Saamu 124 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 124:1-8

Saamu 124

Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi.

1“Ìbá má ṣe pé Olúwa tí ó ti wà fún wa”

ni kí Israẹli kí ó máa wí nísinsin yìí;

2“Ìbá má ṣe pé Olúwa tó wà ní tiwa,”

Nígbà tí àwọn ènìyàn dúró sí wa:

3Nígbà náà ni wọn ò bá gbé wà mì láààyè

nígbà tí ìbínú wọn ru sí wa

4Nígbà náà ni omi

wọ̀n-ọn-nì ìbá bò wá mọ́lẹ̀

5Nígbà náà ni agbéraga

omi ìbá borí ọkàn wa.

6Olùbùkún ni Olúwa, tí kò fi wá fún wọ́n

bí ohun ọdẹ fún eyín wọn.

7Ọkàn wa yọ bí ẹyẹ jáde kúrò nínú okùn apẹyẹ;

okùn já àwa sì yọ.

8Ìrànlọ́wọ́ wa ń bẹ ní orúkọ Olúwa,

tí ó dá ọ̀run òun ayé.