Saamu 46 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 46:1-11

Saamu 46

Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Gẹ́gẹ́ bí ti alamoti. b Orin.

1Ọlọ́run ni ààbò àti agbára wa

ó jẹ́ olùrànlọ́wọ́ ní ìgbà ìpọ́njú.

2Nítorí náà àwa kì yóò bẹ̀rù, bí a tilẹ̀ ṣí ayé ní ìdí,

tí òkè sì ṣubú sínú Òkun.

3Tí omi rẹ̀ tilẹ̀ ń hó tí ó sì ń mì

tí àwọn òkè ńlá tilẹ̀ ń mì pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀. Sela.

4Odò ńlá kan wà tí ṣíṣàn rẹ̀ mú inú ìlú Ọlọ́run dùn,

ibi mímọ́, níbi ti Ọ̀gá-ògo ń gbé.

5Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀, kò ní yẹ̀:

Ọlọ́run yóò ràn án lọ́wọ́ ní kùtùkùtù òwúrọ̀.

6Àwọn orílẹ̀-èdè ń bínú, àwọn ilẹ̀ ọba ṣubú,

ó gbé ohun rẹ̀ sókè, ayé yọ̀.

7Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú wa,

Ọlọ́run Jakọbu ni ààbò wa.

8Ẹ wá wo iṣẹ́ Olúwa

irú ahoro tí ó ṣe ní ayé.

9O mú ọ̀tẹ̀ tán de òpin ilẹ̀ ayé

ó ṣẹ́ ọrun, ó sì gé ọ̀kọ̀ sí méjì

ó fi kẹ̀kẹ́ ogun jóná

10Ẹ dúró jẹ́ẹ́, kí ẹ sì mọ̀ pé èmi ní Ọlọ́run.

A ó gbé mi ga nínú àwọn orílẹ̀-èdè

A ó gbé mi ga ní ayé.

11Ọlọ́run alágbára wà pẹ̀lú wa

Ọlọ́run Jakọbu sì ni ààbò wa.

New International Reader’s Version

Psalm 46:1-11

Psalm 46

For the director of music. A song of the Sons of Korah. According to alamoth.

1God is our place of safety. He gives us strength.

He is always there to help us in times of trouble.

2The earth may fall apart.

The mountains may fall into the middle of the sea.

But we will not be afraid.

3The waters of the sea may roar and foam.

The mountains may shake when the waters rise.

But we will not be afraid.

4God’s blessings are like a river. They fill the city of God with joy.

That city is the holy place where the Most High God lives.

5Because God is there, the city will not fall.

God will help it at the beginning of the day.

6Nations are in disorder. Kingdoms fall.

God speaks, and the people of the earth melt in fear.

7The Lord who rules over all is with us.

The God of Jacob is like a fort to us.

8Come and see what the Lord has done.

See the places he has destroyed on the earth.

9He makes wars stop from one end of the earth to the other.

He breaks every bow. He snaps every spear.

He burns every shield with fire.

10He says, “Be still, and know that I am God.

I will be honored among the nations.

I will be honored in the earth.”

11The Lord who rules over all is with us.

The God of Jacob is like a fort to us.