Saamu 70:1-5 YCB

Saamu 70:1-5

Saamu 70

Fún adarí orin. Ti Dafidi. Ẹ̀bẹ̀.

70.1-5: Sm 40.13-17.Yára, Ọlọ́run, láti gbà mí là,

Olúwa, wá kánkán láti ràn mí lọ́wọ́.

Kí àwọn tí ń wá ọkàn mi

kí a dójútì wọ́n, kí wọn sì dààmú;

kí àwọn tó ń wá ìparun mi

yí ẹ̀yìn padà nínú ìtìjú.

Kí a pa wọ́n ní ẹ̀yìn dà fún èrè

ìtìjú àwọn tí ń wí pé, “Háà! Háà!”

Ṣùgbọ́n kí àwọn tí ó ń wá ọ ó máa yọ̀

kí inú wọn kí ó sì máa dùn nípa rẹ,

kí àwọn tí ó ń fẹ́ ìgbàlà rẹ máa wí pé,

“Jẹ́ kí a gbé Ọlọ́run ga!”

Ṣùgbọ́n mo jẹ́ òtòṣì àti aláìní;

wa kánkán sí ọ̀dọ̀ mi, Ọlọ́run.

Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ àti olùdáǹdè mi;

Olúwa, má ṣe dúró pẹ́.

Read More of Saamu 70