Saamu 35 – YCB & HTB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 35:1-28

Saamu 35

Ti Dafidi.

1Olúwa, gbógun ti àwọn tí ń gbóguntì mí;

kí o sì kọ ojú ìjà sí àwọn tí ó ń bá mi í jà!

2Di asà àti àpáta mú,

kí o sì dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi!

3Fa idà àti ọ̀kọ̀ yọ

kí o sì dojúkọ àwọn tí ń lé mi.

Sọ fún ọkàn mi pé,

“Èmi ni ìgbàlà rẹ.”

4Kí wọn kí ó dààmú,

kí a sì ti àwọn tí ń lépa ọkàn mi lójú;

kí a sì mú wọn padà,

kí a sì dààmú àwọn tí ń gbèrò ìpalára mi.

5Jẹ́ kí wọn dàbí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́,

kí angẹli Olúwa kí ó máa lé wọn kiri.

6Jẹ́ kí ọ̀nà wọn kí ó ṣókùnkùn, kí ó sì máa yọ́,

kí angẹli Olúwa kí ó máa lépa wọn!

7Nítorí pé, ní àìnídìí ni wọ́n dẹ àwọ̀n wọn sílẹ̀ fún mi,

ní àìnídìí ni wọ́n wa kòtò sílẹ̀ fún ọkàn mi.

8Kí ìparun kí ó wá sí orí rẹ̀ ní òjijì.

Àwọ̀n rẹ̀ tí ó dẹ, kí ó mú òun tìkára rẹ̀;

kí wọn ṣubú sínú kòtò sí ìparun ara rẹ̀.

9Nígbà náà ni ọkàn mi yóò yọ̀ nínú Olúwa,

àní, yóò sì máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ̀.

10Gbogbo egungun mi yóò wí pé,

“Ta ni ó dàbí ì ìwọ Olúwa?

O gba tálákà lọ́wọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ,

tálákà àti aláìní lọ́wọ́ ẹni tí ń fi ṣe ìkógun?”

11Àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde;

wọ́n ń bi mi ní ohun tí èmi kò mọ̀.

12Wọ́n fi búburú san ìre fún mi;

láti sọ ọkàn mi di òfo.

13Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni, nígbà tí wọn ń ṣe àìsàn, mo wọ aṣọ ọ̀fọ̀;

mo fi àwẹ̀ pọ́n ara mi lójú.

Mo gba àdúrà pẹ̀lú ìtẹríba ní oókan àyà mi;

14èmí ń lọ kiri bí ẹni ń ṣọ̀fọ̀

bí i ẹni wí pé fún ọ̀rẹ́ tàbí ẹ̀gbọ́n mi ni.

Èmí tẹríba nínú ìbànújẹ́

bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ìyà rẹ̀.

15Ṣùgbọ́n nínú ìkọ̀sẹ̀ mi wọ́n sì yọ̀, wọ́n sì kó ara wọn jọ;

wọ́n kó ara wọn jọ sí mi; àní àwọn tí èmi kò mọ̀.

Wọ́n fà mí ya wọ́n kò sì dákẹ́.

16Bí àwọn àgàbàgebè tí ń ṣe ẹlẹ́yà ní àpèjẹ

wọ́n pa eyín wọn keke sí mi.

17Yóò ti pẹ́ tó Olúwa, tí ìwọ yóò máa wò wọ́n lọ?

Yọ mí kúrò nínú ìparun wọn,

àní ẹ̀mí ì mi kúrò lọ́wọ́ kìnnìún.

18Nígbà náà ni èmi yóò ṣọpẹ́ fún Ọ nínú àjọ ńlá;

èmi yóò máa yìn Ọ́ ní àwùjọ ọ̀pọ̀ ènìyàn.

1935.19: Sm 69.4; Jh 15.25.Má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi

kí ó yọ̀ lórí ì mi;

bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe àwọn tí ó kórìíra mi

ní àìnídìí máa ṣẹ́jú sí mi.

20Nítorí pé wọn kò sọ ọ̀rọ̀ àlàáfíà,

ṣùgbọ́n wọ́n lóyún ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn

sí àwọn ènìyàn dídákẹ́ ilẹ̀ náà.

21Wọ́n ya ẹnu wọn gbòòrò sí mi; wọ́n wí pé, “Háà! Háà!

Ojú wa sì ti rí i.”

22Ìwọ́ ti rí i Olúwa; má ṣe dákẹ́!

Olúwa má ṣe jìnnà sí mi!

23Dìde! ru ara rẹ̀ sókè fún ààbò mi,

àti sí ọ̀ràn mi, Ọlọ́run mi àti Olúwa mi!

24Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa Ọlọ́run mi, gẹ́gẹ́ bí òdodo rẹ,

kí o má sì ṣe jẹ́ kí wọn kí ó yọ̀ lórí mi!

25Má ṣe jẹ́ kí wọn wí nínú ara wọn pé, “Háà! A ti rí ohun tí ọkàn wa ń fẹ́!”

Má ṣe jẹ́ kí wọn kí ó wí pé, “A ti gbé e mì.”

26Kí ojú kí ó tì wọ́n,

kí wọn kí ó sì dààmú pọ̀,

àní àwọn tí ń yọ̀ sí ìyọnu mi

kí a fi ìtìjú àti àbùkù wọ̀ wọ́n ní aṣọ tí ń gbéraga sí mi.

27Jẹ́ kí àwọn tí ó fẹ́ ìdáláre mi

fò fún ayọ̀ àti ìdùnnú;

kí wọn máa sọ ọ́ títí lọ, “Pé gbígbéga ni Olúwa,

sí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ̀.”

28Nígbà náà ni ahọ́n mi yóò máa sọ̀rọ̀ òdodo rẹ,

àti ìyìn rẹ ní gbogbo ọjọ́.

Het Boek

Psalmen 35:1-28

1Een lied van David.

Here, als sommigen met mij argumenteren,

wilt U dan voor mij antwoorden?

Als iemand mij aanvalt,

vecht U dan voor mij terug.

2Neem uw wapens op

en kom mij te hulp!

3Val mijn achtervolgers aan.

Laat mij weten dat U mij zult verlossen!

4Laat hen die mij willen doden,

voor schut staan.

Laat hen die slechte plannen tegen mij beramen,

beschaamd afdruipen.

5Verstrooi hen als kaf in de wind,

op het moment dat uw Engel hen neerslaat.

6Zij gaan op donkere, glibberige wegen

en de Engel van de Here achtervolgt hen daarop.

7Want zonder aanleiding spanden zij een net voor mij

en groeven een valkuil om mij te vangen.

8Ik hoop dat zij zonder het te merken zelf omkomen.

Dat zij in hun eigen kuil zullen vallen.

9Ik verheug mij in de Here,

ik zing een loflied over zijn hulp en bevrijding.

10Alles in mij juicht:

Here, wie kan U evenaren?

U bevrijdt arme en beproefde mensen

van hun onderdrukkers en berovers.

11Leugenachtige getuigen nemen het woord

en vragen mij dingen die ik helemaal niet weet.

12Zij vergelden goed met kwaad.

Mijn ziel is eenzaam geworden.

13Zelf heb ik mij direct in rouwkleding gestoken

toen zij ziek waren.

Ik vernederde mij voor U met vasten

wanneer mijn gebed niet verhoord werd.

14Ik liep rond alsof het mijn broer of mijn vriend betrof,

ik ging in het zwart alsof mijn moeder was gestorven.

15Maar toen ík een keer in problemen zat,

lachten zij om mij en liepen te hoop om mij te zien.

Zelfs onbekenden begonnen mij te slaan

en maakten mij onophoudelijk bespottelijk.

16Een heel stel ongelovige, spotlustige lieden

bedreigde mij.

17Here,

hoe lang laat U hen nog hun gang gaan?

Verlos mij toch, ik ben eenzaam.

Laten zij mij niet verslinden.

18Dan zal ik U te midden van alle gelovigen loven,

U prijzen waar iedereen bij is.

19Laten mijn valse tegenstanders toch geen plezier over mij hebben!

Er zijn er die mij zonder reden haten!

20Zij zijn niet op vrede uit.

Zij maken slechte plannen,

gericht tegen hen die in rust en stilte leven.

21Zij bedreigen mij en zeggen:

‘Ha! Wij hebben het wel gezien!’

22U ziet alles, Here, wilt U optreden?

Och Here, laat mij niet in de steek!

23Sta op en vecht voor mijn recht.

God, mijn Here, voert U voor mij het woord in de rechtzaal.

24Laat uw recht over mij beslissen, Here, mijn God,

zodat zij geen leedvermaak over mij kunnen hebben.

25Dat zij niet kunnen denken:

‘Ha! Nu gebeurt wat wij willen!

Wij hebben hem eronder gekregen!’

26Laten zij zich maar schamen,

al die mensen die op mijn ondergang zitten te wachten.

Ik hoop dat allen die mij verachten, te schande worden gemaakt.

27Maar ik wil dat alle mensen

die verlangen naar mijn vrijspraak,

zullen juichen en zich verheugen.

Dat zij voortdurend de Here zullen grootmaken en zeggen:

‘De Here trekt Zich het lot van zijn geliefde dienaar aan.’

28Zelf zal ik dag in, dag uit

over uw rechtvaardigheid spreken

en U loven en prijzen.