Saamu 73 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 73:1-28

ÌWÉ KẸTA

Saamu 73–89

Saamu 73

Saamu ti Asafu.

1Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli,

fún àwọn ọlọ́kàn funfun.

2Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán;

ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.

3Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé

nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.

4Wọn kò ṣe wàhálà;

ara wọn mókun wọn sì lágbára.

5Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn;

a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.

6Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn;

ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.

7Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá;

ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n

8Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti

ìnilára, wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.

9Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run

ahọ́n wọn gba ipò ayé.

10Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn

wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.

11Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀?

Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”

12Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí

ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.

13Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́;

nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.

14Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu;

a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.

15Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,”

Èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.

16Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí,

Ó jẹ́ ìnilára fún mi.

17Títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run;

Nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.

18Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́

ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.

19Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí

bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan!

Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!

20Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí,

bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa,

ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.

21Nígbà tí inú mi bàjẹ́

àti ọkàn mi ṣì korò,

22Mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye;

mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.

23Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo;

ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.

24Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi

ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo

25Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ?

Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.

26Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà

ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi

àti ìpín mi títí láé.

27Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé

ìwọ ti pa gbogbo wọn run;

tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ

28Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run

Èmi ti fi Olúwa Olódùmarè ṣe ààbò mi;

Kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.

Nouă Traducere În Limba Română

Psalmii 73:1-28

Cartea III

(Psalmii 73–89)

Psalmul 73

Un psalm al lui Asaf.

1Da, bun este Dumnezeu cu Israel,

cu cei cu inima curată.

2Cât despre mine, erau să mi se îndoaie picioarele,

era cât pe ce să‑mi alunece pașii,

3căci îi invidiam pe cei lăudăroși

când vedeam bunăstarea celor răi.

4Căci ei n‑au parte de remușcări până la moarte,

iar trupul le este plin de grăsime.4 Sau: Căci n‑au parte de durere, / iar trupul le este sănătos și puternic.

5N‑au parte de necazul muritorului de rând

și nu sunt loviți ca alți oameni.

6De aceea mândria le este lănțișor la gât,

iar violența îi învelește ca o manta.

7Le iese ochiul din orbită,7 Sau: Le ies ochii din cauza grăsimii. LXX și Siriacă: din grăsimea lor se prelinge ticăloșia.

iar imaginațiile inimii lor întrec măsura.

8Iau în derâdere și vorbesc cu răutate;

vorbesc de sus cu asuprire.

9Își înalță gura până la ceruri,

iar limba lor cutreieră pământul.

10De aceea poporul Lui se întoarce la ei

și soarbe ape din plin de la ei.

11Ei zic: „Cum să știe Dumnezeu

și cum ar putea afla Cel Preaînalt?“

12Iată, așa sunt cei răi:

liniștiți pe vecie și crescând în bogăție.

13Într-adevăr, degeaba mi‑am curățit inima

și mi‑am spălat mâinile în nevinovăție,

14căci sunt lovit toată ziua

și am parte de pedeapsă în fiecare dimineață.

15Dacă aș zice: „Vreau să pot vorbi și eu așa!“,

iată că aș trăda generația fiilor Tăi.

16Când m‑am gândit la aceste lucruri ca să le înțeleg,

a fost o îndeletnicire obositoare pentru mine,

17până când am venit la Sfântul Lăcaș al lui Dumnezeu

și am luat aminte la sfârșitul lor.

18Într-adevăr, Tu îi așezi în locuri alunecoase,

îi arunci în dezastru.

19Cum sunt pustiiți într‑o clipă!

Sunt nimiciți, sfârșiți prin lovituri năprasnice.

20Ei sunt ca un vis la deșteptare.

Stăpâne, când Te trezești, le vei disprețui chipul.

21Când mi se amăra inima

și eram străpuns în rărunchii mei,

22eram fără minte și nu știam nimic;

eram ca un animal înaintea Ta.

23Însă eu totdeauna sunt cu Tine!

Tu mă ții de mâna dreaptă,

24mă călăuzești cu sfatul Tău

și apoi mă vei lua în slavă.

25Pe cine am eu în ceruri în afară de Tine?

Iar pe pământ nu‑mi găsesc plăcerea în nimeni, ci doar în Tine.

26Carnea și inima pot să mi se prăpădească,

dar Dumnezeu este stânca inimii mele

și partea mea de moștenire pe vecie.

27Căci iată, cei ce se depărtează de Tine vor pieri.

Tu nimicești pe oricine curvește, abătându‑se de la Tine.

28Cât despre mine, este bine să fiu lângă Dumnezeu.

Am făcut din Stăpânul Domn adăpostul meu;

voi povesti toate lucrările Tale!