Saamu 149 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 149:1-9

Saamu 149

1Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

Ẹ kọrin tuntun sí Olúwa.

Ẹ yìn ín ní àwùjọ àwọn ènìyàn mímọ́.

2Jẹ́ kí Israẹli kí ó ní inú dídùn sí ẹni tí ó dá a

jẹ́ kí àwọn ọmọ Sioni kí ó ní

ayọ̀ nínú ọba wọn.

3Jẹ́ kí wọn kí ó fi ijó yin orúkọ rẹ̀

jẹ́ kí wọn kí ó fi ohun èlò orin kọrin ìyìn sí i.

4Nítorí Olúwa ní inú dídùn sí àwọn ènìyàn rẹ̀

ó fi ìgbàlà dé àwọn onírẹ̀lẹ̀ ládé

5Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mímọ́ kí ó yọ̀ nínú ọlá rẹ̀

kí wọn kí ó máa kọrin fún ayọ̀ ní orí ibùsùn wọn.

6Kí ìyìn Ọlọ́run kí ó wà ní ẹnu wọn

àti idà olójú méjì ní ọwọ́ wọn.

7Láti gba ẹ̀san lára àwọn orílẹ̀-èdè,

àti ìjìyà lára àwọn ènìyàn,

8Láti fi ẹ̀wọ̀n de àwọn ọba wọn

àti láti fi ṣẹkẹ́ṣẹkẹ̀

irin de àwọn ọlọ́lá wọn.

9Láti ṣe ìdájọ́ tí àkọsílẹ̀ rẹ̀ sí wọn

èyí ni ògo àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀.

Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.