Saamu 35 – YCB & CST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 35:1-28

Saamu 35

Ti Dafidi.

1Olúwa, gbógun ti àwọn tí ń gbóguntì mí;

kí o sì kọ ojú ìjà sí àwọn tí ó ń bá mi í jà!

2Di asà àti àpáta mú,

kí o sì dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi!

3Fa idà àti ọ̀kọ̀ yọ

kí o sì dojúkọ àwọn tí ń lé mi.

Sọ fún ọkàn mi pé,

“Èmi ni ìgbàlà rẹ.”

4Kí wọn kí ó dààmú,

kí a sì ti àwọn tí ń lépa ọkàn mi lójú;

kí a sì mú wọn padà,

kí a sì dààmú àwọn tí ń gbèrò ìpalára mi.

5Jẹ́ kí wọn dàbí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́,

kí angẹli Olúwa kí ó máa lé wọn kiri.

6Jẹ́ kí ọ̀nà wọn kí ó ṣókùnkùn, kí ó sì máa yọ́,

kí angẹli Olúwa kí ó máa lépa wọn!

7Nítorí pé, ní àìnídìí ni wọ́n dẹ àwọ̀n wọn sílẹ̀ fún mi,

ní àìnídìí ni wọ́n wa kòtò sílẹ̀ fún ọkàn mi.

8Kí ìparun kí ó wá sí orí rẹ̀ ní òjijì.

Àwọ̀n rẹ̀ tí ó dẹ, kí ó mú òun tìkára rẹ̀;

kí wọn ṣubú sínú kòtò sí ìparun ara rẹ̀.

9Nígbà náà ni ọkàn mi yóò yọ̀ nínú Olúwa,

àní, yóò sì máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ̀.

10Gbogbo egungun mi yóò wí pé,

“Ta ni ó dàbí ì ìwọ Olúwa?

O gba tálákà lọ́wọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ,

tálákà àti aláìní lọ́wọ́ ẹni tí ń fi ṣe ìkógun?”

11Àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde;

wọ́n ń bi mi ní ohun tí èmi kò mọ̀.

12Wọ́n fi búburú san ìre fún mi;

láti sọ ọkàn mi di òfo.

13Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni, nígbà tí wọn ń ṣe àìsàn, mo wọ aṣọ ọ̀fọ̀;

mo fi àwẹ̀ pọ́n ara mi lójú.

Mo gba àdúrà pẹ̀lú ìtẹríba ní oókan àyà mi;

14èmí ń lọ kiri bí ẹni ń ṣọ̀fọ̀

bí i ẹni wí pé fún ọ̀rẹ́ tàbí ẹ̀gbọ́n mi ni.

Èmí tẹríba nínú ìbànújẹ́

bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ìyà rẹ̀.

15Ṣùgbọ́n nínú ìkọ̀sẹ̀ mi wọ́n sì yọ̀, wọ́n sì kó ara wọn jọ;

wọ́n kó ara wọn jọ sí mi; àní àwọn tí èmi kò mọ̀.

Wọ́n fà mí ya wọ́n kò sì dákẹ́.

16Bí àwọn àgàbàgebè tí ń ṣe ẹlẹ́yà ní àpèjẹ

wọ́n pa eyín wọn keke sí mi.

17Yóò ti pẹ́ tó Olúwa, tí ìwọ yóò máa wò wọ́n lọ?

Yọ mí kúrò nínú ìparun wọn,

àní ẹ̀mí ì mi kúrò lọ́wọ́ kìnnìún.

18Nígbà náà ni èmi yóò ṣọpẹ́ fún Ọ nínú àjọ ńlá;

èmi yóò máa yìn Ọ́ ní àwùjọ ọ̀pọ̀ ènìyàn.

1935.19: Sm 69.4; Jh 15.25.Má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi

kí ó yọ̀ lórí ì mi;

bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe àwọn tí ó kórìíra mi

ní àìnídìí máa ṣẹ́jú sí mi.

20Nítorí pé wọn kò sọ ọ̀rọ̀ àlàáfíà,

ṣùgbọ́n wọ́n lóyún ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn

sí àwọn ènìyàn dídákẹ́ ilẹ̀ náà.

21Wọ́n ya ẹnu wọn gbòòrò sí mi; wọ́n wí pé, “Háà! Háà!

Ojú wa sì ti rí i.”

22Ìwọ́ ti rí i Olúwa; má ṣe dákẹ́!

Olúwa má ṣe jìnnà sí mi!

23Dìde! ru ara rẹ̀ sókè fún ààbò mi,

àti sí ọ̀ràn mi, Ọlọ́run mi àti Olúwa mi!

24Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa Ọlọ́run mi, gẹ́gẹ́ bí òdodo rẹ,

kí o má sì ṣe jẹ́ kí wọn kí ó yọ̀ lórí mi!

25Má ṣe jẹ́ kí wọn wí nínú ara wọn pé, “Háà! A ti rí ohun tí ọkàn wa ń fẹ́!”

Má ṣe jẹ́ kí wọn kí ó wí pé, “A ti gbé e mì.”

26Kí ojú kí ó tì wọ́n,

kí wọn kí ó sì dààmú pọ̀,

àní àwọn tí ń yọ̀ sí ìyọnu mi

kí a fi ìtìjú àti àbùkù wọ̀ wọ́n ní aṣọ tí ń gbéraga sí mi.

27Jẹ́ kí àwọn tí ó fẹ́ ìdáláre mi

fò fún ayọ̀ àti ìdùnnú;

kí wọn máa sọ ọ́ títí lọ, “Pé gbígbéga ni Olúwa,

sí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ̀.”

28Nígbà náà ni ahọ́n mi yóò máa sọ̀rọ̀ òdodo rẹ,

àti ìyìn rẹ ní gbogbo ọjọ́.

Nueva Versión Internacional (Castilian)

Salmo 35:1-28

Salmo 35

Salmo de David.

1Defiéndeme, Señor, de los que me atacan;

combate a los que me combaten.

2Toma tu adarga, tu escudo,

y acude en mi ayuda.

3Empuña la lanza y el hacha,

y haz frente a35:3 el hacha, y haz frente a (lectura probable); cierra contra (TM). los que me persiguen.

Quiero oírte decir:

«Yo soy tu salvación».

4Queden confundidos y avergonzados

los que procuran matarme;

retrocedan humillados

los que traman mi ruina.

5Sean como la paja en el viento,

acosados por el ángel del Señor;

6sea su senda oscura y resbalosa,

perseguidos por el ángel del Señor.

7Ya que sin motivo me tendieron una trampa,

y sin motivo cavaron una fosa para mí,

8que la ruina los tome por sorpresa;

que caigan en su propia trampa,

en la fosa que ellos mismos cavaron.

9Así mi alma se alegrará en el Señor

y se deleitará en su salvación;

10así todo mi ser exclamará:

«¿Quién como tú, Señor?

Tú libras de los poderosos a los pobres;

a los pobres y necesitados libras

de aquellos que los explotan».

11Se presentan testigos despiadados

y me preguntan cosas que yo ignoro.

12Me devuelven mal por bien,

y eso me hiere en el alma;

13pues cuando ellos enfermaban

yo me vestía de luto,

me afligía y ayunaba.

¡Ay, si pudiera retractarme de mis oraciones!

14Me vestía yo de luto,

como por un amigo o un hermano.

Afligido, inclinaba la cabeza,

como si llorara por mi madre.

15Pero yo tropecé, y ellos se alegraron,

y a una se juntaron contra mí.

Gente extraña,35:15 Gente extraña (lectura probable); Gente golpeada (TM). que yo no conocía,

me calumniaba sin cesar.

16Me atormentaban, se burlaban de mí,35:16 Me atormentaban, se burlaban de mí (LXX); Con inicuos burlones de una torta (TM).

y contra mí rechinaban los dientes.

17¿Hasta cuándo, Señor, vas a tolerar esto?

Libra mi vida, mi única vida,

de los ataques de esos leones.

18Yo te daré gracias en la gran asamblea;

ante una multitud te alabaré.

19No dejes que de mí se burlen

mis enemigos traicioneros;

no dejes que se guiñen el ojo

los que me odian sin motivo.

20Porque no vienen en son de paz,

sino que urden mentiras

contra la gente apacible del país.

21De mí se ríen a carcajadas, y exclaman:

«¡Mirad cómo ha acabado!»

22Señor, tú has visto todo esto;

no te quedes callado.

¡Señor, no te alejes de mí!

23¡Despierta, Dios mío, levántate!

¡Hazme justicia, Señor, defiéndeme!

24Júzgame según tu justicia, Señor mi Dios;

no dejes que se burlen de mí.

25No permitas que piensen:

«¡Así queríamos verlo!»

No permitas que digan:

«Nos lo hemos tragado vivo».

26Queden avergonzados y confundidos

todos los que se alegran de mi desgracia;

sean cubiertos de oprobio y vergüenza

todos los que se creen más que yo.

27Pero lancen voces de alegría y regocijo

los que apoyan mi causa,

y digan siempre: «Exaltado sea el Señor,

quien se deleita en el bienestar de su siervo».

28Con mi lengua proclamaré tu justicia,

y todo el día te alabaré.