Sekariah 11 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sekariah 11:1-17

1Ṣí àwọn ìlẹ̀kùn rẹ sílẹ̀, ìwọ Lebanoni,

kí iná bá lè jẹ igi kedari rẹ run,

2Hu, igi junifa; nítorí igi kedari ṣubú,

nítorí tí a ba àwọn igi tí o lógo jẹ́:

hu, ẹ̀yin igi óákù tí Baṣani,

nítorí gé igbó àjàrà lulẹ̀.

3Gbọ́ ohun igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn;

ògo wọn bàjẹ́;

gbọ́ ohùn bíbú àwọn ọmọ kìnnìún

nítorí ògo Jordani bàjẹ́.

Olùṣọ́-àgùntàn méjì

4Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run mi wí: “Bọ́ ọ̀wọ́ ẹran àbọ́pa. 5Tí àwọn olúwa wọn ń pa wọ́n, tí wọn kò sì ka ara wọn sí pé wọn jẹ̀bi: àti àwọn tí ń tà wọ́n wí pé, ‘Ìbùkún ni fún Olúwa, nítorí tí mo dí ọlọ́rọ̀!’ Àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn kò sì ṣàánú wọn. 6Nítorí èmi kì yóò ṣàánú fún àwọn ara ilẹ̀ náà mọ́,” ni Olúwa wí, “Ṣí kíyèsi í, èmi yóò fi olúkúlùkù ènìyàn lé aládùúgbò rẹ̀ lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ ọba rẹ̀, wọn yóò sì fọ́ ilẹ̀ náà, èmi kì yóò sì gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn.”

7Èmi yóò sì bọ́ ẹran àbọ́pa, àní ẹ̀yin òtòṣì nínú ọ̀wọ́ ẹran. Mo sì mu ọ̀pá méjì sọ́dọ̀; mo pè ọ̀kan ni Oore-ọ̀fẹ́, mo pè èkejì ni Àmùrè; mo sì bọ́ ọ̀wọ́ ẹran náà. 8Olùṣọ́-àgùntàn mẹ́ta ni mo sì gé kúrò ní oṣù kan.

Ọkàn mi sì kórìíra wọn, ọkàn wọn pẹ̀lú sì kórìíra mi. 9Mo sì wí pé, “Èmi kì yóò bọ́ yin: èyí ti ń ku lọ, jẹ́ kí òkú o kú; èyí tí a o ba sì gé kúrò, jẹ́ kí a gé e kúrò; ki olúkúlùkù nínú àwọn ìyókù jẹ́ ẹran-ara ẹnìkejì rẹ̀.”

10Mo sì mu ọ̀pá mi, ti a ń pè ní Oore-ọ̀fẹ́, mo ṣẹ́ si méjì, ki èmi bá lè da májẹ̀mú mi tí mo tí bá gbogbo àwọn ènìyàn náà dá. 11Ó sì dá ni ọjọ́ náà, bẹ́ẹ̀ ni àwọn òtòṣì nínú ọ̀wọ́ ẹran náà tí ó dúró tì mí mọ̀ pé, ọ̀rọ̀ Olúwa ni.

1211.12-13: Mt 26.15; 27.9.Mo sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá dára ní ojú yin, ẹ fún mi ni owó ọ̀yà mi; bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ mú un lọ́wọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọn ọgbọ̀n owó fàdákà fún iye owó ọ̀yà mi.

13Olúwa sì wí fún mi pé, “Sọ ọ sí amọ̀kòkò.” Iye dáradára náà, tí wọn yọ owó mi sí. Mo sì mu ọgbọ̀n owó fàdákà náà, mo sì sọ wọ́n sí àpótí ìṣúra ní ilé Olúwa.

14Mo sì ṣẹ́ ọ̀pá mi kejì, àní Àmùrè, sí méjì, kí èmi lè ya ìbátan tí ó wà láàrín Juda àti láàrín Israẹli.

15Olúwa sì wí fún mi pé, “Tún mú ohun èlò aṣiwèrè olùṣọ́-àgùntàn kan sọ́dọ̀ rẹ̀. 16Nítorí Èmi o gbé olùṣọ́-àgùntàn kan dìde ni ilẹ̀ náà, tí kí yóò bẹ àwọn tí ó ṣègbé wò, ti kì yóò sì wá èyí tí ó yapa; tí kì yóò ṣe ìtọ́jú èyí tí a pa lára tàbí kí ó bọ́ àwọn tí ara wọn dá pépé: Ṣùgbọ́n òun yóò jẹ ẹran èyí tí ó ni ọ̀rá, àwọn èyí tiwọn fi èékánná wọn ya ara wọn pẹ́rẹpẹ̀rẹ.

17“Ègbé ni fún olùṣọ́-àgùntàn asán náà,

tí ó fi ọ̀wọ́ ẹran sílẹ̀!

Idà yóò gé apá rẹ̀ àti ojú ọ̀tún rẹ̀:

apá rẹ̀ yóò gbẹ pátápátá,

ojú ọ̀tún rẹ̀ yóò sì fọ́ pátápátá!”

New International Version

Zechariah 11:1-17

1Open your doors, Lebanon,

so that fire may devour your cedars!

2Wail, you juniper, for the cedar has fallen;

the stately trees are ruined!

Wail, oaks of Bashan;

the dense forest has been cut down!

3Listen to the wail of the shepherds;

their rich pastures are destroyed!

Listen to the roar of the lions;

the lush thicket of the Jordan is ruined!

Two Shepherds

4This is what the Lord my God says: “Shepherd the flock marked for slaughter. 5Their buyers slaughter them and go unpunished. Those who sell them say, ‘Praise the Lord, I am rich!’ Their own shepherds do not spare them. 6For I will no longer have pity on the people of the land,” declares the Lord. “I will give everyone into the hands of their neighbors and their king. They will devastate the land, and I will not rescue anyone from their hands.”

7So I shepherded the flock marked for slaughter, particularly the oppressed of the flock. Then I took two staffs and called one Favor and the other Union, and I shepherded the flock. 8In one month I got rid of the three shepherds.

The flock detested me, and I grew weary of them 9and said, “I will not be your shepherd. Let the dying die, and the perishing perish. Let those who are left eat one another’s flesh.”

10Then I took my staff called Favor and broke it, revoking the covenant I had made with all the nations. 11It was revoked on that day, and so the oppressed of the flock who were watching me knew it was the word of the Lord.

12I told them, “If you think it best, give me my pay; but if not, keep it.” So they paid me thirty pieces of silver.

13And the Lord said to me, “Throw it to the potter”—the handsome price at which they valued me! So I took the thirty pieces of silver and threw them to the potter at the house of the Lord.

14Then I broke my second staff called Union, breaking the family bond between Judah and Israel.

15Then the Lord said to me, “Take again the equipment of a foolish shepherd. 16For I am going to raise up a shepherd over the land who will not care for the lost, or seek the young, or heal the injured, or feed the healthy, but will eat the meat of the choice sheep, tearing off their hooves.

17“Woe to the worthless shepherd,

who deserts the flock!

May the sword strike his arm and his right eye!

May his arm be completely withered,

his right eye totally blinded!”