Sekariah 11 – YCB & NSP

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sekariah 11:1-17

1Ṣí àwọn ìlẹ̀kùn rẹ sílẹ̀, ìwọ Lebanoni,

kí iná bá lè jẹ igi kedari rẹ run,

2Hu, igi junifa; nítorí igi kedari ṣubú,

nítorí tí a ba àwọn igi tí o lógo jẹ́:

hu, ẹ̀yin igi óákù tí Baṣani,

nítorí gé igbó àjàrà lulẹ̀.

3Gbọ́ ohun igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn;

ògo wọn bàjẹ́;

gbọ́ ohùn bíbú àwọn ọmọ kìnnìún

nítorí ògo Jordani bàjẹ́.

Olùṣọ́-àgùntàn méjì

4Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run mi wí: “Bọ́ ọ̀wọ́ ẹran àbọ́pa. 5Tí àwọn olúwa wọn ń pa wọ́n, tí wọn kò sì ka ara wọn sí pé wọn jẹ̀bi: àti àwọn tí ń tà wọ́n wí pé, ‘Ìbùkún ni fún Olúwa, nítorí tí mo dí ọlọ́rọ̀!’ Àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn kò sì ṣàánú wọn. 6Nítorí èmi kì yóò ṣàánú fún àwọn ara ilẹ̀ náà mọ́,” ni Olúwa wí, “Ṣí kíyèsi í, èmi yóò fi olúkúlùkù ènìyàn lé aládùúgbò rẹ̀ lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ ọba rẹ̀, wọn yóò sì fọ́ ilẹ̀ náà, èmi kì yóò sì gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn.”

7Èmi yóò sì bọ́ ẹran àbọ́pa, àní ẹ̀yin òtòṣì nínú ọ̀wọ́ ẹran. Mo sì mu ọ̀pá méjì sọ́dọ̀; mo pè ọ̀kan ni Oore-ọ̀fẹ́, mo pè èkejì ni Àmùrè; mo sì bọ́ ọ̀wọ́ ẹran náà. 8Olùṣọ́-àgùntàn mẹ́ta ni mo sì gé kúrò ní oṣù kan.

Ọkàn mi sì kórìíra wọn, ọkàn wọn pẹ̀lú sì kórìíra mi. 9Mo sì wí pé, “Èmi kì yóò bọ́ yin: èyí ti ń ku lọ, jẹ́ kí òkú o kú; èyí tí a o ba sì gé kúrò, jẹ́ kí a gé e kúrò; ki olúkúlùkù nínú àwọn ìyókù jẹ́ ẹran-ara ẹnìkejì rẹ̀.”

10Mo sì mu ọ̀pá mi, ti a ń pè ní Oore-ọ̀fẹ́, mo ṣẹ́ si méjì, ki èmi bá lè da májẹ̀mú mi tí mo tí bá gbogbo àwọn ènìyàn náà dá. 11Ó sì dá ni ọjọ́ náà, bẹ́ẹ̀ ni àwọn òtòṣì nínú ọ̀wọ́ ẹran náà tí ó dúró tì mí mọ̀ pé, ọ̀rọ̀ Olúwa ni.

1211.12-13: Mt 26.15; 27.9.Mo sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá dára ní ojú yin, ẹ fún mi ni owó ọ̀yà mi; bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ mú un lọ́wọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọn ọgbọ̀n owó fàdákà fún iye owó ọ̀yà mi.

13Olúwa sì wí fún mi pé, “Sọ ọ sí amọ̀kòkò.” Iye dáradára náà, tí wọn yọ owó mi sí. Mo sì mu ọgbọ̀n owó fàdákà náà, mo sì sọ wọ́n sí àpótí ìṣúra ní ilé Olúwa.

14Mo sì ṣẹ́ ọ̀pá mi kejì, àní Àmùrè, sí méjì, kí èmi lè ya ìbátan tí ó wà láàrín Juda àti láàrín Israẹli.

