Sefaniah 1 – YCB & BPH

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sefaniah 1:1-18

1Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Sefaniah ọmọ Kuṣi, ọmọ Gedaliah, ọmọ Amariah, ọmọ Hesekiah, ní ìgbà Josiah ọmọ Amoni ọba Juda.

Ìkìlọ̀ fún ìparun tí ń bọ̀

2“Èmi yóò mú gbogbo nǹkan kúrò

lórí ilẹ̀ náà pátápátá,”

ni Olúwa wí.

3“Èmi yóò mú ènìyàn àti ẹranko

kúrò; èmi yóò mú àwọn ẹyẹ ojú

ọ̀run kúrò àti ẹja inú Òkun, àti

ohun ìdìgbòlù pẹ̀lú àwọn

ènìyàn búburú; èmi yóò ké ènìyàn kúrò lórí ilẹ̀ ayé,”

ni Olúwa wí.

Ìlòdì sí Juda

4“Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Juda

àti sórí gbogbo àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu.

Èmi yóò sì ké kúrò níhìn-ín-yìí ìyókù àwọn Baali, àti orúkọ àwọn abọ̀rìṣà

pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà,

5àti àwọn tí ń foríbalẹ̀ lórí òrùlé,

àwọn tí ń sin ogun ọ̀run,

àwọn tó ń foríbalẹ̀, tí wọ́n sì ń fi Olúwa búra,

tí wọ́n sì ń fi Moleki búra.

6Àwọn tí ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa;

Àti àwọn tí kò tí wá Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì béèrè rẹ̀.”

71.7: Hk 2.20; Sk 2.13.Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa Olódùmarè,

nítorí tí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀.

Olúwa ti pèsè ẹbọ kan sílẹ̀,

ó sì ti ya àwọn alápèjẹ rẹ̀ sí mímọ́.

8“Ní ọjọ́ ẹbọ Olúwa,

Èmi yóò bẹ àwọn olórí wò, àti àwọn

ọmọ ọba ọkùnrin,

pẹ̀lú gbogbo

àwọn tí ó wọ àjèjì aṣọ.

9Ní ọjọ́ náà, èmi yóò fi ìyà jẹ

gbogbo àwọn tí ó yẹra láti rìn lórí ìloro ẹnu-ọ̀nà,

tí wọ́n sì kún tẹmpili àwọn ọlọ́run wọn

pẹ̀lú ìwà ipá àti ẹ̀tàn.

10“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí,

“Ohùn ẹkún yóò wà láti ìhà Ibodè ẹja,

híhu láti ìhà kejì wá àti

ariwo ńlá láti òkè kékeré wá.

11Ẹ hu, ẹ̀yin tí ń gbé ní (Maktẹsi) agbègbè ọjà,

gbogbo àwọn oníṣòwò rẹ̀ ni a ó mú kúrò,

gbogbo àwọn ẹni tí ó ń ra fàdákà ni a ó sì parun.

12Ní àkókò wọ̀n-ọn-nì, èmi yóò wá Jerusalẹmu kiri pẹ̀lú fìtílà,

èmi ó sì fi ìyà jẹ àwọn tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn,

tí wọn sì dàbí àwọn ènìyàn tí ó sinmi sínú gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ wọn,

àwọn tí wọn sì ń wí ní ọkàn wọn pé, ‘Olúwa kì yóò ṣe nǹkan kan

tí ó jẹ́ rere tàbí tí ó jẹ́ búburú.’

13Nítorí náà, ọrọ̀ wọn yóò di ìkógun,

àti ilé wọn yóò sì run.

Àwọn yóò sì kọ́ ilé pẹ̀lú, ṣùgbọ́n

wọn kì yóò gbé nínú ilé náà,

wọn yóò gbin ọgbà àjàrà,

ṣùgbọ́n wọn kì yóò mu ọtí

wáìnì láti inú rẹ̀.”

Ọjọ́ ńlá Olúwa

14“Ọjọ́ ńlá Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀,

ó kù sí dẹ̀dẹ̀ ó sì ń yára bọ̀

kánkán. Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ohùn ẹkún

àwọn alágbára ní ọjọ́ Olúwa yóò korò púpọ̀,

15Ọjọ́ náà yóò jẹ́ ọjọ́ ìbínú,

ọjọ́ ìrora àti ìpọ́njú,

ọjọ́ òfò àti idà ọjọ́ ìdahoro

ọjọ́ òkùnkùn àti ìtẹ̀ba,

ọjọ́ kurukuru àti òkùnkùn biribiri,

16ọjọ́ ìpè àti ìpè ogun

sí àwọn ìlú olódi

àti sí àwọn ilé ìṣọ́ gíga.

