Saamu 20 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 20:1-9

Saamu 20

Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.

1Olúwa kí ó gbóhùn rẹ ní ọjọ́ ìpọ́njú;

kí orúkọ Ọlọ́run Jakọbu kí ó dáàbò bò ọ́.

2Kí ó rán ìrànlọ́wọ́ sí ọ, láti ibi mímọ́

kí ó sì tì ọ́ lẹ́yìn láti Sioni wá.

3Kí ó sì rántí gbogbo ẹbọ rẹ

kí ó sì gba ẹbọ sísun rẹ. Sela

4Kí ó fi fún ọ gẹ́gẹ́ bi ti èrò ọkàn rẹ

kí ó sì mú gbogbo ìmọ̀ rẹ ṣẹ.

5Àwa yóò hó fún ayọ̀ nígbà tí o bá di aṣẹ́gun

àwa yóò gbé àsíá wa sókè ní orúkọ Ọlọ́run wa.

Kí Ọlọ́run kí ó mú gbogbo ìbéèrè rẹ̀ ṣẹ.

6Nísinsin yìí, èmi mọ̀ wí pé:

Olúwa pa ẹni ààmì òróró rẹ̀ mọ́.

Yóò gbọ́ láti ọ̀run mímọ́ rẹ̀ wá

pẹ̀lú agbára ìgbàlà ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.

7Àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé kẹ̀kẹ́, àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé ẹṣin,

ṣùgbọ́n àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa Ọlọ́run wa.

8Wọ́n wólẹ̀, ní eékún, wọ́n sì ṣubú,

ṣùgbọ́n àwa dìde, a sì dúró ṣinṣin.

9Olúwa, fi ìṣẹ́gun fún ọba!

Dá wa lóhùn nígbà tí a bá ń kígbe pè!

New International Version

Psalms 20:1-9

Psalm 20In Hebrew texts 20:1-9 is numbered 20:2-10.

For the director of music. A psalm of David.

1May the Lord answer you when you are in distress;

may the name of the God of Jacob protect you.

2May he send you help from the sanctuary

and grant you support from Zion.

3May he remember all your sacrifices

and accept your burnt offerings.20:3 The Hebrew has Selah (a word of uncertain meaning) here.

4May he give you the desire of your heart

and make all your plans succeed.

5May we shout for joy over your victory

and lift up our banners in the name of our God.

May the Lord grant all your requests.

6Now this I know:

The Lord gives victory to his anointed.

He answers him from his heavenly sanctuary

with the victorious power of his right hand.

7Some trust in chariots and some in horses,

but we trust in the name of the Lord our God.

8They are brought to their knees and fall,

but we rise up and stand firm.

9Lord, give victory to the king!

Answer us when we call!