Saamu 116 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 116:1-19

Saamu 116

1Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi;

ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.

2Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi,

èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.

3Okùn ikú yí mi ká,

ìrora isà òkú wá sórí mi;

ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi.

4Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa:

Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”

5Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo;

Ọlọ́run wa kún fún àánú.

6Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́

nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.

7Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ,

nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.

8Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi

kúrò lọ́wọ́ ikú,

ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé,

àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,

9Nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa

ní ilẹ̀ alààyè.

10116.10: 2Kọ 4.13.Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé,

“èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.

11Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé

“Èké ni gbogbo ènìyàn”.

12Kí ni èmi yóò san fún Olúwa

nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?

13Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè

èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.

14Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa

ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.

15Iyebíye ní ojú Olúwa

àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.

16Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́;

èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ;

ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.

17Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ

èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa

18Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa

ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,

19Nínú àgbàlá ilé Olúwa

ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu.

Ẹ yin Olúwa.

New International Version

Psalms 116:1-19

Psalm 116

1I love the Lord, for he heard my voice;

he heard my cry for mercy.

2Because he turned his ear to me,

I will call on him as long as I live.

3The cords of death entangled me,

the anguish of the grave came over me;

I was overcome by distress and sorrow.

4Then I called on the name of the Lord:

Lord, save me!”

5The Lord is gracious and righteous;

our God is full of compassion.

6The Lord protects the unwary;

when I was brought low, he saved me.

7Return to your rest, my soul,

for the Lord has been good to you.

8For you, Lord, have delivered me from death,

my eyes from tears,

my feet from stumbling,

9that I may walk before the Lord

in the land of the living.

10I trusted in the Lord when I said,

“I am greatly afflicted”;

11in my alarm I said,

“Everyone is a liar.”

12What shall I return to the Lord

for all his goodness to me?

13I will lift up the cup of salvation

and call on the name of the Lord.

14I will fulfill my vows to the Lord

in the presence of all his people.

15Precious in the sight of the Lord

is the death of his faithful servants.

16Truly I am your servant, Lord;

I serve you just as my mother did;

you have freed me from my chains.

17I will sacrifice a thank offering to you

and call on the name of the Lord.

18I will fulfill my vows to the Lord

in the presence of all his people,

19in the courts of the house of the Lord

in your midst, Jerusalem.

Praise the Lord.116:19 Hebrew Hallelu Yah