Saamu 125 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 125:1-5

Saamu 125

Orin fún ìgòkè.

1Àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò dàbí òkè Sioni,

tí a kò lè ṣí ní ìdí, bí kò ṣe pé ó dúró láéláé

2Bí òkè ńlá ti yí Jerusalẹmu ká,

bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yí ènìyàn ká

láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé.

3Nítorí tí ọ̀pá àwọn ènìyàn búburú

kì yóò bà lé ìpín àwọn olódodo;

kí àwọn olódodo kí ó máa ba à

fi ọwọ́ wọn lé ẹ̀ṣẹ̀.

4Olúwa ṣe rere fún àwọn ẹni rere,

àti fún àwọn tí àyà wọn dúró ṣinṣin.

5Bí ó ṣe ti irú àwọn tí wọn yà sí ipa ọ̀nà wíwọ́ wọn;

Olúwa yóò jẹ́ kí wọn lọ pẹ̀lú àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.

Ṣùgbọ́n àlàáfíà yóò wà lórí Israẹli.