù Olúwa wà láìléwu.
26Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ń wá ojúrere alákòóso,
ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ènìyàn tí ń gba ìdájọ́ òdodo.
27Olódodo kórìíra àwọn aláìṣòótọ́:
ènìyàn búburú kórìíra olódodo.