Sefaniah 1 – YCB & CCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sefaniah 1:1-18

1Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Sefaniah ọmọ Kuṣi, ọmọ Gedaliah, ọmọ Amariah, ọmọ Hesekiah, ní ìgbà Josiah ọmọ Amoni ọba Juda.

Ìkìlọ̀ fún ìparun tí ń bọ̀

2“Èmi yóò mú gbogbo nǹkan kúrò

lórí ilẹ̀ náà pátápátá,”

ni Olúwa wí.

3“Èmi yóò mú ènìyàn àti ẹranko

kúrò; èmi yóò mú àwọn ẹyẹ ojú

ọ̀run kúrò àti ẹja inú Òkun, àti

ohun ìdìgbòlù pẹ̀lú àwọn

ènìyàn búburú; èmi yóò ké ènìyàn kúrò lórí ilẹ̀ ayé,”

ni Olúwa wí.

Ìlòdì sí Juda

4“Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Juda

àti sórí gbogbo àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu.

Èmi yóò sì ké kúrò níhìn-ín-yìí ìyókù àwọn Baali, àti orúkọ àwọn abọ̀rìṣà

pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà,

5àti àwọn tí ń foríbalẹ̀ lórí òrùlé,

àwọn tí ń sin ogun ọ̀run,

àwọn tó ń foríbalẹ̀, tí wọ́n sì ń fi Olúwa búra,

tí wọ́n sì ń fi Moleki búra.

6Àwọn tí ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa;

Àti àwọn tí kò tí wá Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì béèrè rẹ̀.”

71.7: Hk 2.20; Sk 2.13.Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa Olódùmarè,

nítorí tí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀.

Olúwa ti pèsè ẹbọ kan sílẹ̀,

ó sì ti ya àwọn alápèjẹ rẹ̀ sí mímọ́.

8“Ní ọjọ́ ẹbọ Olúwa,

Èmi yóò bẹ àwọn olórí wò, àti àwọn

ọmọ ọba ọkùnrin,

pẹ̀lú gbogbo

àwọn tí ó wọ àjèjì aṣọ.

9Ní ọjọ́ náà, èmi yóò fi ìyà jẹ

gbogbo àwọn tí ó yẹra láti rìn lórí ìloro ẹnu-ọ̀nà,

tí wọ́n sì kún tẹmpili àwọn ọlọ́run wọn

pẹ̀lú ìwà ipá àti ẹ̀tàn.

10“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí,

“Ohùn ẹkún yóò wà láti ìhà Ibodè ẹja,

híhu láti ìhà kejì wá àti

ariwo ńlá láti òkè kékeré wá.

11Ẹ hu, ẹ̀yin tí ń gbé ní (Maktẹsi) agbègbè ọjà,

gbogbo àwọn oníṣòwò rẹ̀ ni a ó mú kúrò,

gbogbo àwọn ẹni tí ó ń ra fàdákà ni a ó sì parun.

12Ní àkókò wọ̀n-ọn-nì, èmi yóò wá Jerusalẹmu kiri pẹ̀lú fìtílà,

èmi ó sì fi ìyà jẹ àwọn tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn,

tí wọn sì dàbí àwọn ènìyàn tí ó sinmi sínú gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ wọn,

àwọn tí wọn sì ń wí ní ọkàn wọn pé, ‘Olúwa kì yóò ṣe nǹkan kan

tí ó jẹ́ rere tàbí tí ó jẹ́ búburú.’

13Nítorí náà, ọrọ̀ wọn yóò di ìkógun,

àti ilé wọn yóò sì run.

Àwọn yóò sì kọ́ ilé pẹ̀lú, ṣùgbọ́n

wọn kì yóò gbé nínú ilé náà,

wọn yóò gbin ọgbà àjàrà,

ṣùgbọ́n wọn kì yóò mu ọtí

wáìnì láti inú rẹ̀.”

