Saamu 37 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 37:1-40

Saamu 37

Ti Dafidi.

1Má ṣe ìkanra nítorí àwọn olùṣe búburú,

kí ìwọ má sì ṣe ṣe ìlara nítorí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀;

2nítorí pé wọn yóò gbẹ bí i koríko,

wọn yóò sì rẹ̀ dànù bí ewéko tútù.

3Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, kí o sì máa ṣe rere;

torí pé ìwọ yóò gbé ilẹ̀ náà, kí o sì gbádùn ààbò rẹ̀.

4Ṣe inú dídùn sí Olúwa;

òun yóò sì fún ọ ní ìfẹ́ inú rẹ̀.

5Fi ọ̀nà rẹ lé Olúwa lọ́wọ́;

gbẹ́kẹ̀lé pẹ̀lú, òun yóò sì ṣe é.

6Yóò sì mú kí òdodo rẹ̀ jáde bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀,

àti ìdájọ́ rẹ̀ bí ọ̀sán gangan.

7Ìwọ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa,

kí o sì fi sùúrù dúró dè é;

má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọn tí ń rí rere ní ọ̀nà wọn,

nítorí ọkùnrin náà ti mú èrò búburú ṣẹ.

8Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí, kí o sì kọ ìkáàánú sílẹ̀,

má ṣe ṣe ìkanra, kí ó má ba à ṣé búburú pẹ̀lú.

9Nítorí tí á ó gé àwọn olùṣe búburú kúrò,

ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwa àwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.

10Síbẹ̀ nígbà díẹ̀ sí i, àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ̀;

nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀ wo ipò rẹ̀, wọn kì yóò sí níbẹ̀.

11Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò jogún ilẹ̀ náà,

wọn yóò sì máa ṣe inú dídùn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.

12Ènìyàn búburú di rìkíṣí sí olóòtítọ́,

wọ́n sì pa eyín wọn keke sí wọn;

13ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rìn-ín sí àwọn ènìyàn búburú,

nítorí tí ó rí wí pé ọjọ́ wọn ń bọ̀.

14Ènìyàn búburú fa idà yọ,

wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn,

láti sọ tálákà àti aláìní kalẹ̀,

láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.

15Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ,

àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.

16Ohun díẹ̀ tí olódodo ní,

sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú;

17nítorí pé a óò ṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú,

ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.

18Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn tó dúró ṣinṣin,

àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé;

19Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi,

àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.

20Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé.

Àwọn ọ̀tá Olúwa yóò dàbí ẹwà oko tútù;

wọn fò lọ; bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.

21Àwọn ènìyàn búburú yá, wọn kò sì san án padà,

ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa ṣàánú, a sì máa fi fún ni;

22Nítorí àwọn tí Olúwa bá bùkún ni yóò jogún ilẹ̀ náà,

àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.

23Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá,

o sì ṣe inú dídùn sí ọ̀nà rẹ̀;

24Bí ó tilẹ̀ ṣubú a kì yóò ta á nù pátápátá,

nítorí tí Olúwa di ọwọ́ rẹ̀ mú.

25Èmi ti wà ni èwe, báyìí èmi sì dàgbà;

síbẹ̀ èmi kò ì tí ì ri kí a kọ olódodo sílẹ̀,

tàbí kí irú-ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe oúnjẹ.

26Aláàánú ni òun nígbà gbogbo a máa yá ni;

a sì máa bùsi i fún ni.

27Lọ kúrò nínú ibi, kí o sì máa ṣe rere;

nígbà náà ni ìwọ yóò gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.

28Nítorí pé Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́,

kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀.

Àwọn olódodo ni a ó pamọ́ títí ayérayé,

ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburú ni a ó ké kúrò.

29Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà,

yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.

30Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n,

ahọ́n rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.

31Òfin Ọlọ́run rẹ̀ ń bẹ ní àyà wọn;

àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀ kì yóò yẹ̀.

32Ènìyàn búburú ń ṣọ́ olódodo,

Ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á.

33Olúwa kì yóò fi lé e lọ́wọ́ kì yóò sì dá a lẹ́bi,

nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.

34Dúró de Olúwa,

kí o sì máa pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́.

Yóò sì gbé ọ lékè láti jogún ilẹ̀ náà;

nígbà tí a bá gé àwọn ènìyàn búburú kúrò ìwọ yóò ri.

