Saamu 50 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 50:1-23

Saamu 50

Saamu ti Asafu

1Olúwa, Ọlọ́run alágbára

sọ̀rọ̀ kí o sì pe ayé jọ

láti ìlà-oòrùn títí dé ìwọ̀ rẹ̀.

2Láti Sioni wá, pípé ni ẹwà,

Ọlọ́run tí ń tan ìmọ́lẹ̀

3Ọlọ́run ń bọ̀,

bẹ́ẹ̀ ni kì yóò dákẹ́,

iná yóò máa jó níwájú rẹ̀,

àti ní àyíká rẹ̀ ni ẹ̀fúùfù líle yóò ti máa jà ká.

4Yóò sì pe àwọn ọ̀run láti òkè wá jọ àti ayé,

kí o le máa ṣe ìdárò àwọn ènìyàn rẹ̀.

5“Kó àwọn ènìyàn mímọ́ jọ fún mi

àwọn tí wọn fi ẹbọ dá májẹ̀mú fún mi.”

6Àwọn ọ̀run yóò sì sọ̀rọ̀ òdodo rẹ̀,

Nítorí Ọlọ́run fúnrarẹ̀ ni onídàájọ́.

7“Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi yóò si sọ̀rọ̀, ìwọ Israẹli, èmi yóò jẹ́rìí sí ọ:

èmi ní Ọlọ́run, àní Ọlọ́run rẹ.

8Èmi kí yóò bá ọ wí

nítorí àwọn ìrúbọ rẹ,

tàbí ọrẹ ẹbọ sísun rẹ, èyí tí ó wà níwájú mi

ní ìgbà gbogbo.

9Èmí kò fẹ́ kí ó mú akọ màlúù láti inú ilé tí o kọ́ fún un,

tàbí kí o mú òbúkọ láti

inú agbo ẹran rẹ̀

10Nítorí gbogbo ẹran igbó ni tèmi

àti ẹran ọ̀sìn lórí ẹgbẹ̀rún òkè.

11Èmi mọ gbogbo ẹyẹ ní orí àwọn òkè ńlá

àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó wà ní orí ilẹ̀ ni tèmi

12Bí ebi tilẹ̀ ń pa mí, èmi kì yóò sọ fún ọ,

nítorí ayé ni tèmi àti ohun gbogbo

tí ó wa ní inú rẹ̀.

13Ǹjẹ́ èmi yóò ha jẹ ẹran akọ màlúù tàbí

mú ẹ̀jẹ̀ òbúkọ?

14“Rú ẹbọ ọpẹ́ sí Ọlọ́run,

kí o sì san ẹ̀jẹ́ rẹ fún Ọ̀gá-ògo.

15Kí o sì pè mí ní ọjọ́ ìpọ́njú,

èmi yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì bu ọlá fún mi.”

16Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún àwọn, ènìyàn búburú:

“Kí ní ẹ̀tọ́ tí o ní tí ìwọ fi ń tún àwọn ìlànà mi sọ,

tàbí tí ìwọ sì ń sọ májẹ̀mú mi ní ẹnu rẹ?

17Ìwọ kórìíra àṣẹ mi,

ìwọ sì ṣá ọ̀rọ̀ mí tì sí apá kan.

18Nígbà tí ìwọ rí olè, ìwọ dára pọ̀ mọ́ ọn,

ìwọ sì da ara rẹ dé àwọn alágbèrè.

19Ìwọ lo ẹnu rẹ fún aburú,

ìwọ sì ń fi ahọ́n rẹ pète ẹ̀tàn.

20Ní ìgbà gbogbo ìwọ ń sọ̀rọ̀ sí arákùnrin rẹ,

ìwọ sì ń ba orúkọ ọmọ ìyá rẹ jẹ́.

21Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ìwọ ti ṣe, mo sì dákẹ́;

ìwọ rò pé mo jẹ́ irú kan náà bí ìrẹ,

ṣùgbọ́n èmi yóò bá ọ wí,

èmi yóò sì fi ẹ̀sùn kàn ọ́ ní ojú ara rẹ.

22“Ǹjẹ́ ìwọ ro èyí wò, ẹ̀yin tí ó gbàgbé Ọlọ́run.

Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ èmi yóò fa yin ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, láìsí ẹni tí yóò gbà yin sílẹ̀.

23Ẹni tí ó ba ní ẹbọ ọrẹ-ọpẹ́ bu ọlá fún mi; kí ó sì tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe,

kí èmi kí ó le fi ìgbàlà Ọlọ́run hàn án.”