Ọjọ́ ńlá Olúwa

14“Ọjọ́ ńlá Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀,

ó kù sí dẹ̀dẹ̀ ó sì ń yára bọ̀

kánkán. Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ohùn ẹkún

àwọn alágbára ní ọjọ́ Olúwa yóò korò púpọ̀,

15Ọjọ́ náà yóò jẹ́ ọjọ́ ìbínú,

ọjọ́ ìrora àti ìpọ́njú,

ọjọ́ òfò àti idà ọjọ́ ìdahoro

ọjọ́ òkùnkùn àti ìtẹ̀ba,

ọjọ́ kurukuru àti òkùnkùn biribiri,

16ọjọ́ ìpè àti ìpè ogun

sí àwọn ìlú olódi

àti sí àwọn ilé ìṣọ́ gíga.

17“Èmi yóò sì mú ìpọ́njú wá sórí

ènìyàn, wọn yóò sì máa rìn gẹ́gẹ́ bí afọ́jú,

nítorí àwọn ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa.

Ẹ̀jẹ̀ wọn ni a ó sì tú jáde bí eruku

àti ẹran-ara wọn bí ìgbẹ́.

18Bẹ́ẹ̀ ni fàdákà tàbí wúrà wọn

kì yóò sì le gbà wọ́n là

ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.”

Ṣùgbọ́n gbogbo ayé ni a ó fi iná

ìjowú rẹ̀ parun,

nítorí òun yóò fi ìyára fi òpin sí

gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilẹ̀ ayé.

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

西番雅书 1:1-18

1犹大亚们的儿子约西亚执政期间,耶和华对希西迦的玄孙、亚玛利亚的曾孙、基大利的孙子、古示的儿子西番雅说:

耶和华审判的日子

2“我必毁灭地上的一切。

这是耶和华说的。

3我必毁灭人类、兽类、

天上的鸟和海里的鱼。

我必使恶人倒毙,

我必铲除地上的人类。

这是耶和华说的。

4“我必伸手攻击犹大

以及所有住在耶路撒冷的人,

铲除巴力的余迹及拜偶像之祭司的名号。

5我必铲除那些在屋顶祭拜天上万象的人,

铲除敬拜我、凭我起誓又凭米勒公起誓的人,

6铲除离弃我、不寻求我、不求问我的人。”

7要在主耶和华面前肃静,

因为耶和华的日子近了。

耶和华已准备好祭物,

洁净了祂邀请的人。

8耶和华说:“在我献祭的日子,

我必惩罚首领和王子,

以及所有穿外族服装的人。

9到那日,我必惩罚所有跳过门槛1:9 跳过门槛……的人”指祭拜偶像的人,参见撒母耳记上5:5

使主人的家充满暴力和欺诈的人。

10到那日,鱼门必传出哭喊声,

新区必响起哀号声,

山陵必发出崩裂的巨响。

这是耶和华说的。

11市场区的居民啊,哀哭吧!

因为所有的商人必灭亡,

所有做买卖的必被铲除。

12那时,我必提着灯巡查耶路撒冷

惩罚那些安于罪中的人。

他们心想,‘耶和华不赐福也不降祸。’

13他们的财物必遭抢掠,

家园必沦为废墟。

他们建造房屋,却不能住在里面;

栽种葡萄园,却喝不到葡萄酒。

14“耶和华的大日子近了,

近了,很快就到了。

那将是痛苦的日子,

勇士也必凄声哀号。

15那是降烈怒的日子,

是困苦艰难的日子,

是摧残毁坏的日子,

是黑暗幽冥的日子,

是阴霾密布的日子,

16是吹号呐喊、

攻打坚城高垒的日子。

17“我要使人们灾难临头,

以致他们行路像瞎子,

因为他们得罪了我。

他们的血必被倒出,如同灰尘;

他们的尸体必被丢弃,如同粪便。

18在耶和华发怒的日子,

他们的金银救不了他们。

祂的怒火必吞噬大地,

祂必骤然毁灭一切世人。”