Saamu 27 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 27:1-14

Saamu 27

Ti Dafidi.

1Olúwa ni ìmọ́lẹ̀ mi àti ìgbàlà mi;

ta ni èmi yóò bẹ̀rù?

Olúwa ni ibi ìsádi ẹ̀mí mi,

ẹ̀rù ta ni yóò bà mí?

2Nígbà tí àwọn ènìyàn búburú kọjú ìjà sí mi

láti jẹ ẹran-ara mi,

àní àwọn ọ̀tá mi àti àwọn abínúkú mi,

wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.

3Bí ọmọ-ogun tilẹ̀ yí mi ká tí wọ́n sì dìde sí mi,

ọkàn mi kì yóò bẹ̀rù;

bí ogun tilẹ̀ dìde sí mi,

nínú èyí ni ọkàn mi yóò le.

4Ohun kan ni mo béèrè lọ́dọ̀ Olúwa,

òhun ni èmi yóò máa wá kiri:

kí èmi kí ó le wà ní ilé Olúwa

ní ọjọ́ ayé mi gbogbo,

kí èmi: kí ó le kíyèsi ẹwà Olúwa,

kí èmi kí ó sì máa wà ní tẹmpili rẹ̀.

5Nítorí pé ní ìgbà ìpọ́njú

òun yóò pa mí mọ́ nínú àgọ́ rẹ̀;

níbi ìkọ̀kọ̀ àgọ́ rẹ̀ ni òun yóò pa mí mọ́;

yóò sì gbé mi sókè lórí àpáta.

6Ní ìsinsin yìí, a ti gbé orí mi sókè

ga ju ti àwọn ọ̀tá mi lọ tí ó yí mí ká;

èmi yóò rú ẹbọ nínú àgọ́ rẹ, ẹbọ ariwo àti ti ayọ̀;

èmi yóò kọrin àní orin dídùn sí Olúwa.

7Gbọ́ ohùn mi nígbà tí ẹ̀mí bá à ń pè, Háà! Olúwa,

ṣe àánú fún mi kí o sì dá mi lóhùn;

8“Wá,” ọkàn mi wí pé, “wá ojú u rẹ̀.”

Ojú rẹ, Olúwa, ni èmí ń wá.

9Má ṣe fi ojú rẹ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi,

má ṣe fi ìbínú sá ìránṣẹ́ rẹ tì;

ìwọ tí o ti jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi,

Má ṣe fi mí sílẹ̀, má sì ṣe kọ̀ mí,

háà! Ọlọ́run ìgbàlà mi.

10Bí ìyá àti baba bá kọ̀ mí sílẹ̀,

Olúwa yóò tẹ́wọ́ gbà mí.

11Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa,

kí o sì sìn mi lọ sí ọ̀nà tí ó tẹ́jú

nítorí àwọn ọ̀tá mi.

12Má ṣe fi mí lé ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi lọ́wọ́,

nítorí àwọn ẹlẹ́rìí èké ti dìde sí mi,

wọ́n sì mí ìmí ìkà.

13Èmi ní ìgbàgbọ́ pé,

èmi yóò rí ìre Olúwa

ní ilẹ̀ alààyè.

14Dúró de Olúwa;

kí ó jẹ alágbára, kí o sì mú ọkàn le

àní dúró de Olúwa.

New International Reader’s Version

Psalm 27:1-14

Psalm 27

A psalm of David.

1The Lord is my light, and he saves me.

Why should I fear anyone?

The Lord is my place of safety.

Why should I be afraid?

2My enemies are evil.

They will trip and fall

when they attack me

and try to swallow me up.

3Even if an army attacks me,

my heart will not be afraid.

Even if war breaks out against me,

I will still trust in God.

4I’m asking the Lord for only one thing.

Here is what I want.

I want to live in the house of the Lord

all the days of my life.

I want to look at the beauty of the Lord.

I want to worship him in his temple.

5When I’m in trouble,

he will keep me safe in his house.

He will hide me in the safety of his holy tent.

He will put me on a rock that is very high.

6Then I will win the battle

over my enemies who are all around me.

At his holy tent I will offer my sacrifice with shouts of joy.

I will sing and make music to the Lord.

7Lord, hear my voice when I call out to you.

Treat me with kindness and answer me.

8My heart says, “Seek him!”

Lord, I will seek you.

9Don’t turn your face away from me.

Don’t turn me away because you are angry.

You have helped me.

God my Savior, don’t say no to me.

Don’t desert me.

10My father and mother may desert me,

but the Lord will accept me.

11Lord, teach me your ways.

Lead me along a straight path.

There are many people who treat me badly.

12My enemies want to harm me. So don’t turn me over to them.

Witnesses who tell lies are rising up against me.

They say all sorts of evil things about me.

13Here is something I am still sure of.

I will see the Lord’s goodness

while I’m still alive.

14Wait for the Lord.

Be strong and don’t lose hope.

Wait for the Lord.