Saamu 106 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 106:1-48

Saamu 106

1106.1: 1Ki 16.34.Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún

Olúwa, nítorí tí ó ṣeun.

Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun;

Nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.

2Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa,

ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?

3Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́?

Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.

4Rántí mi, Olúwa,

Nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn,

wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,

5Kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn,

kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn,

ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.

6Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe,

àwa ti ṣe ohun tí kò dá a,

a sì ti hùwà búburú

7Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti,

iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn,

wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ,

gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun pupa

8Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ

láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀

9O bá Òkun pupa wí, ó sì gbẹ;

o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù

10O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn

láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n

11Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn, bẹ́ẹ̀ ni

kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.

12Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́

wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.

13Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe

wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ

14Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́

nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò

15Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún

ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.

16Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose

pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.

17Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì

ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀

18Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀;

iná jo àwọn ènìyàn búburú.

19Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù

wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.

20Wọ́n pa ògo wọn dà

sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.

21Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n

ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,

22Iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu

àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun pupa

23Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run

bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn,

tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà

tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.

24Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà

wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.

25Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn

wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.

26Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè

kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,

27Láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè

láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.

28Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori,

wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà

29Wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe

àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.

30Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i,

àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán

31A sì ka èyí sí òdodo fún un àti

fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀

32Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú,

ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.

33Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ẹ̀mí Ọlọ́run.

Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.

34Wọn kò pa àwọn ènìyàn run

gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti sọ fún wọn,

35Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè,

wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn

36Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn

tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.

37Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ

àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.

38Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀.

Ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn

ọmọbìnrin wọn.

Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀

39Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́,

wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.

40Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀

ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀

41Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́,

àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.

42Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú

wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.

43Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n,

Síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i

wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

44Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro

nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn;

45Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn

Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.

46Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn

ó mú wọn rí àánú.

47106.47-48: 1Ki 16.35-36.Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa,

kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí,

láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ

láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.

48Olùbùkún ni Olúwa,

Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran.

Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!”

Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!

New International Version

Psalms 106:1-48

Psalm 106

1Praise the Lord.106:1 Hebrew Hallelu Yah; also in verse 48

Give thanks to the Lord, for he is good;

his love endures forever.

2Who can proclaim the mighty acts of the Lord

or fully declare his praise?

3Blessed are those who act justly,

who always do what is right.

4Remember me, Lord, when you show favor to your people,

come to my aid when you save them,

5that I may enjoy the prosperity of your chosen ones,

that I may share in the joy of your nation

and join your inheritance in giving praise.

6We have sinned, even as our ancestors did;

we have done wrong and acted wickedly.

7When our ancestors were in Egypt,

they gave no thought to your miracles;

they did not remember your many kindnesses,

and they rebelled by the sea, the Red Sea.106:7 Or the Sea of Reeds; also in verses 9 and 22

8Yet he saved them for his name’s sake,

to make his mighty power known.

9He rebuked the Red Sea, and it dried up;

he led them through the depths as through a desert.

10He saved them from the hand of the foe;

from the hand of the enemy he redeemed them.

11The waters covered their adversaries;

not one of them survived.

12Then they believed his promises

and sang his praise.

13But they soon forgot what he had done

and did not wait for his plan to unfold.

14In the desert they gave in to their craving;

in the wilderness they put God to the test.

15So he gave them what they asked for,

but sent a wasting disease among them.

16In the camp they grew envious of Moses

and of Aaron, who was consecrated to the Lord.

17The earth opened up and swallowed Dathan;

it buried the company of Abiram.

18Fire blazed among their followers;

a flame consumed the wicked.

19At Horeb they made a calf

and worshiped an idol cast from metal.

20They exchanged their glorious God

for an image of a bull, which eats grass.

21They forgot the God who saved them,

who had done great things in Egypt,

22miracles in the land of Ham

and awesome deeds by the Red Sea.

23So he said he would destroy them—

had not Moses, his chosen one,

stood in the breach before him

to keep his wrath from destroying them.

24Then they despised the pleasant land;

they did not believe his promise.

25They grumbled in their tents

and did not obey the Lord.

26So he swore to them with uplifted hand

that he would make them fall in the wilderness,

27make their descendants fall among the nations

and scatter them throughout the lands.

28They yoked themselves to the Baal of Peor

and ate sacrifices offered to lifeless gods;

29they aroused the Lord’s anger by their wicked deeds,

and a plague broke out among them.

30But Phinehas stood up and intervened,

and the plague was checked.

31This was credited to him as righteousness

for endless generations to come.

32By the waters of Meribah they angered the Lord,

and trouble came to Moses because of them;

33for they rebelled against the Spirit of God,

and rash words came from Moses’ lips.106:33 Or against his spirit, / and rash words came from his lips

34They did not destroy the peoples

as the Lord had commanded them,

35but they mingled with the nations

and adopted their customs.

36They worshiped their idols,

which became a snare to them.

37They sacrificed their sons

and their daughters to false gods.

38They shed innocent blood,

the blood of their sons and daughters,

whom they sacrificed to the idols of Canaan,

and the land was desecrated by their blood.

39They defiled themselves by what they did;

by their deeds they prostituted themselves.

40Therefore the Lord was angry with his people

and abhorred his inheritance.

41He gave them into the hands of the nations,

and their foes ruled over them.

42Their enemies oppressed them

and subjected them to their power.

43Many times he delivered them,

but they were bent on rebellion

and they wasted away in their sin.

44Yet he took note of their distress

when he heard their cry;

45for their sake he remembered his covenant

and out of his great love he relented.

46He caused all who held them captive

to show them mercy.

47Save us, Lord our God,

and gather us from the nations,

that we may give thanks to your holy name

and glory in your praise.

48Praise be to the Lord, the God of Israel,

from everlasting to everlasting.

Let all the people say, “Amen!”

Praise the Lord.