Saamu 59 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 59:1-17

Saamu 59

Fún adarí orin. Tí ohùn orin “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí Saulu rán àwọn olùṣọ́ sí ilé Dafidi kí òun bá le rí i pa.

1Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi, Ọlọ́run;

dáàbò bò mí kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó dìde sí mi.

2Gbà mí lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ búburú

kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ènìyàn tí ń pòǹgbẹ ẹ̀jẹ̀.

3Wò ó, bí wọ́n ṣe ba ní bùba dè mí!

Àwọn alágbára ń gbìmọ̀ lòdì sí mi

Kì í ṣe nítorí ìrékọjá mi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ mí, Olúwa.

4Èmi kò ṣe àìṣedéédéé kan, síbẹ̀ wọ́n sáré wọ́n ṣetán láti kọlù mí.

Dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi, kí o sì wo àìlera mi.

5Olúwa Ọlọ́run Alágbára,

Ọlọ́run Israẹli,

dìde fún ara rẹ kí o sì bá àwọn orílẹ̀-èdè wí;

má ṣe ṣàánú fún àwọn olùrékọjá búburú nì. Sela.

6Wọ́n padà ní àṣálẹ́,

wọ́n ń gbó bí àwọn ajá,

wọ́n ń rìn yí ìlú náà káàkiri.

7Kíyèsi ohun tí wọ́n tú jáde ní ẹnu:

wọn ń tú idà jáde láti ètè wọn,

wọ́n sì wí pé, “Ta ni ó lè gbọ́ ọ̀rọ̀ wa?”

8Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, yóò fi wọ́n rẹ́rìn-ín

Ìwọ ó yọ ṣùtì sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.

9Ìwọ agbára mi, èmi ó máa kọrin ìyìn sí ọ;

nítorí ìwọ Ọlọ́run ni ààbò mi,

10Ọlọ́run àánú mi ni yóò ṣáájú mi.

Ọlọ́run yóò sì jẹ́ kí èmi rí ìfẹ́ mi lára àwọn ọ̀tá mi.

Yóò sì jẹ́ kí n yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi.

11Ṣùgbọ́n má ṣe pa wọ́n, Olúwa asà wa,

kí àwọn ènìyàn mi má ba à gbàgbé.

Nínú agbára rẹ, jẹ́ kí wọn máa rìn kiri,

kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.

12Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnu wọn,

ní ọ̀rọ̀ ètè wọn,

kí a mú wọn nínú ìgbéraga wọn.

Nítorí èébú àti èké tí wọn ń sọ,

13Pa wọ́n run nínú ìbínú,

run wọ́n di ìgbà tí wọn kò ní sí mọ́.

Nígbà náà ni yóò di mí mọ̀ dé òpin ayé

pé Ọlọ́run jẹ ọba lórí Jakọbu. Sela.

14Wọ́n padà ní àṣálẹ́,

wọn ń gbó bí àwọn ajá

wọ́n ń rin ìlú náà káàkiri.

15Wọ́n ń rin kiri fún oúnjẹ

wọ́n sì ń yán nígbà tí wọn kò yó.

16Ṣùgbọ́n èmi ó kọrin agbára rẹ,

n ó kọrin ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀;

nítorí ìwọ ni ààbò mi,

ibi ìsádi mi ní ìgbà ìpọ́njú.

17Ìwọ agbára mi, èmi ó kọrin ìyìn sí ọ;

ìwọ, Ọlọ́run, ààbò mi, Ọlọ́run ìfẹ́ mi.

New International Reader’s Version

Psalm 59:1-17

Psalm 59

For the director of music. A miktam of David when Saul had sent men to watch David’s house. Saul sent the men to kill David. To the tune of “Do Not Destroy.”

1God, save me from my enemies.

Keep me safe from people who are attacking me.

2Save me from those who do evil.

Save me from people who want to kill me.

3See how they hide and wait for me!

Lord, angry people plan to harm me,

even though I haven’t hurt them in any way or sinned against them.

4I haven’t done anything wrong to them. But they are ready to attack me.

Rise up and help me! Look at what I’m up against!

5Lord God who rules over all, rise up. God of Israel,

punish all the nations.

Don’t show any mercy to those sinful people

who have turned against me.

6My enemies are like a pack of barking dogs

that come back to the city in the evening.

They prowl around the city.

7Listen to what pours out of their mouths.

The words from their lips are like swords.

They think, “Who can hear us?”

8But you laugh at them, Lord.

You make fun of all those nations.

9You give me strength. I look to you.

God, you are like a fort to me. 10You are my God, and I can depend on you.

God will march out in front of me.

He will let me look down on those who tell lies about me.

11Lord, you are like a shield that keeps us safe.

Don’t kill my enemies all at once.

If you do, my people will forget about it.

Use your power to pull my enemies up by the roots like weeds.

Destroy them.

12They have sinned with their mouths.

Their lips have spoken evil words.

They have cursed me and lied.

Let them be caught in their pride.

13Burn them up in your anger.

Burn them up until there isn’t anything left of them.

Then everyone from one end of the earth to the other will know

that God rules over the people of Jacob.

14My enemies are like a pack of barking dogs

that come back into the city in the evening.

They prowl around the city.

15They wander around looking for food.

They groan if they don’t find something that will satisfy them.

16But I will sing about your strength.

In the morning I will sing about your love.

You are like a fort to me.

You keep me safe in times of trouble.

17You give me strength. I sing praise to you.

God, you are like a fort to me. You are my God, and I can depend on you.