Saamu 55 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 55:1-23

Saamu 55

Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi.

1Fi etí sí àdúrà mi, Ọlọ́run,

Má ṣe fi ojú pa ẹ̀bẹ̀ mi rẹ́:

2Gbọ́ mi kí o sì dá mi lóhùn.

Èrò mi ń dà mí láàmú, èmi sì ń pariwo.

3Sí ohùn àwọn ọ̀tá ni,

nítorí igbe àwọn ènìyàn búburú;

nítorí wọ́n mú ìjìyà wá sórí mi,

wọ́n sì kẹ́gàn mi nínú ìbínú wọn.

4Ọkàn mi wà nínú ìrora pẹ̀lú;

ẹ̀rù ikú kọjú ìjà sí mi.

5Ìbẹ̀rù àti ìwárìrì wa sí ara mi;

ìbẹ̀rù ti bò mí mọ́lẹ̀.

6Èmi sọ pé, “Èmi ìbá ní ìyẹ́ bí àdàbà!

Èmi ìbá fò lọ kí n sì sinmi.

7Èmi ìbá sálọ, jìnnà réré,

kí ń sì dúró sí aginjù;

8Èmi ìbá yára lọ́ si ibùgbé mi ní ibi ààbò,

jìnnà kúrò nínú ìjì àti ẹ̀fúùfù líle.”

9Da àwọn ẹni búburú láàmú, Olúwa, da ahọ́n wọn rú,

nítorí èmi rí ìwà agbára àti ìjà ní ìlú náà.

10Ọ̀sán àti òru ni wọ́n fi ń rìn gbogbo odi kiri;

ìwà ìkà àti èébú wà láàrín rẹ̀.

11Ìwà búburú ń bẹ ní àárín rẹ̀;

ẹ̀tàn àti èké kò kúrò ní ìgboro rẹ̀.

12Tí ọ̀tá bá tàbùkù mi,

èmi yóò fi ara mọ́ ọn;

tí ọ̀tá bá gbé ara rẹ̀ ga sí mi,

èmi ìbá sápamọ́ fún un.

13Ṣùgbọ́n tí ó bá ṣe ìwọ, ọkùnrin bí ẹgbẹ́ mi,

ẹlẹgbẹ́ mi, àti ọ̀rẹ́ tí ó súnmọ́ mi,

14pẹ̀lú ẹni tí èmi ti jẹ ìgbádùn adùn ìdàpọ̀,

bí a ṣe ń rìn pẹ̀lú àwùjọ ní ilé Ọlọ́run.

15Kí ikú kí ó dé bá wọn,

Kí wọn ó lọ láààyè sí isà òkú,

Jẹ́ kí wọn ó sọ̀kalẹ̀ sí ibojì pẹ̀lú ìpayà,

nítorí tí ìwà búburú ń bẹ ní ibùjókòó wọn, àti nínú wọn.

16Ṣùgbọ́n èmi pe Ọlọ́run;

Olúwa yóò sì gbà mí.

17Ní alẹ́, ní òwúrọ̀ àti ní ọ̀sán

èmi sọkún jáde nínú ìpọ́njú,

o sì gbọ́ ohùn mi.

18Ó rà mí padà láìléwu

kúrò nínú ogun tí ó dìde sí mi,

nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó dìde sí mi.

19Ọlọ́run yóò gbọ́, yóò sì pọ́n wọn lójú

àní, ẹni tí ó ti jókòó láti ìgbàanì—Sela.

Nítorí tí wọn kò ní àyípadà,

tí wọn kò sì bẹ̀rù Ọlọ́run.

20Ọ̀rẹ́ mi yìí ti dalẹ̀ èmi ọ̀rẹ́ rẹ̀;

ó ti ba májẹ̀mú rẹ̀ jẹ́.

21Ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ kúnná ju òrí-àmọ́,

ṣùgbọ́n ogun wà ni àyà rẹ̀;

ọ̀rọ̀ rẹ̀ fẹ́lẹ́ ju òróró lọ,

ṣùgbọ́n idà fífàyọ ní wọn.

2255.22: 1Pt 5.7.Gbé ẹrù rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ Olúwa

yóò sì mú ọ dúró;

òun kò ní jẹ́ kí olódodo ṣubú.

23Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni yóò mu àwọn ọ̀tá mi

wá sí ihò ìparun;

Àwọn ẹni tí òǹgbẹ ẹ̀jẹ̀ ń gbẹ àti ẹni ẹ̀tàn,

kì yóò gbé ààbọ̀ ọjọ́ wọn.

Ṣùgbọ́n fún èmi, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ.

New International Version

Psalms 55:1-23

Psalm 55In Hebrew texts 55:1-23 is numbered 55:2-24.

For the director of music. With stringed instruments. A maskilTitle: Probably a literary or musical term of David.

1Listen to my prayer, O God,

do not ignore my plea;

2hear me and answer me.

My thoughts trouble me and I am distraught

3because of what my enemy is saying,

because of the threats of the wicked;

for they bring down suffering on me

and assail me in their anger.

4My heart is in anguish within me;

the terrors of death have fallen on me.

5Fear and trembling have beset me;

horror has overwhelmed me.

6I said, “Oh, that I had the wings of a dove!

I would fly away and be at rest.

7I would flee far away

and stay in the desert;55:7 The Hebrew has Selah (a word of uncertain meaning) here and in the middle of verse 19.

8I would hurry to my place of shelter,

far from the tempest and storm.”

9Lord, confuse the wicked, confound their words,

for I see violence and strife in the city.

10Day and night they prowl about on its walls;

malice and abuse are within it.

11Destructive forces are at work in the city;

threats and lies never leave its streets.

12If an enemy were insulting me,

I could endure it;

if a foe were rising against me,

I could hide.

13But it is you, a man like myself,

my companion, my close friend,

14with whom I once enjoyed sweet fellowship

at the house of God,

as we walked about

among the worshipers.

15Let death take my enemies by surprise;

let them go down alive to the realm of the dead,

for evil finds lodging among them.

16As for me, I call to God,

and the Lord saves me.

17Evening, morning and noon

I cry out in distress,

and he hears my voice.

18He rescues me unharmed

from the battle waged against me,

even though many oppose me.

19God, who is enthroned from of old,

who does not change—

he will hear them and humble them,

because they have no fear of God.

20My companion attacks his friends;

he violates his covenant.

21His talk is smooth as butter,

yet war is in his heart;

his words are more soothing than oil,

yet they are drawn swords.

22Cast your cares on the Lord

and he will sustain you;

he will never let

the righteous be shaken.

23But you, God, will bring down the wicked

into the pit of decay;

the bloodthirsty and deceitful

will not live out half their days.

But as for me, I trust in you.