35Èmi ti rí ènìyàn búburú tí ń hu ìwà ìkà,

ó sì fi ara rẹ̀ gbilẹ̀ bí igi tútù ńlá,

36ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan sí i ó kọjá lọ, sì kíyèsi, kò sì sí mọ́;

bi ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé mo wá a kiri, ṣùgbọ́n a kò le è ri.

37Máa kíyèsi ẹni pípé, kí o sì wo ẹni tó dúró ṣinṣin;

nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.

38Ṣùgbọ́n àwọn olùrékọjá ni a ó parun papọ̀;

ìran àwọn ènìyàn búburú ni a ó gé kúrò.

39Ìgbàlà àwọn onídùúró ṣinṣin wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa;

òun ni ààbò wọn ní ìgbà ìpọ́njú

40Olúwa yóò ràn wọ́n lọ́wọ́ yóò sì gbà wọ́n;

yóò gbà wọ́n lọ́wọ́ ènìyàn búburú, yóò sì gbà wọ́n là,

nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé e.

New International Reader’s Version

Psalm 37:1-40

Psalm 37

A psalm of David.

1Don’t be upset because of sinful people.

Don’t be jealous of those who do wrong.

2Like grass, they will soon dry up.

Like green plants, they will soon die.

3Trust in the Lord and do good.

Then you will live in the land and enjoy its food.

4Find your delight in the Lord.

Then he will give you everything your heart really wants.

5Commit your life to the Lord.

Here is what he will do if you trust in him.

6He will make the reward for your godly life shine like the dawn.

He will make the proof of your honest life shine like the sun at noon.

7Be still and wait patiently for the Lord to act.

Don’t be upset when other people succeed.

Don’t be upset when they carry out their evil plans.

8Turn away from anger and don’t give in to wrath.

Don’t be upset, because that only leads to evil.

9Sinful people will be destroyed.

But those who put their hope in the Lord will receive the land.

10In a little while, there won’t be any more sinners.

Even if you look for them, you won’t be able to find them.

11But those who are free of pride will be given the land.

They will enjoy peace and success.

12Sinful people make plans to harm those who do what is right.

They grind their teeth at them.

13But the Lord laughs at those who do evil.

He knows the day is coming when he will judge them.

14Sinners pull out their swords.

They bend their bows.

They want to kill poor and needy people.

They plan to murder those who lead honest lives.

15But they will be killed by their own swords.

Their own bows will be broken.

16Those who do what is right may have very little.

But it’s better than the wealth of many sinners.

17The power of those who are evil will be broken.

But the Lord takes good care of those who do what is right.

18Those who are without blame spend their days in the Lord’s care.

What he has given them will last forever.

19When trouble comes to them, they will have what they need.

When there is little food in the land, they will still have plenty.

20But sinful people will die.

The Lord’s enemies may be like flowers in the field.

But they will be swallowed up.

They will disappear like smoke.

21Sinful people borrow and don’t pay back.

But those who are godly give freely to others.

22The Lord will give the land to those he blesses.

But he will destroy those he curses.

23The Lord makes secure the footsteps

of the person who delights in him,

24Even if that person trips, he won’t fall.

The Lord’s hand takes good care of him.

25I once was young, and now I’m old.

But I’ve never seen godly people deserted.

I’ve never seen their children begging for bread.

26The godly are always giving and lending freely.

Their children will be a blessing.

27Turn away from evil and do good.

Then you will live in the land forever.

28The Lord loves those who are honest.

He will not desert those who are faithful to him.

Those who do wrong will be completely destroyed.

The children of sinners will die.

29Those who do what is right will be given the land.

They will live in it forever.

30The mouths of those who do what is right speak words of wisdom.

They say what is honest.

31God’s law is in their hearts.

Their feet do not slip.

32Those who are evil hide and wait for godly people.

They want to kill them.

33But the Lord will not leave the godly in their power.

He will not let them be found guilty when they are brought into court.

34Put your hope in the Lord.

Live as he wants you to.

He will honor you by giving you the land.

When sinners are destroyed, you will see it.

35I saw a mean and sinful person.

He was doing well, like a green tree in its own land.

36But he soon passed away and was gone.

Even though I looked for him, I couldn’t find him.

37Consider honest people who are without blame.

People who seek peace will have a tomorrow.

38But all sinners will be destroyed.

Those who are evil won’t have a tomorrow.

39The Lord saves those who do what is right.

He is their place of safety when trouble comes.

40The Lord helps them and saves them.

He saves them from sinful people

because they go to him for safety.