Sekariah 12 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sekariah 12:1-14

A o pa àwọn ọ̀tá Jerusalẹmu run

1Ọ̀rọ̀-ìmọ̀: Ọ̀rọ̀ Olúwa fún Israẹli ni.

Olúwa wí, ẹni tí ó na àwọn ọ̀run, tí ó sì fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, tí ó sì da ẹ̀mí ènìyàn tí ń bẹ ni inú rẹ̀: 2“Kíyèsi í, èmi yóò sọ Jerusalẹmu dí àgọ́ ìwárìrì sí gbogbo ènìyàn yíká, nígbà tí wọn yóò dó ti Juda àti Jerusalẹmu. 3Ní ọjọ́ náà, nígbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè ayé bá parapọ̀ sí i, ni èmi yóò sọ Jerusalẹmu di òkúta ti ko ṣe yí kúrò fún gbogbo ènìyàn: gbogbo àwọn tí ó bá sì fẹ́ yí i ni a ó gé sí wẹ́wẹ́, 4ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí, “Ni èmi yóò fi ìdágìrì lu gbogbo ẹṣin, àti fi òmùgọ̀ kọlu ẹni tí ń gun un; èmi yóò sì ṣí ojú mi sí ilé Juda, èmi yóò sì bu ìfọ́jú lu gbogbo ẹṣin tí orílẹ̀-èdè. 5Àti àwọn baálẹ̀ Juda yóò sì wí ni ọkàn wọn pé, ‘Àwọn ara Jerusalẹmu ni agbára mi nípa Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ọlọ́run wọn.’

6“Ní ọjọ́ náà, ni èmi yóò ṣe àwọn baálẹ̀ Juda bí ààrò iná kan láàrín igi, àti bi ẹ̀fúùfù iná láàrín ìtí; wọn yóò sì jẹ gbogbo àwọn ènìyàn run yíká lápá ọ̀tún àti lápá òsì: a ó sì tún máa gbé inú Jerusalẹmu ní ipò rẹ̀.

7Olúwa pẹ̀lú yóò kọ́ tètè gba àgọ́ Juda là ná, kí ògo ilé Dafidi àti ògo àwọn ara Jerusalẹmu má ba gbé ara wọn ga sí Juda. 8Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò dáàbò bò àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu; ẹni tí ó bá sì ṣe àìlera nínú wọn ní ọjọ́ náà, yóò dàbí Dafidi; ilé Dafidi yóò sì dàbí Ọlọ́run, bí angẹli Olúwa níwájú wọn. 9Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, èmi yóò wá láti pa gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè run tí ó wá kọjú ìjà sí Jerusalẹmu.”

Ìṣọ̀fọ̀ fún ọba wọn tí wọn gún lọ́kọ̀

1012.10: Jh 19.37.“Èmi ó sì tu ẹ̀mí oore-ọ̀fẹ́ àti ẹ̀bẹ̀ sórí ilé Dafidi àti sórí Jerusalẹmu: wọn ó sì máa wo ẹni tí wọn tí gún ni ọ̀kọ̀, wọn ó sì máa ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, bí ẹnìkan ti ń ṣọ̀fọ̀ fún ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo àti gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí wọn yóò sì wà ni ìbànújẹ́, bí ẹni tí ń banújẹ́ fún àkọ́bí rẹ̀. 11Ní ọjọ́ náà ni ẹkún, ńláńlá yóò wà ni Jerusalẹmu, gẹ́gẹ́ bí ọ̀fọ̀ Hadadi Rimoni ni Àfonífojì Megido. 12Ilẹ̀ náà yóò ṣọ̀fọ̀, ìdílé, kọ̀ọ̀kan fun ara rẹ, lọ́tọ̀ọ̀tọ̀; ìdílé Dafidi lọ́tọ̀; àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀; ìdílé Natani lọ́tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ́. 13Ìdílé Lefi lọ́tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀; ìdílé Ṣimei lọ́tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀. 14Gbogbo àwọn ìdílé tí o kù, ìdílé, ìdílé, lọ́tọ̀ọ̀tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀ọ̀tọ̀.

Swedish Contemporary Bible

Sakarja 12:1-14

Messias ankomst och mottagande

(12:1—14:21)

Jerusalems fiender förgörs

1En profetia: Herrens ord om Israel. Herren, som har spänt ut himlen, lagt jordens grund och format människans livsande, säger: 2”Jag ska göra Jerusalem till en berusande bägare för alla grannfolk. Också Juda ska belägras, liksom Jerusalem. 3På den tiden ska jag göra Jerusalem till en tung sten för alla folk. Var och en som lyfter den ska göra sig illa. Alla folk på jorden ska samla sig mot den. 4På den dagen, säger Herren, ska jag slå varje häst med panik och deras ryttare med vanvett. Men mina ögon ska vaka över Juda folk, medan jag slår alla folkens hästar med blindhet. 5Då ska ledarna i Juda tänka: ’Jerusalems invånare har sin styrka i härskarornas Herre, sin Gud.’

6På den dagen ska jag göra ledarna i Juda till ett brinnande fyrfat bland ved, en brinnande fackla bland sädeskärvar. De ska förtära alla folk i alla riktningar runt omkring, men Jerusalems befolkning ska förbli i Jerusalem.

7Herren ska först rädda boningarna i Juda, så att inte Davids ätt och Jerusalems invånare äras mer än Juda. 8På den dagen ska Herren beskydda Jerusalems invånare. Den svagaste bland dem ska på den dagen bli lik David, och Davids ätt ska vara som Gud, som en Herrens ängel framför dem. 9På den dagen tänker jag förgöra alla folk som kommer mot Jerusalem.

Klagan över Den genomborrade

10Över Davids ätt och över Jerusalems invånare ska jag utgjuta en nådens och bönens ande12:10 Eller: Ande. De ska se upp till mig som de har genomborrat, sörja honom som man sörjer den ende sonen och gråta bittert som man gråter över den förstfödde. 11Den dagen ska sorgen i Jerusalem bli lika stor som sorgen över Hadad-Rimmon på Megiddoslätten. 12Landet ska sörja, släkt för släkt: Davids släkt för sig och dess kvinnor för sig, Natans släkt för sig och dess kvinnor för sig, 13Levis släkt för sig och dess kvinnor för sig, Shimis släkt för sig och dess kvinnor för sig, 14alla de övriga släkterna var för sig och deras kvinnor för sig.