Saamu 121
Orin fún ìgòkè.
1Èmi yóò gbé ojú mi sórí òkè wọ̀n-ọn-nì—
níbo ni ìrànlọ́wọ́ mi yóò ti wá
2Ìrànlọ́wọ́ mi tí ọwọ́ Olúwa wá
Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
3Òun kì yóò jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó yẹ̀;
ẹni tí ó pa ọ́ mọ́ kì í tòògbé.
4Kíyèsi, ẹni tí ń pa Israẹli mọ́,
kì í tòògbé bẹ́ẹ̀ ni kì í sùn.
5Olúwa ni olùpamọ́ rẹ;
Olúwa ní òjìji rẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ
6Oòrùn kì yóò pa ọ́ ní ìgbà ọ̀sán
tàbí òṣùpá ní ìgbà òru.
7Olúwa yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ibi gbogbo
yóò pa ọkàn rẹ mọ́
8Olúwa yóò pa àlọ àti ààbọ̀ rẹ mọ́
láti ìgbà yìí lọ àti títí láéláé.
Psalm 121
A song for those who go up to Jerusalem to worship the Lord.
1I look up to the mountains.
Where does my help come from?
2My help comes from the Lord.
He is the Maker of heaven and earth.
3He won’t let your foot slip.
He who watches over you won’t get tired.
4In fact, he who watches over Israel
won’t get tired or go to sleep.
5The Lord watches over you.
The Lord is like a shade tree at your right hand.
6The sun won’t harm you during the day.
The moon won’t harm you during the night.
7The Lord will keep you from every kind of harm.
He will watch over your life.
8The Lord will watch over your life no matter where you go,
both now and forever.