Saamu 95
1Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a kọ orin ayọ̀ sí Olúwa
Ẹ jẹ́ kí a kígbe sókè sí àpáta ìgbàlà wa.
2Ẹ jẹ́ kí a wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́
kí a sì pòkìkí rẹ̀ pẹ̀lú ohun èlò
orin àti ìyìn.
3Nítorí Olúwa Ọlọ́run títóbi ni,
ọba tí ó tóbi ju gbogbo òrìṣà lọ.
4Ní ọwọ́ rẹ̀ ni ọ̀gbun ilẹ̀ wà,
ṣóńṣó orí òkè tirẹ̀ ní ṣe.
5Tirẹ̀ ni Òkun, nítorí òun ni ó dá a
àti ọwọ́ rẹ̀ ni ó fi dá ìyàngbẹ ilẹ̀.
6Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a foríbalẹ̀ kí a sìn ín,
Ẹ jẹ́ kí a kúnlẹ̀ níwájú
Olúwa ẹni tí ó dá wa;
795.7-11: Hb 3.7-11; 4.3-11.Nítorí òun ni Ọlọ́run wa
àwa sì ni ènìyàn pápá rẹ̀,
àti ọ̀wọ́ ẹran ni abẹ́ ìpamọ́ rẹ̀.
Lónìí tí ìwọ bá gbọ́ ohùn rẹ̀,
8“Ẹ má ṣe sé ọkàn yín le gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ní Meriba,
àti bí ẹ ti ṣe ní ọjọ́ náà ní Massa ní aginjù,
9Nígbà tí àwọn baba yín dán mi wò
tí wọn wádìí mi,
tí wọn sì rí iṣẹ́ mi
10Fún ogójì ọdún ni èmi fi bínú sí ìran náà;
mo wí pé, ‘Wọ́n jẹ́ ènìyàn tí ọkàn wọn ṣáko lọ
wọn kò sì mọ ọ̀nà mi.’
11Nítorí náà ni mo kéde ìbúra nínú ìbínú mi
‘Wọn kì yóò wọ ibi ìsinmi mi.’ ”
Psalm 95
1Come, let us sing for joy to the Lord;
let us shout aloud to the Rock of our salvation.
2Let us come before him with thanksgiving
and extol him with music and song.
3For the Lord is the great God,
the great King above all gods.
4In his hand are the depths of the earth,
and the mountain peaks belong to him.
5The sea is his, for he made it,
and his hands formed the dry land.
6Come, let us bow down in worship,
let us kneel before the Lord our Maker;
7for he is our God
and we are the people of his pasture,
the flock under his care.
Today, if only you would hear his voice,
8“Do not harden your hearts as you did at Meribah,95:8 Meribah means quarreling.
as you did that day at Massah95:8 Massah means testing. in the wilderness,
9where your ancestors tested me;
they tried me, though they had seen what I did.
10For forty years I was angry with that generation;
I said, ‘They are a people whose hearts go astray,
and they have not known my ways.’
11So I declared on oath in my anger,
‘They shall never enter my rest.’ ”