Saamu 88 – YCB & NAV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 88:1-18

Saamu 88

Orin. Saamu ti àwọn ọmọ Kora. Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti mahalati leannoti. Maskili ti Hemani ará Esra.

1Olúwa, Ọlọ́run tí ó gbà mí là,

ní ọ̀sán àti ní òru ni mo kígbe sókè sí Ọ.

2Jẹ́ kí àdúrà mi kí ó wá sí iwájú rẹ;

dẹ etí rẹ sí igbe mi.

3Nítorí ọkàn mi kún fún ìpọ́njú

ọkàn mi sì súnmọ́ isà òkú.

4A kà mí mọ́ àwọn tí wọ́n lọ sí ọ̀gbun ilẹ̀

èmi dàbí ọkùnrin tí kò ni agbára.

5A yà mí sọ́tọ̀ pẹ̀lú àwọn òkú

bí ẹni tí a pa tí ó dùbúlẹ̀ ní ipò ikú,

ẹni tí ìwọ kò rántí mọ́,

ẹni tí a gé kúrò lára àwọn tí ìwọ ń tọ́jú.

6Ìwọ tí ó fi mí sí kòtò jíjìn,

ní ibi ọ̀gbun tó ṣókùnkùn.

7Ìbínú rẹ ṣubú lé mi gidigidi;

ìwọ ti fi àwọn ìjì rẹ borí mi.

8Ìwọ tí gba ọ̀rẹ́ mi tí ó súnmọ́ mi kúrò lọ́wọ́ mi

ìwọ sì sọ mi di ìríra sí wọn.

A há mi mọ́, èmi kò sì le è jáde;

9Ojú mi káàánú nítorí ìpọ́njú.

Mo kígbe pè ọ́, Olúwa, ní gbogbo ọjọ́;

mo na ọwọ́ mi jáde sí ọ.

10Ìwọ ó fi iṣẹ́ ìyanu rẹ hàn fún òkú bi?

Àwọn òkú yóò ha dìde láti yìn ọ́ bí?

11A ó ha fi ìṣeun ìfẹ́ rẹ hàn ní ibojì bí:

Tàbí òtítọ́ rẹ ní ipò ìparun?

12A ha lè mọ iṣẹ́ ìyanu rẹ ní òkùnkùn bí

àti òdodo rẹ ní ilẹ̀ ìgbàgbé?

13Ṣùgbọ́n mo kígbe sí ọ fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa;

ní òwúrọ̀ ni àdúrà mí wá sọ́dọ̀ rẹ.

14Olúwa, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí

tí ìwọ fi ojú rẹ pamọ́ fún mi?

15Láti ìgbà èwe mi, ìṣẹ́ ń ṣẹ́ mi,

èmi múra àti kú;

nígbà tí ẹ̀rù rẹ bá ń bà mí,

èmi di gbére-gbère

16Ìbínú rẹ ti kọjá lára mi;

ìbẹ̀rù rẹ ti gé mi kúrò

17Ní gbogbo ọjọ́ ni wọn yí mi ká bí ìkún omi;

wọ́n mù mí pátápátá.

18Ìwọ ti mú ọ̀rẹ́ àti olùfẹ́ mi kúrò lọ́dọ̀ mi;

òkùnkùn sì jẹ́ ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ mi.

Ketab El Hayat

مزمور 88:1-18

الْمَزْمُورُ الثَّامِنُ وَالثَّمَانُونَ

تَسْبِيحَةٌ: مَزْمُورٌ لِبَنِي قُورَحَ. لِقَائِدِ الْمُنْشِدِينَ عَلَى النَّايِ الْحَزِينِ لِلْغِنَاءِ الْخَافِتِ. قَصِيدَةٌ تَعْلِيمِيَّةٌ لِهَيْمَانَ الأَزْرَاحِيِّ

1يَا رَبُّ يَا إِلَهَ خَلاصِي، أَمَامَكَ أَصْرُخُ نَهَاراً وَلَيْلاً. 2لِتَأْتِ صَلاتِي أَمَامَكَ، أَمِلْ أُذُنَكَ إِلَى صَرْخَتِي، 3فَإِنَّ نَفْسِي شَبِعَتْ مَصَائِبَ، وَحَيَاتِي تَقْتَرِبُ مِنَ الْمَوْتِ. 4حُسِبْتُ فِي عِدَادِ الْهَابِطِينَ إِلَى قَعْرِ هُوَّةِ الْمَوْتِ، وَكَرَجُلٍ لَا قُوَّةَ لَهُ. 5تَرَكُونِي أَمُوتُ كَقَتْلَى الْحَرْبِ الْمُمَدَّدِينَ فِي الْقَبْرِ، الَّذِينَ لَا تَعُودُ تَذْكُرُهُمْ وَتَكُفُّ يَدَكَ عَنْ إِغَاثَتِهِمْ. 6قَدْ طَرَحْتَنِي فِي الْهُوَّةِ السُّفْلَى، فِي الأَمَاكِنِ الْمُظْلِمَةِ وَالْعَمِيقَةِ. 7اسْتَقَرَّ علَيَّ غَضَبُكَ، وَبِأَمْوَاجِكَ الطَّامِيَةِ ذَلَّلْتَنِي. 8أَبْعَدْتَ عَنِّي أَصْحَابِي، وَجَعَلْتَنِي عَاراً عِنْدَهُمْ. قَدْ حُبِسْتُ فَلَا نَجَاةَ لِي. 9كَلَّتْ عَيْنَايَ مِنْ فَرْطِ البُكَاءِ. إِيَّاكَ يَا رَبُّ دَعَوْتُ كُلَّ يَوْمٍ بَاسِطاً إِلَيْكَ يَدَيَّ.

10هَلْ تَصْنَعُ عَجَائِبَ لِلأَمْوَاتِ، أَمْ تَقُومُ أَشْبَاحُ الْمَوْتَى فَتُمَجِّدَكَ؟ 11أَفِي الْقَبْرِ تُعْلَنُ رَحْمَتُكَ، وَفِي الْهَاوِيَةِ أَمَانَتُكَ؟ 12هَلْ فِي الظَّلامِ تُعْرَفُ عَجَائِبُكَ، وَفِي أَرْضِ النِّسْيَانِ يَظْهَرُ بِرُّكَ؟

13أَمَّا أَنَا فَإِلَيْكَ أَصْرُخُ مُسْتَغِيثاً يَا رَبُّ، وَفِي الصَّبَاحِ تَمْثُلُ صَلاتِي أَمَامَكَ. 14لِمَاذَا يَا رَبُّ تَرْفُضُ نَفْسِي، وَتَحْجُبُ عَنِّي وَجْهَكَ؟ 15إِنَّنِي مِسْكِينٌ، وَمُشْرِفٌ عَلَى الْمَوْتِ مُنْذُ صِبَايَ، وَقَدْ قَاسَيْتُ أَهْوَالَكَ، وَذُهِلْتُ. 16اجْتَاحَنِي غَضَبُكَ الشَّدِيدُ وَأَفْنَتْنِي أَهْوَالُكَ. 17أَحَاطَتْ بِي طُولَ النَّهَارِ كَالْمِيَاهِ وَأَطْبَقَتْ عَلَيَّ كُلُّهَا. 18فَرَّقْتَ عَنِّي الأَصْدِقَاءَ فَصَارَ الظَّلامُ مُلازِماً لِي.