Saamu 107 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 107:1-43

ÌWÉ KARÙN-ÚN

Saamu 107–150

Saamu 107

1Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun;

nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.

2Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà Olúwa kí ó wí báyìí, àwọn

ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,

3Àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì

láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn,

láti àríwá àti Òkun wá.

4Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí,

wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tí

wọn ó máa gbé

5Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n,

ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.

6Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókè

Olúwa nínú ìdààmú wọn,

ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn

7Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlú

tí wọn lè máa gbé

8Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́

ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,

9Nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́run

ó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.

10Ọ̀pọ̀ jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú,

a dè wọ́n ní ìrora àti ní irin,

11Nítorí tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀

Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ìbáwí Ọ̀gá-ògo,

12Ó sì fi ìkorò rẹ àyà wọn sílẹ̀;

wọn ṣubú, kò sì ṣí ẹni tí

yóò ràn wọ́n lọ́wọ́.

13Ní ìgbà náà wọ́n ké pe

Olúwa nínú ìdààmú wọn,

ó sì gbà wọ́n nínú ìṣòro wọn

14Ó mú wọn jáde kúrò nínú

òkùnkùn àti òjìji ikú,

ó sì fa irin tí wọ́n fi dè wọ́n já.

15Ẹ jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa! Nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí ọmọ ènìyàn.

16Nítorí tí ó já ìlẹ̀kùn idẹ wọ̀n-ọn-nì

ó sì ké irin wọn ní agbede-méjì.

17Ọ̀pọ̀ di aṣiwèrè nítorí ìrékọjá wọn

wọ́n sì pọ́n wọn lójú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn

18Wọ́n kọ gbogbo oúnjẹ

wọ́n sì súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú.

19Nígbà náà wọ́n kígbe sí Olúwa nínú

ìṣòro wọn, ó sì yọ wọ́n nínú ìdààmú wọn

20Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀, ara wọn sì dá

ó sì yọ wọ́n nínú isà òkú.

21Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.

22Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́

kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ̀.

23Àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun nínú ọkọ̀

ojú omi, wọ́n jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.

24Wọ́n rí iṣẹ́ Olúwa,

àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ nínú ibú

25Nítorí tí ó pàṣẹ, ó sì mú ìjì fẹ́

tí ó gbé ríru rẹ̀ sókè.

26Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọ́n sì

tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú:

nítorí ìpọ́njú, ọkàn wọn di omi

27Wọ́n ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn:

ọgbọ́n wọn sì dé òpin.

28Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókè

Olúwa nínú ìdààmú wọn,

ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.

29Ó sọ ìjì di ìdákẹ́rọ́rọ́

bẹ́ẹ̀ ni ríru omi rẹ̀ dúró jẹ́ẹ́;

30Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀,

ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ,

31Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún

Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀

àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.

32Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárín àwọn ènìyàn

kí wọn kí ó sì yìn ín ní ìjọ àwọn àgbàgbà.

33Ó sọ odò di aginjù,

àti orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.

34Ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀

nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú rẹ̀;

35O sọ aginjù di adágún omi àti

ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi

36Níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà,

wọ́n sì pilẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé

37Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàrà

tí yóò máa so èso tí ó dára;

38Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iye

kò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dínkù.

39Nígbà náà, ọjọ́ wọn kúrú,

ìnira, ìpọ́njú àti ìṣòro wọn sì dínkù

40Ẹni tí ó da ẹ̀gàn lu ọmọ-aládé

ó sì mú wọn rìn níbi tí ọ̀nà kò sí

41Ṣùgbọ́n ó gbé aláìní sókè kúrò nínú ìnira

ó mú ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran

42Àwọn tí ó dúró sì rí i, inú wọn sì dùn

ṣùgbọ́n gbogbo olùṣe búburú yóò pa ẹnu rẹ̀ mọ́.

43Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyí

kí ó wo títóbi ìfẹ́ Olúwa.

New International Reader’s Version

Psalm 107:1-43

Book V

Psalms 107–150

Psalm 107

1Give thanks to the Lord, because he is good.

His faithful love continues forever.

2Let those who have been set free by the Lord tell their story.

He set them free from the power of the enemy.

3He brought them back from other lands.

He brought them back from east and west, from north and south.

4Some of them wandered in deserts that were dry and empty.

They couldn’t find a city where they could make their homes.

5They were hungry and thirsty.

Their lives were slipping away.

6Then they cried out to the Lord because of their problems.

And he saved them from their troubles.

7He led them straight

to a city where they could make their homes.

8Let them give thanks to the Lord for his faithful love.

Let them give thanks for the wonderful things he does for people.

9He gives those who are thirsty all the water they want.

He gives those who are hungry all the good food they can eat.

10Others lived in the deepest darkness.

They suffered as prisoners in iron chains.

11That’s because they hadn’t obeyed the commands of God.

They had refused to follow the plans of the Most High God.

12So he made them do work that was hard and bitter.

They tripped and fell, and there was no one to help them.

13Then they cried out to the Lord because of their problems.

And he saved them from their troubles.

14He brought them out of the deepest darkness.

He broke their chains off.

15Let them give thanks to the Lord for his faithful love.

Let them give thanks for the wonderful things he does for people.

16He breaks down gates that are made of bronze.

He cuts through bars that are made of iron.

17Others were foolish. They suffered because of their sins.

They suffered because they wouldn’t obey the Lord.

18They refused to eat anything.

They came close to passing through the gates of death.

19Then they cried out to the Lord because of their problems.

And he saved them from their troubles.

20He gave his command and healed them.

He saved them from the grave.

21Let them give thanks to the Lord for his faithful love.

Let them give thanks for the wonderful things he does for people.

22Let them sacrifice thank offerings.

Let them talk about what he has done as they sing with joy.

23Some people sailed out on the ocean in ships.

They traded goods on the mighty waters.

24They saw the works of the Lord.

They saw the wonderful deeds he did on the ocean.

25He spoke and stirred up a storm.

It lifted the waves high.

26They rose up to the heavens. Then they went down deep into the ocean.

In that kind of danger the people’s boldness melted away.

27They were unsteady like people who have become drunk.

They didn’t know what to do.

28Then they cried out to the Lord because of their problems.

And he brought them out of their troubles.

29He made the storm as quiet as a whisper.

The waves of the ocean calmed down.

30The people were glad when the ocean became calm.

Then he guided them to the harbor they were looking for.

31Let them give thanks to the Lord for his faithful love.

Let them give thanks for the wonderful things he does for people.

32Let them honor him among his people who gather for worship.

Let them praise him in the meeting of the elders.

33He turned rivers into a desert.

He turned flowing springs into thirsty ground.

34He turned land that produced crops into a salty land where nothing could grow.

He did it because the people who lived there were evil.

35He turned the desert into pools of water.

He turned the dry and cracked ground into flowing springs.

36He brought hungry people there to live.

They built a city where they could make their homes.

37They planted fields and vineyards

that produced large crops.

38He blessed the people, and they greatly increased their numbers.

He kept their herds from getting smaller.

39Then the number of God’s people got smaller.

They were made humble by trouble, suffering and sorrow.

40The God who looks down on proud nobles

made them wander in a desert where no one lives.

41But he lifted needy people out of their suffering.

He made their families increase like flocks of sheep.

42Honest people see it and are filled with joy.

But no one who is evil has anything to say.

43Let those who are wise pay attention to these things.

Let them think about the loving deeds of the Lord.