Saamu 22 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 22:1-31

Saamu 22

Fún adarí orin. Tí ohùn orin “àgbọ̀nrín òwúrọ̀.” Saamu ti Dafidi.

122.1: Mt 27.46; Mk 15.34.Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí sílẹ̀?

Èéṣe tí o fi jìnnà láti gbà mí là,

àní sí igbe ìkérora mi?

2Ọlọ́run mi, ní ọ̀sán gangan ni mo kígbe, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi ní ohùn:

àti ní òru èmi kò dákẹ́.

3Ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹni mímọ́ ni ìwọ;

ẹni tí ó tẹ ìyìn Israẹli dó;

4Àwọn baba ńlá wa ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú rẹ;

wọ́n ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ìwọ sì gbà wọ́n.

5Ìwọ ni wọ́n sun ẹkún sí, wọ́n sì ní ìgbàlà;

ìwọ ni wọ́n gbẹ́kẹ̀lé, a kò sì dójútì wọ́n.

6Ṣùgbọ́n kòkòrò ní mo jẹ́, kì í sì í ṣe ènìyàn;

mo di ẹlẹ́gàn àwọn ènìyàn, ẹlẹ́yà àwọn ènìyàn

7Gbogbo àwọn tí ó rí mí fi mí ṣe ẹlẹ́yà;

wọ́n yọ ètè ẹ̀gàn wọn sí mi, wọ́n sì ń mi orí wọn pé.

8“Ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé Olúwa;

jẹ́ kí Olúwa gbà á là.

Jẹ́ kí ó gbà á là,

nítorí pé, ó ní ayọ̀ nínú rẹ̀.”

9Síbẹ̀ ìwọ ni ó ti mú mi wá láti inú;

ìwọ ni ó mú mi wà láìléwu, nígbà tí mo rọ̀ mọ́ ọmú ìyá mi.

10Ìwọ ni a fi mí lé lọ́wọ́ láti inú ìyá mi wá,

nígbà tí ìyá mí sì ti bí mi, ìwọ ni Ọlọ́run mi.

11Má ṣe jìnnà sí mi,

nítorí pé ìyọnu súnmọ́ tòsí

kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò ṣe ìrànlọ́wọ́.

12Ọ̀pọ̀ akọ màlúù yí mi ká;

àwọn màlúù alágbára Baṣani rọ̀gbà yí mi ká.

13Wọ́n ya ẹnu wọn sì mi bí i kìnnìún tí ń dọdẹ kiri,

tí ń ké ramúramù.

14A dà mí jáde gẹ́gẹ́ bí omi,

gbogbo egungun mi ti yẹ̀ kúrò ní oríkèé rẹ̀.

Ọkàn mi sì dàbí i ìda;

tí ó yọ́ láàrín inú mi.

15Agbára mí ti gbẹ bí àpáàdì,

ahọ́n mí sì tilẹ̀ mọ́ párí ẹ̀rẹ̀kẹ́ ẹ mi;

ìwọ ti tẹ́ mi sínú eruku ikú.

16Àwọn ajá yí mi ká;

ìjọ àwọn ènìyàn ibi ti ká mi mọ́,

Wọ́n gún mi lọ́wọ́, wọ́n sì gún mi lẹ́sẹ̀

17Mo lè ka gbogbo àwọn egungun mi;

àwọn tìkára wọn ń wò, wọ́n dójú lé mi.

18Wọ́n pín aṣọ mi láàrín ara wọn

àní lórí aṣọ mi ni wọ́n ṣẹ́ gègé.

19Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, má ṣe jìnnà sí mi;

Háà! Olùrànlọ́wọ́ ọ̀ mi, yára wá fún àtìlẹ́yìn mi!

20Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ idà,

àní ẹ̀mí mi lọ́wọ́ agbára àwọn ajá.

21Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ kìnnìún;

Kí o sì gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ìwo àgbáǹréré.

22Èmi yóò kéde orúkọ rẹ láàrín arákùnrin àti arábìnrin mi;

nínú ìjọ ni èmi yóò máa yìn ọ́.

23Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ yìn ín!

Gbogbo ẹ̀yin ìran Jakọbu, ẹ fi ògo fún un!

Ẹ dìde fún un tẹ̀rù tẹ̀rù, ẹ̀yin irú-ọmọ Israẹli!

24Nítorí pé òun kò ṣátá, bẹ́ẹ̀ ni kò sì kórìíra

ìpọ́njú àwọn tí a ni lára;

kò sì fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún mi

ṣùgbọ́n ó gbọ́ nígbà tí mo ké pè é.

25Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìyìn mi yóò ti wá nínú àjọ ńlá;

ẹ̀jẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò san níwájú àwọn tí o bẹ̀rù rẹ̀

26tálákà yóò jẹ yóò sì yó;

àwọn tí n wá Olúwa yóò yin

jẹ́ kí ẹ̀mí rẹ̀ wà láààyè títí ayérayé!

27Gbogbo òpin ayé ni yóò rántí

wọn yóò sì yípadà sí Olúwa,

àti gbogbo ìdílé orílẹ̀-èdè

ni wọn yóò jọ́sìn níwájú rẹ̀,

28Nítorí ìjọba ni ti Olúwa.

Òun ni ó ń pàṣẹ lórí àwọn orílẹ̀-èdè.

29Bẹ́ẹ̀ náà ni gbogbo àwọn olówó ayé wọn yóò ṣe àsè, wọn yóò sì sìn;

gbogbo àwọn tí ó wọ inú ilẹ̀ lọ yóò kúnlẹ̀ ní iwájú rẹ̀

àti ẹni tí kò lè pa ọkàn ara rẹ̀ mọ́ ni ààyè.

30Irú-ọmọ rẹ̀ yóò sìn ín;

a ó sọ fún àwọn ìran tí ń bọ̀ nípa Olúwa,

31Wọn yóò polongo òdodo rẹ̀

sí àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí,

wí pé, òun ni ó ṣe èyí.

New International Reader’s Version

Psalm 22:1-31

Psalm 22

For the director of music. A psalm of David to the tune of “The Doe of the Morning.”

1My God, my God, why have you deserted me?

Why do you seem so far away when I need you to save me?

Why do you seem so far away that you can’t hear my groans?

2My God, I cry out in the daytime. But you don’t answer.

I cry out at night. But you don’t let me sleep.

3But you rule from your throne as the Holy One.

You are the God Israel praises.

4Our people of long ago put their trust in you.

They trusted in you, and you saved them.

5They cried out to you and were saved.

They trusted in you, and you didn’t let them down.

6Everyone treats me like a worm and not a man.

They hate me and look down on me.

7All those who see me laugh at me.

They shout at me and make fun of me.

They shake their heads at me.

8They say, “He trusts in the Lord.

Let the Lord help him.

If the Lord is pleased with him,

let him save him.”

9But you brought me out of my mother’s body.

You made me trust in you

even when I was at my mother’s breast.

10From the time I was born, you took good care of me.

Ever since I came out of my mother’s body, you have been my God.

11Don’t be far away from me.

Trouble is near,

and there is no one to help me.

12Many enemies are all around me.

They are like strong bulls from the land of Bashan.

13They are like roaring lions that tear to pieces what they kill.

They open their mouths wide to attack me.

14My strength is like water that is poured out on the ground.

I feel as if my bones aren’t connected.

My heart has turned to wax.

It has melted away inside me.

15My mouth is dried up like a piece of broken pottery.

My tongue sticks to the roof of my mouth.

You bring me down to the edge of the grave.

16A group of sinful people has closed in on me.

They are all around me like a pack of dogs.

They have pierced my hands and my feet.

17Everyone can see all my bones right through my skin.

People stare at me. They laugh when I suffer.

18They divide up my clothes among them.

They cast lots for what I am wearing.

19Lord, don’t be so far away from me.

You give me strength. Come quickly to help me.

20Save me from being killed by the sword.

Save the only life I have. Save me from the power of those dogs.

21Save me from the mouths of those lions.

Save me from the horns of those wild oxen.

22I will announce your name to my people.

I will praise you among those who are gathered to worship you.

23You who have respect for the Lord, praise him!

All you people of Jacob, honor him!

All you people of Israel, worship him!

24He has not forgotten the one who is hurting.

He has not turned away from his suffering.

He has not turned his face away from him.

He has listened to his cry for help.

25Because of what you have done,

I will praise you in the whole community of those who worship you.

In front of those who respect you,

I will keep my promises.

26Those who are poor will eat and be satisfied.

Those who seek the Lord will praise him.

May their hearts be filled with new hope!

27People from one end of the earth to the other

will remember and turn to the Lord.

The people of all the nations

will bow down in front of him.

28The Lord is King.

He rules over the nations.

29All rich people of the earth will feast and worship God.

All who go down to the grave will kneel in front of him.

Those who cannot keep themselves alive will kneel.

30Those who are not yet born will serve him.

Those who are born later will be told about the Lord.

31And they will tell people who have not yet been born,

“The Lord has done what is right!”