Saamu 38 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 38:1-22

Saamu 38

Saamu Dafidi. Ẹ̀bẹ̀.

1Olúwa, Má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ,

bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe fi ìyà jẹ mí nínú ìrunú rẹ̀.

2Nítorí tí ọfà rẹ kàn mọ́ mi ṣinṣin,

ọwọ́ rẹ sì kì mí mọ́lẹ̀.

3Kò sí ibi yíyè ní ara à mi, nítorí ìbínú rẹ;

kò sí àlàáfíà nínú egungun mi nítorí i ẹ̀ṣẹ̀ mi.

4Nítorí àìṣedéédéé mi ti borí mi mọ́lẹ̀;

wọ́n tó ìwọ̀n bi àjàgà tí ó wúwo jù fún mi.

5Ọgbẹ́ mi ń rùn ó sì díbàjẹ́

nítorí òmùgọ̀ mi.

6Èmi ń jòwèrè, orí mi tẹ̀ ba gidigidi

èmi ń ṣọ̀fọ̀ rìn kiri ní gbogbo ọjọ́.

7Nítorí ẹ̀gbẹ́ mi kún fún ìgbóná tí ń jóni

kò sì ṣí ibi yíyè ní ara mi,

8Ara mi hù, a sì wó mi jẹ́gẹjẹ̀gẹ;

mo kérora nítorí ìrúkèrúdò àyà mi.

9Olúwa, gbogbo ìfẹ́ mi ń bẹ níwájú rẹ;

ìmí ẹ̀dùn mi kò sápamọ́ fún ọ.

10Àyà mi ń mí hẹlẹ, agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀;

bí ó ṣe ti ìmọ́lẹ̀ ojú mi ni, ó ti lọ kúrò lára mi.

11Àwọn ọ̀rẹ́ mi àti àwọn ẹlẹgbẹ́ mi dúró lókèèrè réré kúrò níbi ìpọ́njú mi,

àwọn alábágbé mi, dúró lókèèrè.

12Àwọn tí n wá ẹ̀mí mi dẹ okùn sílẹ̀ fún mi;

àti àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára ń sọ̀rọ̀ nípa ìparun,

wọ́n sì ń gbèrò ẹ̀tàn ní gbogbo ọjọ́.

13Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi, èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀;

àti bí odi, tí kò le sọ̀rọ̀.

14Nítòótọ́, mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́rọ̀,

àti bí ẹnu ẹni tí kò sí ìjiyàn.

15Ṣùgbọ́n sí ọ Olúwa, ìwọ ni mo dúró dè;

ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run mi, ẹni tí yóò dáhùn.

16Nítorí tí mo gbàdúrà, “Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí;

nígbà tí ẹsẹ̀ mi bá yọ̀ wọn yóò máa gbé ara wọn ga sí mi.”

17Nítorí tí mo ti ṣetán láti ṣubú,

ìrora mi sì wà pẹ̀lú mi nígbà gbogbo.

18Mo jẹ́wọ́ ìrékọjá mi;

àánú sì ṣe mí fún ẹ̀ṣẹ̀ mi.

19Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí pàtàkì, wọ́n lágbára púpọ̀,

ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó kórìíra mi lọ́nà òdì.

20Àwọn tí wọn ń fi ibi san rere fún mi

àwọn ni ọ̀tá mi

nítorí pé mò ń tọ ìre lẹ́yìn.

21Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, ìwọ Olúwa!

Ọlọ́run mi, Má ṣe jìnnà sí mi.

22Yára láti ràn mí lọ́wọ́,

Olúwa, Olùgbàlà mi.