箴言 29 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

箴言 29:1-27

1屡教不改、顽固不化者,

必突然灭亡,无可挽救。

2义人增多,万众欢腾;

恶人得势,万民叹息。

3爱慕智慧的使父亲欢欣,

结交妓女的必耗尽钱财。

4君王秉公行义,国家安定;

他若收受贿赂,国必倾倒。

5奉承邻舍,等于设网罗绊他。

6恶人被自己的罪缠住,

义人却常常欢喜歌唱。

7义人关心穷人的冤屈,

恶人对此漠不关心。

8狂徒煽动全城,

智者平息众怒。

9智者跟愚人对簿公堂,

愚人会怒骂嬉笑不止。

10嗜杀之徒憎恶纯全无过的人,

但正直的人保护他们29:10 但正直的人保护他们”或译“索取正直人的性命”。

11愚人尽发其怒,

智者忍气含怒。

12君王若听谗言,

臣仆必成奸徒。

13贫穷人和欺压者有共同点:

他们的眼睛都是耶和华所赐。

14君王若秉公审判穷人,

他的王位必永远坚立。

15管教之杖使孩子得智慧,

放纵的子女让母亲蒙羞。

16恶人当道,罪恶泛滥;

义人必得见他们败亡。

17好好管教儿子,

他会带给你平安和喜乐。

18百姓无神谕便任意妄为,

但遵守律法的人必蒙福。

19管教仆人不能单靠言语,

因为他虽明白却不服从。

20言语急躁的人,

还不如愚人有希望。

21主人若从小就娇惯仆人,

他终必成为主人的麻烦。

22愤怒的人挑起纷争,

暴躁的人多有过犯。

23骄傲的人必遭贬抑,

谦卑的人必得尊荣。

24与盗贼为伍是憎恶自己,

他即使发誓也不敢作证。

25惧怕人的必自陷网罗,

信靠耶和华的必安稳。

26许多人讨君王的欢心,

但正义伸张靠耶和华。

27为非作歹,义人厌恶;

行为正直,恶人憎恨。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 29:1-27

1Ẹni tí ó sì ń ṣorí kunkun lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìbáwí

yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.

2Nígbà tí olódodo bá ń gbilẹ̀, àwọn ènìyàn a yọ̀

nígbà tí ènìyàn búburú ń ṣàkóso, àwọn ènìyàn ń kórìíra.

3Ènìyàn tí ó fẹ́ràn ọgbọ́n mú kí baba rẹ̀ láyọ̀

ṣùgbọ́n ẹni ti ń bá panṣágà kẹ́gbẹ́ ba ọrọ̀ ọ rẹ̀ jẹ́.

4Nípa ìdájọ́ òdodo ni ọba fi í mú ìlú tòrò nini,

ṣùgbọ́n èyí tí ń ṣe ojúkòkòrò àbẹ̀tẹ́lẹ̀ fà á lulẹ̀.

5Ẹnikẹ́ni tí ó bá tan aládùúgbò rẹ̀

ó ń dẹ àwọ̀n de ẹsẹ̀ ẹ rẹ̀.

6Ẹ̀ṣẹ̀ ènìyàn ibi ni ó jẹ́ ìdẹ̀kùn rẹ̀

ṣùgbọ́n olódodo le è kọrin kí ó sì máa yọ̀.

7Olódodo ń máa ro ọ̀rọ̀ tálákà,

ṣùgbọ́n ènìyàn búburú kò sú sí i láti rò ó.

8Àwọn ẹlẹ́yà a máa ru ìlú sókè,

ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn máa ń mú ìbínú kúrò.

9Bí ọlọ́gbọ́n ènìyàn bá lọ sí ilé ẹjọ́ pẹ̀lú aláìgbọ́n

aláìgbọ́n a máa bínú a sì máa jà, kò sì ní sí àlàáfíà.

10Àwọn tí ó ń tàjẹ̀ sílẹ̀ kò rí ẹni dídúró ṣinṣin

wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa olódodo.

11Aláìgbọ́n ènìyàn fi gbogbo ẹnu rẹ̀ bínú

ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa kó ìbínú rẹ̀ ní ìjánu.

12Bí olórí bá fetí sí irọ́,

gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ a di ènìyàn búburú lójú rẹ̀.

13Tálákà ènìyàn àti aninilára jọ ní àbùdá yìí,

Olúwa jẹ́ kí ojú àwọn méjèèjì máa ríran.

14Bí ọba kan bá ń ṣe ìdájọ́ tálákà pẹ̀lú òtítọ́

ìtẹ́ ìjọba rẹ yóò fìdímúlẹ̀ nígbà gbogbo.

15Ọ̀pá ìbániwí ń fún ni ní ọgbọ́n

ṣùgbọ́n ọmọ tí a fi sílẹ̀ fúnrarẹ̀ a dójútì ìyá rẹ̀.

16Nígbà tí ènìyàn búburú ń gbilẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀ṣẹ̀ ń gbilẹ̀

ṣùgbọ́n olódodo yóò rí ìṣubú wọn.

17Bá ọmọ rẹ wí, yóò sì fún ọ ní àlàáfíà

yóò sì mú inú dídùn wá sí inú ọkàn rẹ.

18Níbi tí kò ti sí ìfihàn, àwọn ènìyàn a gbé ìgbé ayé àìbìkítà,

ṣùgbọ́n ìbùkún ní fún àwọn tí ń pa òfin mọ́.

19A kò le fi ọ̀rọ̀ lásán kìlọ̀ fún ìránṣẹ́

bí ó tilẹ̀ yé e, kò ní kọbi ara sí i.

20Ǹjẹ́ ó rí ènìyàn tí ń kánjú sọ̀rọ̀?

Ìrètí wà fún aláìgbọ́n jù ú lọ.

21Bí ènìyàn kan bá kẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ lákẹ̀ẹ́jù láti kékeré

yóò mú ìbànújẹ́ wá ní ìgbẹ̀yìn.

22Oníbìínú ènìyàn a ru ìjà sókè,

onínú-fùfù ènìyàn a sì máa dá ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀.

23Ìgbéraga ènìyàn a máa sọ ọ́ di ẹni ilẹ̀

ṣùgbọ́n onírẹ̀lẹ̀ ènìyàn a máa gba iyì kún iyì.

24Ẹni tí ó ń kó ẹgbẹ́, olè kórìíra ọkàn ara rẹ̀,

ó ń gbọ́ èpè olóhun kò sì le è fọhùn.

25Ìbẹ̀rù ènìyàn kan yóò sì di ìdẹ̀kùn

ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bẹ̀rù Olúwa wà láìléwu.

26Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ń wá ojúrere alákòóso,

ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ènìyàn tí ń gba ìdájọ́ òdodo.

27Olódodo kórìíra àwọn aláìṣòótọ́:

ènìyàn búburú kórìíra olódodo.