15Olúwa sì wí fún mi pé, “Tún mú ohun èlò aṣiwèrè olùṣọ́-àgùntàn kan sọ́dọ̀ rẹ̀. 16Nítorí Èmi o gbé olùṣọ́-àgùntàn kan dìde ni ilẹ̀ náà, tí kí yóò bẹ àwọn tí ó ṣègbé wò, ti kì yóò sì wá èyí tí ó yapa; tí kì yóò ṣe ìtọ́jú èyí tí a pa lára tàbí kí ó bọ́ àwọn tí ara wọn dá pépé: Ṣùgbọ́n òun yóò jẹ ẹran èyí tí ó ni ọ̀rá, àwọn èyí tiwọn fi èékánná wọn ya ara wọn pẹ́rẹpẹ̀rẹ.

17“Ègbé ni fún olùṣọ́-àgùntàn asán náà,

tí ó fi ọ̀wọ́ ẹran sílẹ̀!

Idà yóò gé apá rẹ̀ àti ojú ọ̀tún rẹ̀:

apá rẹ̀ yóò gbẹ pátápátá,

ojú ọ̀tún rẹ̀ yóò sì fọ́ pátápátá!”

New Serbian Translation

Књига пророка Захарије 11:1-17

1О, Ливане, врата своја отвори

да прождере огањ твоје кедре!

2Јадикуј, чемпресу, јер је пао кедар.

Та су моћна стабла уништена.

Јадикујте, храстови Васана,

јер је оборена густа шума.

3Ево јаука пастирског ридања

јер је ојађен њихов сјај.

Ево јеке рикања лавића

јер су опустошени јордански честари.

Два пастира

4Овако каже Господ, мој Бог: „Напасај стадо које је за клање. 5Купци њихови их кољу и не мисле да су криви. А они који их продају говоре: ’Благословен Господ! Обогатио сам се.’ Њихови пастири су немилосрдни према њима. 6Зато ни ја више нећу да се смилујем на становнике земље – говори Господ. Ево, предајем свакога у руке његовог ближњег и у руке његовог цара. Они ће сатрти земљу, а ја нећу да их избавим из њихових руку.“

7И ја сам напасао стадо за клање, баш оне најнезнатније у стаду. Узео сам два штапа. Један сам назвао „Благост“, а други сам назвао „Слога“, па сам напасао стадо. 8Онда сам за месец дана збрисао три пастира јер су ми се смучили, а и ја сам њима огадио. 9Онда сам рекао: „Нећу више да вас напасам! Нека скапа овца која је за смрт и нека пропадне која је за пропаст. А оне којe преживе нека глођу једна другу.“

10Елем, узео сам „Благост“, свој штап, и преломио га. Тако сам раскинуо свој савез који сам склопио са свим народима. 11Тог дана је био сломљен, па су и најнезнатнији у стаду, они што су у мене гледали, знали да је ова реч била од Господа.

12Рекао сам им: „Ако је право у вашим очима ви ми дајте моју надницу. А ако није, не дајте ми.“ Онда су ми одмерили надницу од тридесет сребрњака.

13Господ ми је рекао: „Баци грнчару ту силну вредност којом су ме проценили!“ И ја сам узео од њих тридесет сребрњака и бацио их грнчару Дома Господњег.

14Затим сам преломио „Слогу“, свој други штап, и тако прекинуо братство између Јуде и Израиља.

15Господ ми је казао: „Поново узми опрему безумног пастира. 16Јер, ево, подижем у земљи пастира који неће марити за оне што скапавају, неће тражити залутале, неће лечити рањене, неће водити врлудаве. Он ће јести месо угојених оваца и кидаће им папке.

17Јао безумном пастиру

који напушта стадо!

Мач му је над руком и над десним оком.

Рука му се сасвим осушила,

десно му се око сасвим замутило!“