Saamu 28 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 28:1-9

Saamu 28

Ti Dafidi.

1Ìwọ Olúwa,

mo ké pe àpáta mi;

Má ṣe kọ etí dídi sí mi.

Tí ìwọ bá dákẹ́ sí mi,

èmí yóò dàbí àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun.

2Gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi fún àánú,

bí mo ṣe ń ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́,

bí mo ṣe gbé àwọn ọwọ́ mi sókè

sí ibi mímọ́ rẹ jùlọ.

3Má ṣe fà mí lọ pẹ̀lú ènìyàn búburú àti,

pẹ̀lú àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀,

tí ń sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò wọn

ṣùgbọ́n tí ìwà ìkà ń bẹ nínú wọn.

4San ẹ̀san wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn

àti fún iṣẹ́ ibi wọn;

gba ẹ̀san wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn;

kí o sì san ẹ̀san wọn bí ó ti tọ́.

5Nítorí pé wọn kò ka iṣẹ́ Olúwa sí,

tàbí àwọn iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀

òun ó rún wọn wọlẹ̀

kì yóò sì gbé wọn ró mọ́.

6Alábùkún fún ni Olúwa!

Nítorí pé ó ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.

7Olúwa ni agbára mi àti asà mi;

nínú rẹ̀ ni mo gbẹ́kẹ̀lé; àní, ó sì ràn mí lọ́wọ́.

Ọkàn mi sì gbé sókè fún ayọ̀

àní pẹ̀lú orin mi mo fi ọpẹ́ fún un.

8Olúwa ni agbára àwọn ènìyàn rẹ̀

òun ni odi ìgbàlà àwọn ẹni ààmì òróró rẹ̀.

9Ìwọ gba àwọn ènìyàn rẹ là, kí o sì bùkún àwọn ajogún rẹ;

di olùṣọ́-àgùntàn wọn, kí o sì gbé wọn lékè títí ayérayé.