Saamu 98 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 98:1-9

Saamu 98

1Ẹ kọrin tuntun sí Olúwa,

nítorí tí ó ṣe ohun ìyanu;

ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti apá mímọ́ rẹ̀

o ṣe iṣẹ́ ìgbàlà fún un

2Olúwa ti sọ ìgbàlà rẹ̀ di mí mọ̀

o fi òdodo rẹ̀ han àwọn orílẹ̀-èdè.

3Ó rántí ìfẹ́ rẹ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ fún àwọn ará ilé Israẹli;

gbogbo òpin ayé ni ó ti rí

iṣẹ́ ìgbàlà Ọlọ́run wa.

4Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Olúwa, gbogbo ayé,

ẹ bú sáyọ̀, ẹ kọrin ìyìn

5Ẹ fi dùùrù kọrin sí Olúwa, pẹ̀lú dùùrù àti ìró ohùn orin mímọ́,

6Pẹ̀lú ìpè àti fèrè

ẹ hó fún ayọ̀ níwájú Olúwa ọba.

7Jẹ́ kí Òkun kí ó hó pẹ̀lú gbogbo

ohun tí ó wà nínú rẹ̀,

Gbogbo ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.

8Ẹ jẹ́ kí odo kí ó ṣápẹ́,

ẹ jẹ́ kí òkè kí ó kọrin pẹ̀lú ayọ̀;

9Ẹ jẹ́ kí wọn kọrin níwájú Olúwa

Nítorí tí yóò wá ṣèdájọ́ ayé

bẹ́ẹ̀ ni yóò ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè nínú òdodo

àti àwọn ènìyàn ní àìṣègbè pẹ̀lú.