17“Èmi yóò sì mú ìpọ́njú wá sórí

ènìyàn, wọn yóò sì máa rìn gẹ́gẹ́ bí afọ́jú,

nítorí àwọn ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa.

Ẹ̀jẹ̀ wọn ni a ó sì tú jáde bí eruku

àti ẹran-ara wọn bí ìgbẹ́.

18Bẹ́ẹ̀ ni fàdákà tàbí wúrà wọn

kì yóò sì le gbà wọ́n là

ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.”

Ṣùgbọ́n gbogbo ayé ni a ó fi iná

ìjowú rẹ̀ parun,

nítorí òun yóò fi ìyára fi òpin sí

gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilẹ̀ ayé.

Bibelen på hverdagsdansk

Zefaniasʼ Bog 1:1-18

Zefanias forudsiger verdens og Judas undergang

1Zefanias var søn af Kushi, der var søn af Gedalja, der var søn af Amarja, der var søn af Hizkija. Han modtog følgende profetiske budskab fra Herren, mens Josias, Amons søn, var konge i Juda.

2„Jeg vil fjerne alt fra jordens overflade,” erklærer Herren.

3„Jeg vil udrydde både mennesker og dyr.

Jeg vil fjerne alt, hvad der førte mennesket til fald,

sammen med de mennesker, der faldt.

Hele menneskeheden skal forsvinde fra jordens overflade.

4Jeg vil straffe Judas folk

og ramme Jerusalems indbyggere.

Jeg vil fjerne, hvad der er tilbage af afgudsdyrkelsen

og udrydde alle afgudspræsterne.

Jeg gør det af med mine frafaldne præster,

så ingen vil huske dem mere.

5Jeg vil udrydde dem, der på husenes tage

tilbeder solen, månen og stjernerne,

og dem, der lover mig troskab,

men samtidig tilbeder Molok.1,5 Eller: „deres konge”, dvs. deres afgud. Afguden Molok kaldes også Milkom.

6Jeg vil udrydde dem, som har vendt mig ryggen,

så de ikke længere søger at gøre min vilje.”

7Vis ærefrygt for den almægtige Gud,

for han vil snart udføre sin dom.

Han har besluttet at ramme sit folk

og har allerede udvalgt nogle til opgaven.

8Herren siger: „Jeg vil straffe Judas ledere og kongeslægten,

ja, alle der tilbeder fremmede guder.

9Jeg vil straffe alle afgudsdyrkerne,

som i deres templer planlægger vold og bedrageri.1,9 Teksten er uklar.

10Når fjenden kommer, vil der lyde skrig fra Fiskeporten,

høje råb fra den nye bydel

og voldsomme tumulter fra de omkringliggende høje.

11I, der bor på markedspladsen i dalsænkningen,

sørg og græd, for I bliver de første, der omkommer.

12Jeg vil gennemsøge Jerusalem med lys og lygte,

straffe de selvsikre syndere, der tror,

at Gud er ligeglad med, hvad de gør.

13Fjenden vil plyndre deres huse

og stjæle deres rigdomme.

De kommer aldrig til at bo i de huse,

som de er i færd med at bygge.

De kommer ikke til at smage vinen fra de vingårde,

de har haft så travlt med at anlægge.

14Min dom vil snart ramme jer.

Dagen er nær og kommer med hast.

Det bliver en frygtelig dag,

hvor selv de tapreste mænd vil græde,

15for jeg udøser min vrede over byen.

Det bliver en dag fuld af nød og fortvivlelse,

af ødelæggelse og undergang,

håbløshed og mismod,

dysterhed og mørke,

og kulsorte skyer på himlen.

16Det bliver en dag med hornsignaler

og høje krigsråb.

Selv de befæstede byer bukker under,

og de høje fæstningstårne falder sammen.

17Jeg vil ramme dem så hårdt,

at de raver rundt som i blinde,

for de har syndet imod mig.

Strømme af blod vil flyde i støvet,

ligene ligge og rådne på jorden.

18Deres sølv og guld kan ikke redde dem,

når jeg udfører min dom over dem.

Min glødende vrede vil sætte verden i brand,

så hele jordens befolkning får en brat og frygtelig død.”