Saamu 138 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 138:1-8

Saamu 138

Ti Dafidi

1Èmi yóò yìn ọ́ tinútinú mi gbogbo;

níwájú àwọn òrìṣà ni èmi ó kọrin ìyìn sí ọ.

2Èmi ó máa gbàdúrà sí ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ̀

èmi ó sì máa yin orúkọ rẹ

nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ àti òtítọ́ rẹ;

nítorí ìwọ gbé ọ̀rọ̀ rẹ ga ju orúkọ rẹ lọ.

3Ní ọjọ́ tí mo ké pè é ọ́, ìwọ dá mi lóhùn,

ìwọ sì fi ipa mú mi lára le ní ọkàn mi.

4Gbogbo àwọn ọba ayé yóò yìn ọ́,

Olúwa, ní ìgbà tí wọn bá gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ

5Nítòótọ́, wọn ó máa kọrin ní ipa ọ̀nà Olúwa;

nítorí pé ńlá ni ògo Olúwa.

6Olúwa tilẹ̀ ga, síbẹ̀ ó júbà àwọn onírẹ̀lẹ̀;

ṣùgbọ́n agbéraga ni ó mọ̀ ní òkèrè réré.

7Bí èmi tilẹ̀ ń rìn nínú ìpọ́njú ìwọ ni yóò sọ mi di ààyè;

ìwọ ó na ọwọ́ rẹ sí àwọn ọ̀tá mi,

ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò sì gbà mí.

8Olúwa yóò ṣe ohun tí ń ṣe tèmi láṣepé;

Olúwa, àánú rẹ dúró láéláé;

Má ṣe kọ iṣẹ́ ọwọ́ ara rẹ sílẹ̀.