Sekariah 1 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sekariah 1:1-21

Ìpè láti padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run

1Ní oṣù kẹjọ ọdún kejì ọba Dariusi, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah ọmọ Berekiah, ọmọ Iddo pé:

2Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín. 3Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn: Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí Ọ̀dọ̀ mi,’ Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. 4Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé: Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí. 5Àwọn baba yín, níbo ni wọ́n wà? Àti àwọn wòlíì, wọ́n ha wà títí ayé? 6Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi àti ìlànà mi, ti mo pa ní àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, kò ha tún bá àwọn baba yín?

“Wọ́n sì padà wọ́n wí pé, ‘Gẹ́gẹ́ bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rò láti ṣe sí wa, gẹ́gẹ́ bi ọ̀nà wa, àti gẹ́gẹ́ bí ìṣe wa, bẹ́ẹ̀ ní o ti ṣe sí wa.’ ”

Ènìyàn láàrín àwọn igi miritili

7Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kọkànlá, tí ó jẹ́, oṣù Sebati, ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah, ọmọ Bẹrẹkiah ọmọ Iddo wá, pé.

8Mo rí ìran kan ni òru, si wò ó, ọkùnrin kan ń gun ẹṣin pupa kan, òun sì dúró láàrín àwọn igi maritili tí ó wà ní ibi òòji; lẹ́yìn rẹ̀ sì ni ẹṣin pupa, adíkálà, àti funfun gbé wà.

9Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni wọ̀nyí olúwa mi?”

Angẹli tí ń ba mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Èmi ó fi ohun tí àwọn wọ̀nyí jẹ́ hàn ọ́.”

10Ọkùnrin tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili sì dáhùn ó sì wí pé, “Wọ̀nyí ní àwọn tí Olúwa ti rán láti máa rìn sókè sódò ni ayé.”

11Wọ́n si dá angẹli Olúwa tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili náà lóhùn pé, “Àwa ti rìn sókè sódò já ayé, àwa sí ti rí i pé gbogbo ayé wà ní ìsinmi àti àlàáfíà.”

12Nígbà náà ni angẹli Olúwa náà dáhùn ó sì wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ kì yóò fi ṣàánú fún Jerusalẹmu, àti fún àwọn ìlú ńlá Juda, ti ìwọ ti bínú sí ni àádọ́rin ọdún wọ̀nyí?” 13Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ rere àti ọ̀rọ̀ ìtùnú dá angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ lóhùn.

14Angẹli ti ń bá mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Ìwọ kígbe wí pé: Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Èmi ń fi ìjowú ńlá jowú fún Jerusalẹmu àti fún Sioni. 15Èmi sì bínú púpọ̀púpọ̀ si àwọn orílẹ̀-èdè tí ó rò wí pé òun ní ààbò. Nítorí nígbà tí mo bínú díẹ̀, wọ́n ran ìparun lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú.’

16“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: ‘Mo padà tọ Jerusalẹmu wá pẹ̀lú àánú; ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, a ó kọ́ ilé mi sínú rẹ̀, a o sí ta okùn ìwọ̀n kan jáde sórí Jerusalẹmu.’

17“Máa ké síbẹ̀ pé: Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘A o máa fi ìre kún ìlú ńlá mi síbẹ̀; Olúwa yóò sì máa tu Sioni nínú síbẹ̀, yóò sì yan Jerusalẹmu síbẹ̀.’ ”

Ìwo mẹ́rin àti alágbẹ̀dẹ mẹ́rin

18Mo si gbé ojú sókè, mo sì rí, sì kíyèsi i, ìwo mẹ́rin. 19Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?”

Ó si dà mí lóhùn pé, “Àwọn ìwo wọ̀nyí ni ó tí tú Juda, Israẹli, àti Jerusalẹmu ká.”

20Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí. 21Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?”

