Saamu 118 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 118:1-29

Saamu 118

1118.1: 1Ki 16.34; 2Ki 5.13; 7.3; Es 3.11; Sm 100.5; 106.1; 107.1; 136.1; Jr 33.11.Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára;

àánú rẹ̀ dúró láéláé.

2Jẹ́ kí Israẹli wí pé:

“Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.

3Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé:

“Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.

4Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé:

“Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”

5Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa,

ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.

6118.6: Hb 13.6.Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù.

Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?

7Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi

Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.

8Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa

ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.

9Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa

ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.

10Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri,

ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò

11Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́,

ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù

12Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin,

ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún;

ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.

13Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú,

ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.

14Olúwa ni agbára àti orin mi;

ó sì di ìgbàlà mi.

15Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo:

“Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!

16Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga;

ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”

17Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè,

èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.

18Olúwa bá mi wí gidigidi,

ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.

19Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi:

èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.

20Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa

ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.

21Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn;

ìwọ sì di ìgbàlà mi.

22118.22-23: Mt 21.42; Mk 12.10-11; Lk 20.17; Ap 4.11; 1Pt 2.7.Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀,

ni ó di pàtàkì igun ilé;

23Olúwa ti ṣe èyí,

ó ṣe ìyanu ní ojú wa.

24Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá:

ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.

25118.25-26: Mt 21.9; 23.39; Mk 11.9-10; Lk 13.35; 19.38; Jh 12.13.Olúwa, gbà wá;

Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.

26Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa.

Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.

27Olúwa ni Ọlọ́run,

ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára

pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́

ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀

ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.

28Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ;

ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.

29Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun;

nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.