Saamu 58 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 58:1-11

Saamu 58

Fún adarí orin. Tí ohùn “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu.

1Ẹ̀yin ha ń sọ òdodo nítòótọ́

ẹ̀yin ìjọ ènìyàn?

Ǹjẹ́ ẹ̀yin ń ṣe ìdájọ́ tí ó ṣe títọ́

ẹ̀yìn ọmọ ènìyàn?

2Bẹ́ẹ̀ kọ́, nínú ọkàn yín ẹ̀yìn ń gbèrò àìṣòdodo,

ọwọ́ yín sì tú ìwà ipá jáde ni ayé.

3Ní inú ìyá wọn wá ni ènìyàn búburú tí ṣìnà,

lójúkan náà tí a ti bí wọn, wọn a máa ṣèké.

4Oró wọn dàbí oró ejò,

wọn dàbí adití ejò paramọ́lẹ̀ tí ó di ara rẹ̀ ni etí,

5tí kò ní gbọ́ ìpè àwọn atunilójú,

bí ó ti wù kí ó máa fi ọgbọ́n ṣe ìtujú tó.

6Ká eyín ẹnu wọn, Ọlọ́run;

ní ẹnu wọn,

ká ọ̀gàn àwọn ọmọ kìnnìún, Olúwa.

7Jẹ́ kí wọn parẹ́ bí omi tó ń sàn lọ;

nígbà tí ó bá fa ọfà rẹ̀, kí ọ̀kọ̀ wọn kí ó ṣẹ́.

8Jẹ́ kí wọn rí bí ìgbín tí rẹ̀ dànù tí ó sì ṣègbé

bí ọmọ tí oṣù rẹ̀ kò pé, kí wọn má ṣe rí oòrùn.

9Kí ìkòkò yín kí ó tó mọ ìgbóná ẹ̀gún;

bóyá ní tútù tàbí ní gbígbẹ, yóò fi ìjì gbá wọn lọ.

10Olódodo yóò yọ̀ nígbà a bá ń gbẹ̀san wọn,

nígbà tí wọn bá wẹ ẹsẹ̀ wọn nínú ẹ̀jẹ̀ ènìyàn búburú.

11Àwọn ènìyàn yóò wí pé,

“Lóòtítọ́ èrè àwọn ń bẹ fún olódodo;

lóòtítọ́ òun ni Ọlọ́run tí ń ṣe ìdájọ́ ní ayé.”