Sekariah 10 – YCB & HTB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sekariah 10:1-12

Olúwa yóò gba Juda

1Ẹ béèrè òjò nígbà àrọ̀kúrò ni ọwọ́ Olúwa;

Olúwa tí o dá mọ̀nàmọ́ná,

tí ó sì fi ọ̀pọ̀ òjò fún ènìyàn,

fún olúkúlùkù koríko ní pápá.

2Nítorí àwọn òrìṣà tí sọ̀rọ̀ asán,

àwọn aláfọ̀ṣẹ sì tí rí èké,

wọn sì tí rọ àlá èké;

wọ́n ń tu ni nínú lásán,

nítorí náà àwọn ènìyàn náà ṣáko lọ bí àgùntàn,

a ṣẹ wọn níṣẹ̀ẹ́, nítorí Olùṣọ́-àgùntàn kò sí.

3“Ìbínú mi ru sí àwọn darandaran,

èmi o sì jẹ àwọn olórí ní yà

nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti bẹ agbo rẹ̀,

ilé Juda wò,

yóò sì fi wọn ṣe ẹṣin rẹ̀ dáradára ní ogun.

4Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni òkúta igun ilé ti jáde wá,

láti ọ̀dọ̀ rẹ ni èèkàn àgọ́ tí wá,

láti ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrún ogun tí wá,

láti ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn akóniṣiṣẹ́ gbogbo tí wá.

5Gbogbo wọn yóò sì dàbí ọkùnrin

alágbára ni ogun tí ń tẹ àwọn ọ̀tá wọn mọ́lẹ̀ ní ìgboro, wọn ó sì jagun,

nítorí Olúwa wà pẹ̀lú wọn,

wọn ó sì dààmú àwọn tí ń gun ẹṣin.

6“Èmi o sì mú ilé Juda ní agbára,

èmi o sì gba ilé Josẹfu là,

èmi ó sì tún mú wọn padà

nítorí mo tí ṣàánú fún wọn,

ó sì dàbí ẹni pé èmi kò ì tì í ta wọ́n nù;

nítorí èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn,

èmi o sì gbọ́ tiwọn

7Efraimu yóò sì ṣe bí alágbára,

ọkàn wọn yóò sì yọ̀ bi ẹni pé nípa ọtí wáìnì:

àní àwọn ọmọ wọn yóò rí í,

wọn o sì yọ̀, inú wọn ó sì dùn nínú Olúwa.

8Èmi ó kọ sí wọn, èmi ó sì ṣà wọ́n jọ;

nítorí èmi tí rà wọ́n padà;

wọn ó sì pọ̀ sí i gẹ́gẹ́ bí

wọ́n tí ń pọ̀ sí í rí.

9Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo tú wọn káàkiri orílẹ̀-èdè:

síbẹ̀ wọn ó sì rántí mi ni ilẹ̀ jíjìn;

wọn ó sì gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn,

wọn ó sì tún padà.

10Èmi ó sì tún mú wọn padà kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti

pẹ̀lú, èmi ó sì ṣà wọn jọ kúrò ni ilẹ̀ Asiria:

èmi ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ Gileadi àti Lebanoni; a

a kì yóò sì rí ààyè fún wọn bí ó ti yẹ.

11Wọn yóò sì la Òkun wàhálà já,

yóò sì bori rírú omi nínú Òkun,

gbogbo ibú odò ni yóò sì gbẹ,

a ó sì rẹ ìgbéraga Asiria sílẹ̀,

ọ̀pá aládé Ejibiti yóò sí lọ kúrò.

12Èmi ó sì mú wọn ní agbára nínú Olúwa;

wọn ó sì rìn sókè rìn sódò ni orúkọ rẹ̀,”

ni Olúwa wí.

Het Boek

Zacharia 10:1-12

God zorgt voor zijn volk

1Vraag de Here om regen in het voorjaar en Hij zal antwoorden met onweer en stortbuien. Op ieders veld zullen de gewassen goed groeien. 2Wat is het dom zoiets aan een afgodsbeeld te vragen! De voorspellingen van waarzeggers zijn leugens. Zij doen aan misleidende droomuitleg en bieden geen enkele troost. Juda en Israël dwalen als schapen die de weg kwijt zijn, omdat een herder ontbreekt.

3‘Ik ben toornig geworden op die zogenaamde herders, die leiders van u, en Ik zal hen straffen, die bokken. Want Ik, de Here van de hemelse legers, ben gekomen om mijn kudde Juda te helpen. Ik zal haar sterk en onbevreesd maken als een prachtig oorlogspaard. 4Uit haar zal de hoeksteen voortkomen, de tentpin, de oorlogsboog, uit dit volk komen alle overwinnaars voort. 5Zij zullen dappere strijders voor God zijn en hun vijanden onder hun voeten vertrappen als modder op straat. De Here helpt hen in de strijd, de vijandelijke ruiters zijn gedoemd te sterven.

6Het volk van Juda zal Ik sterk maken, de nakomelingen van Jozef zal Ik bevrijden. Ik zal hen weer thuisbrengen, omdat Ik hen liefheb. Het zal zijn alsof Ik ze nooit heb verworpen. Want Ik ben de Here, hun God, en Ik zal hun hulpgeroep horen. 7Zij zullen op dappere helden lijken. Zij zullen zó uitgelaten van blijdschap zijn dat het net is of zij wijn hebben gedronken! Ook hun kinderen zullen Gods zegeningen zien en blij zijn. Zij zullen juichen in de Here. 8Als Ik fluit, zullen zij komen aanrennen, want Ik heb hen gered. En zij zullen weer even talrijk worden als vroeger. 9Al heb Ik hen als zaad uitgestrooid onder vreemde volken, ook in die verre streken zullen zij aan Mij denken en met al hun kinderen zullen zij weer terugkomen naar Israël. 10Ja, Ik zal hen terughalen uit Egypte en Assyrië en zij zullen zich opnieuw vestigen in Israël, in het gebied Gilead en de Libanon. Er zal nauwelijks plaats genoeg zijn voor iedereen! 11Zij zullen veilig door een zee van problemen trekken, want de golven zullen worden tegengehouden. De Nijl zal droogvallen, aan het bewind van Assyrië en Egypte over mijn volk zal een einde komen. 12Ik zal mijn volk sterk maken met mijn kracht. Het zal gaan waar het maar wil, en waar het ook gaat, zal Ik persoonlijk voor mijn volk zorgen,’ belooft de Here.