Saamu 92
Saamu. Orin. Fún ọjọ́ Ìsinmi
1Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa
àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
2Láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀
àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́
3Lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá
àti lára ohun èlò orin haapu.
4Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn
nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa;
èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
5Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa?
Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
6Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n,
aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
7Nígbà tí àwọn ènìyàn búburú
bá rú jáde bí i koríko
àti gbogbo àwọn olùṣe
búburú gbèrú,
wọn yóò run láéláé.
8Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
9Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ,
Olúwa,
nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé;
gbogbo àwọn olùṣe búburú
ni a ó fọ́nká.
10Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó;
òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
11Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi;
ìparun sí àwọn ènìyàn búburú
tí ó dìde sí mi.
12Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ,
wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni;
13Tí a gbìn sí ilé Olúwa,
Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
14Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó,
wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
15Láti fihàn pé “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa;
òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú
kankan nínú rẹ̀.”
Psalm 92
A psalm. A song for the Sabbath day.
1Lord, it is good to praise you.
Most High God, it is good to make music to honor you.
2It is good to sing every morning about your love.
It is good to sing every night about how faithful you are.
3I sing about it to the music of the lyre that has ten strings.
I sing about it to the music of the harp.
4Lord, you make me glad by your deeds.
I sing for joy about what you have done.
5Lord, how great are the things you do!
How wise your thoughts are!
6Here is something that people without sense don’t know.
Here is what foolish people don’t understand.
7Those who are evil spring up like grass.
Those who do wrong succeed.
But they will be destroyed forever.
8But Lord, you are honored forever.
9Lord, your enemies will certainly die.
All those who do evil will be scattered.
10You have made me as strong as a wild ox.
You have poured the finest olive oil on me.
11I’ve seen my evil enemies destroyed.
I’ve heard that they have lost the battle.
12Those who do what is right will grow like a palm tree.
They will grow strong like a cedar tree in Lebanon.
13Their roots will be firm in the house of the Lord.
They will grow strong and healthy in the courtyards of our God.
14When they get old, they will still bear fruit.
Like young trees they will stay fresh and strong.
15They will say to everyone, “The Lord is honest.
He is my Rock, and there is no evil in him.”