O sì sọ wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìwo tí ó ti tú Juda ká, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò fi gbé orí rẹ̀ sókè? Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí wá láti dẹ́rùbà wọ́n, láti lé ìwo àwọn orílẹ̀-èdè jáde, ti wọ́n gbé ìwo wọn sórí ilẹ̀ Juda láti tú ènìyàn rẹ̀ ká.”

Swedish Contemporary Bible

Sakarja 1:1-21

Uppdraget att återuppbygga templet

(1:1—8:23)

Vänd tillbaka till Herren

1I åttonde månaden av kung Dareios andra regeringsår1:1 I oktober-november 520 f.Kr. kom Herrens ord till profeten Sakarja, Berekjas son och Iddos sonson:

2Herren var mycket vred på era förfäder. 3Tala därför till folket: Så säger härskarornas Herre: ’Vänd om till mig, säger härskarornas Herre, så ska jag vända mig till er, säger härskarornas Herre.’ 4Var inte som era förfäder! För dem predikade de tidigare profeterna: Så säger härskarornas Herre: ’Vänd om från era onda vägar och era onda gärningar.’ Men de lyssnade inte och brydde sig inte om mig, säger Herren. 5Var är era förfäder nu? Och profeterna? Lever de för evigt? 6Mina ord och mina förordningar, som jag gett befallning om genom mina tjänare profeterna, nådde ju era förfäder. Då vände de om och sa:

’Så som härskarornas Herre har beslutat att göra med oss, i enlighet med vad våra levnadssätt och våra gärningar har förtjänat, så har han också handlat med oss.’ ”

Mannen bland myrtenträden

7Den tjugofjärde dagen i elfte månaden, i månaden shevat, av Dareios andra regeringsår,1:7 Den 15 febr. 519 f.Kr. kom Herrens ord till profeten Sakarja, son till Berekja och sonson till Iddo:

8Jag såg en syn om natten, och där var en man som red på en röd häst. Han stod bland myrtenträden i ravinen. Bakom honom stod röda, bruna1:8 Det hebreiska ordets betydelse är osäker. och vita hästar.

9Jag frågade: ”Vad är dessa för något, herre?”

Ängeln som talade med mig svarade: ”Det ska jag visa dig.”

10Mannen som stod bland myrtenträden sa: ”Herren har sänt dem för att färdas över jorden.”

11De sa då till Herrens ängel som stod bland myrtenträden: ”Vi har färdats över hela jorden, och där är det lugnt och stilla.”

12Då svarade Herrens ängel: ”Härskarornas Herre, hur länge ska du dröja med att förbarma dig över Jerusalem och Juda städer? Du har nu varit förbittrad på dem i sjuttio år.” 13Herren gav ängeln som talade med mig ett svar med goda och tröstande ord.

14Då sa ängeln som talade med mig: ”Ropa ut: Så säger härskarornas Herre: ’Min lidelse är stark för Jerusalem och för Sion. 15Men jag är mycket vred på de självsäkra folken, för medan min vrede ännu inte var så stor, gjorde de det onda ännu värre.’

16Därför säger Herren: ’Jag har vänt tillbaka till Jerusalem i barmhärtighet. Mitt tempel ska byggas där, säger härskarornas Herre, mätsnöret ska dras över Jerusalem.’

17Ropa igen: Så säger härskarornas Herre: ’Mina städer ska åter flöda över av det goda. Herren ska åter trösta Sion och åter utvälja Jerusalem.’ ”

Fyra horn och fyra smeder

18Jag lyfte blicken och fick se fyra horn1:18 Horn står för styrka och övermod.. 19Jag frågade ängeln som talade med mig: ”Vad är dessa för något?”

Han svarade: ”De är de horn som har skingrat Juda, Israel och Jerusalem.”

20Sedan visade Herren mig fyra smeder. 21Jag frågade: ”Vad har dessa kommit för att göra?” Han svarade: ”Där är de horn som skingrade Juda så att ingen orkade lyfta sitt huvud. Men nu har dessa kommit för att sätta skräck i dem och slå av hornen på de folk som lyfte sina horn mot Juda land och skingrade dem.”