Saamu 9 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 9:1-20

Saamu 9

Fún adarí orin. Ní ti ohun orin “Ní ti ikú ọmọ.” Saamu ti Dafidi.

1Èmi ó yìn ọ́, Olúwa, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi;

Èmi ó sọ ti ìyanu rẹ gbogbo.

2Inú mi yóò dùn, èmi yóò sì yọ̀ nínú rẹ;

Èmi ó kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ, Ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.

3Àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà;

Wọ́n kọsẹ̀ wọn sì ṣègbé níwájú rẹ.

4Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú;

ìwọ ti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ, láti ṣe ìdájọ́ òdodo.

5Ìwọ ti bá orílẹ̀-èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run;

Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé.

6Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀tá,

Ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu;

àní ìrántí wọn sì ti ṣègbé.

7Olúwa jẹ ọba títí láé;

ó ti gbé ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ fún ìdájọ́.

89.8: Ap 17.31.Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ ayé ní òdodo;

yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.

9Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára,

ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.

10Àwọn tí ó mọ orúkọ rẹ yóò gbẹ́kẹ̀lé ọ,

nítorí, Olúwa, kò kọ àwọn tó ń wá a sílẹ̀.

11Kọ orin ìyìn sí Olúwa, tí o ń jẹ ọba ní Sioni;

kéde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun tí ó ṣe.

12Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí;

òun kò kọ ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.

13Olúwa, wo bí àwọn ọ̀tá ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi!

Ṣàánú, kí o sì gbé mí sókè kúrò ní ẹnu-ọ̀nà ikú,

14Kí èmi kí ó lè sọ ti ìyìn rẹ

ni ẹnu-ọ̀nà àwọn ọmọbìnrin Sioni

àti láti máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ.

15Àwọn orílẹ̀-èdè ti jì sí kòtò tí wọn ti gbẹ́;

ẹsẹ̀ wọn ni àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ kọ́.

16A mọ Olúwa nípa òdodo rẹ̀;

àwọn ènìyàn búburú ni a dẹ́kun mú nípa iṣẹ́ ọwọ́ wọn.

17Àwọn ènìyàn búburú ni a ó dà sí isà òkú,

àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó gbàgbé Ọlọ́run.

18Ṣùgbọ́n àwọn aláìní ni a kò ní gbàgbé láéláé,

ìrètí àwọn ti ó tálákà ni a kì yóò gbàgbé láéláé.

19Dìde, Olúwa, má ṣe jẹ́ kí ènìyàn borí;

Jẹ́ kí a ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ni iwájú rẹ.

20Lù wọ́n pẹ̀lú ìpayà, Olúwa;

jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé ènìyàn lásán ni wọ́n. Sela.

New International Version

Psalms 9:1-20

Psalm 9Psalms 9 and 10 may originally have been a single acrostic poem in which alternating lines began with the successive letters of the Hebrew alphabet. In the Septuagint they constitute one psalm.In Hebrew texts 9:1-20 is numbered 9:2-21.

For the director of music. To the tune of “The Death of the Son.” A psalm of David.

1I will give thanks to you, Lord, with all my heart;

I will tell of all your wonderful deeds.

2I will be glad and rejoice in you;

I will sing the praises of your name, O Most High.

3My enemies turn back;

they stumble and perish before you.

4For you have upheld my right and my cause,

sitting enthroned as the righteous judge.

5You have rebuked the nations and destroyed the wicked;

you have blotted out their name for ever and ever.

6Endless ruin has overtaken my enemies,

you have uprooted their cities;

even the memory of them has perished.

7The Lord reigns forever;

he has established his throne for judgment.

8He rules the world in righteousness

and judges the peoples with equity.

9The Lord is a refuge for the oppressed,

a stronghold in times of trouble.

10Those who know your name trust in you,

for you, Lord, have never forsaken those who seek you.

11Sing the praises of the Lord, enthroned in Zion;

proclaim among the nations what he has done.

12For he who avenges blood remembers;

he does not ignore the cries of the afflicted.

13Lord, see how my enemies persecute me!

Have mercy and lift me up from the gates of death,

14that I may declare your praises

in the gates of Daughter Zion,

and there rejoice in your salvation.

15The nations have fallen into the pit they have dug;

their feet are caught in the net they have hidden.

16The Lord is known by his acts of justice;

the wicked are ensnared by the work of their hands.9:16 The Hebrew has Higgaion and Selah (words of uncertain meaning) here; Selah occurs also at the end of verse 20.

17The wicked go down to the realm of the dead,

all the nations that forget God.

18But God will never forget the needy;

the hope of the afflicted will never perish.

19Arise, Lord, do not let mortals triumph;

let the nations be judged in your presence.

20Strike them with terror, Lord;

let the nations know they are only mortal.