Saamu 106 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 106:1-48

Saamu 106

1106.1: 1Ki 16.34.Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún

Olúwa, nítorí tí ó ṣeun.

Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun;

Nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.

2Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa,

ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?

3Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́?

Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.

4Rántí mi, Olúwa,

Nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn,

wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,

5Kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn,

kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn,

ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.

6Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe,

àwa ti ṣe ohun tí kò dá a,

a sì ti hùwà búburú

7Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti,

iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn,

wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ,

gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun pupa

8Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ

láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀

9O bá Òkun pupa wí, ó sì gbẹ;

o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù

10O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn

láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n

11Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn, bẹ́ẹ̀ ni

kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.

12Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́

wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.

13Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe

wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ

14Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́

nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò

15Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún

ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.

16Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose

pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.

17Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì

ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀

18Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀;

iná jo àwọn ènìyàn búburú.

19Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù

wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.

20Wọ́n pa ògo wọn dà

sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.

21Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n

ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,

22Iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu

àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun pupa

23Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run

bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn,

tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà

tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.

24Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà

wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.

25Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn

wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.

26Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè

kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,

27Láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè

láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.

28Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori,

wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà

29Wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe

àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.

30Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i,

àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán

31A sì ka èyí sí òdodo fún un àti

fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀

32Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú,

ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.

33Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ẹ̀mí Ọlọ́run.

Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.

34Wọn kò pa àwọn ènìyàn run

gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti sọ fún wọn,

35Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè,

wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn

36Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn

tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.

37Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ

àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.

38Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀.

Ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn

ọmọbìnrin wọn.

Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀

39Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́,

wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.

40Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀

ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀

41Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́,

àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.

42Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú

wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.

43Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n,

Síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i

wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

44Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro

nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn;

45Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn

Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.

46Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn

ó mú wọn rí àánú.

47106.47-48: 1Ki 16.35-36.Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa,

kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí,

láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ

láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.

48Olùbùkún ni Olúwa,

Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran.

Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!”

Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!