Sekariah 1 – YCB & NSP

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sekariah 1:1-21

Ìpè láti padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run

1Ní oṣù kẹjọ ọdún kejì ọba Dariusi, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah ọmọ Berekiah, ọmọ Iddo pé:

2Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín. 3Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn: Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí Ọ̀dọ̀ mi,’ Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. 4Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé: Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí. 5Àwọn baba yín, níbo ni wọ́n wà? Àti àwọn wòlíì, wọ́n ha wà títí ayé? 6Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi àti ìlànà mi, ti mo pa ní àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, kò ha tún bá àwọn baba yín?

“Wọ́n sì padà wọ́n wí pé, ‘Gẹ́gẹ́ bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rò láti ṣe sí wa, gẹ́gẹ́ bi ọ̀nà wa, àti gẹ́gẹ́ bí ìṣe wa, bẹ́ẹ̀ ní o ti ṣe sí wa.’ ”

Ènìyàn láàrín àwọn igi miritili

7Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kọkànlá, tí ó jẹ́, oṣù Sebati, ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah, ọmọ Bẹrẹkiah ọmọ Iddo wá, pé.

8Mo rí ìran kan ni òru, si wò ó, ọkùnrin kan ń gun ẹṣin pupa kan, òun sì dúró láàrín àwọn igi maritili tí ó wà ní ibi òòji; lẹ́yìn rẹ̀ sì ni ẹṣin pupa, adíkálà, àti funfun gbé wà.

9Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni wọ̀nyí olúwa mi?”

Angẹli tí ń ba mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Èmi ó fi ohun tí àwọn wọ̀nyí jẹ́ hàn ọ́.”

10Ọkùnrin tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili sì dáhùn ó sì wí pé, “Wọ̀nyí ní àwọn tí Olúwa ti rán láti máa rìn sókè sódò ni ayé.”

11Wọ́n si dá angẹli Olúwa tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili náà lóhùn pé, “Àwa ti rìn sókè sódò já ayé, àwa sí ti rí i pé gbogbo ayé wà ní ìsinmi àti àlàáfíà.”

12Nígbà náà ni angẹli Olúwa náà dáhùn ó sì wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ kì yóò fi ṣàánú fún Jerusalẹmu, àti fún àwọn ìlú ńlá Juda, ti ìwọ ti bínú sí ni àádọ́rin ọdún wọ̀nyí?” 13Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ rere àti ọ̀rọ̀ ìtùnú dá angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ lóhùn.

14Angẹli ti ń bá mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Ìwọ kígbe wí pé: Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Èmi ń fi ìjowú ńlá jowú fún Jerusalẹmu àti fún Sioni. 15Èmi sì bínú púpọ̀púpọ̀ si àwọn orílẹ̀-èdè tí ó rò wí pé òun ní ààbò. Nítorí nígbà tí mo bínú díẹ̀, wọ́n ran ìparun lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú.’

16“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: ‘Mo padà tọ Jerusalẹmu wá pẹ̀lú àánú; ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, a ó kọ́ ilé mi sínú rẹ̀, a o sí ta okùn ìwọ̀n kan jáde sórí Jerusalẹmu.’

17“Máa ké síbẹ̀ pé: Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘A o máa fi ìre kún ìlú ńlá mi síbẹ̀; Olúwa yóò sì máa tu Sioni nínú síbẹ̀, yóò sì yan Jerusalẹmu síbẹ̀.’ ”

Ìwo mẹ́rin àti alágbẹ̀dẹ mẹ́rin

18Mo si gbé ojú sókè, mo sì rí, sì kíyèsi i, ìwo mẹ́rin. 19Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?”

Ó si dà mí lóhùn pé, “Àwọn ìwo wọ̀nyí ni ó tí tú Juda, Israẹli, àti Jerusalẹmu ká.”

20Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí. 21Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?”

O sì sọ wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìwo tí ó ti tú Juda ká, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò fi gbé orí rẹ̀ sókè? Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí wá láti dẹ́rùbà wọ́n, láti lé ìwo àwọn orílẹ̀-èdè jáde, ti wọ́n gbé ìwo wọn sórí ilẹ̀ Juda láti tú ènìyàn rẹ̀ ká.”

New Serbian Translation

Књига пророка Захарије 1:1-21

Позив на повратак Господу

1Осмог месеца друге Даријеве године, реч Господња је дошла пророку Захарији, Варахијином сину и Идовом унуку.

2„Господ се веома разгневио на ваше претке! 3Реци им зато: овако каже Господ над војскама: ’Вратите ми се, говори Господ над војскама, и ја ћу се вратити вама – каже Господ над војскама. 4Не будите као ваши преци којима су пророковали пређашњи пророци речима: овако каже Господ над војскама: одвратите се, молим вас, од својих злих путева и својих злих дела. Али нису послушали, нису марили за мене – говори Господ. 5И где су сада ваши преци? Довека ли живе пророци? 6Зар нису стигле ваше претке моје речи и моји закони, које сам заповедио својим слугама пророцима?

И они су се покајали и одговорили: учинио је баш како је и намеравао Господ над војскама да нам узврати према нашим путевима и према нашим делима.’“

Човек међу стаблима мирте

7Двадесет четвртог дана једанаестог месеца, а то је месец сават, друге Даријеве године, дошла је реч Господња пророку Захарији, Варахијином сину и Идовом унуку:

8Гле, била је ноћ када сам видео човека како седи на коњу риђану. Стајао је међу стаблима мирте, тамо у долу, а иза њега коњи риђани, сивци и белци.

9Рекао сам: „Господару мој, ко су ови?“

Одговорио ми је анђео који је разговарао са мном: „Показаћу ти ко су ови.“

10Тада је узвратио човек који је стајао међу стаблима мирте. Рекао је: „Ово су они које је Господ послао да обилазе земљу.“

11А они су казали Анђелу Господњем који је стајао међу стаблима мирте: „Обишли смо земљу. Ево, сва је земља мирна и спокојна.“

12Анђео Господњи је одговорио: „О, Господе над војскама, зар се нећеш смиловати Јерусалиму и Јудиним градовима на које си, ево, озлојеђен ових седамдесет година?!“ 13А Господ је анђелу који је разговарао са мном одговорио благонаклоним речима, утешним речима.

14Анђео који је разговарао са мном ми је казао: „Објављуј! Реци: ’Овако каже Господ над војскама: стало ми је до Јерусалима и до Сиона ми је веома стало. 15Страховито сам гневан на лакомислене народе, а на њих сам био тек мало гневан. Али они су зло потпомогли.’

16Зато овако каже Господ: ’Вратићу се Јерусалиму са смиловањем! Обновиће се у њему мој Дом – говори Господ над војскама. Зидарско уже ће развучено бити над Јерусалимом.’

17Опет објављуј и реци: ’Овако каже Господ над војскама: моји ће се градови поново преливати благостањем! Господ ће поново да се смилује Сиону, поново ће да одабере Јерусалим!’“

Четири рога и четворица ковача

18Тада сам погледао горе, и гле – четири рога. 19Питао сам анђела који је разговарао са мном: „А шта су они?“

Одговорио ми је: „Ово су рогови који су расејали Јуду, Израиљ и Јерусалим.“

20А Господ ми је показао четворицу ковача. 21Упитао сам: „Шта су они дошли да раде?“

Одговорио ми је речима: „Ово су рогови који су расејали Јуду тако да нико ни главу подигао није. А ови ковачи су дошли да их преплаше, да развале рогове народа који су подигнули рог против Јудине земље, да је расеју.“