Saamu 105 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 105:1-45

Saamu 105

1105.1-15: 1Ki 16.8-22.Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀:

Jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè;

2Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i;

sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.

3Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀:

Jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.

4Olúwa àti ipá rẹ̀;

wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.

5Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe,

ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,

6Ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀,

ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.

7Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa:

ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.

8105.8-9: Lk 1.72-73.Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé,

ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹgbẹ̀rún ìran,

9májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu,

ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.

10Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ

sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:

11“Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani

gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”

12Nígbà tí wọn kéré níye,

wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀

13wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè,

láti ìjọba kan sí èkejì.

14Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú;

ó fi ọba bú nítorí tiwọn:

15“Má ṣe fọwọ́ kan ẹni ààmì òróró mi, má sì ṣe wòlíì mi níbi.”

16Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà

ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;

17Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn

Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.

18Wọn fi ṣẹkẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀

a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin

19Títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ

títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.

20Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀

àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀

21Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀

aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,

22Gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa

ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé

kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.

23Israẹli wá sí Ejibiti;

Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.

24Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i

ó sì mú wọn lágbára jù

àwọn ọ̀tá wọn lọ

25Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn

láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.

26Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀

àti Aaroni tí ó ti yàn

27Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn

ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.

28Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú

wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.

29Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀,

ó pa ẹja wọn.

30Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá,

èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.

31Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde,

ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn

32Ó sọ òjò di yìnyín,

àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;

33Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn

ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.

34Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé,

àti kòkòrò ní àìníye,

35Wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn,

wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run

36Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn,

ààyò gbogbo ipá wọn.

37Ó mú Israẹli jáde

ti òun ti fàdákà àti wúrà,

nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.

38Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ,

nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.

39Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí,

àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́

40Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá,

ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.

41Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde;

gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.

42Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀

àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.

43Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde

pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀

44Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà,

wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,

45Kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́

kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀.

Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

New International Reader’s Version

Psalm 105:1-45

Psalm 105

1Give praise to the Lord and announce who he is.

Tell the nations what he has done.

2Sing to him, sing praise to him.

Tell about all the wonderful things he has done.

3Praise him, because his name is holy.

Let the hearts of those who trust in the Lord be glad.

4Seek the Lord and the strength he gives.

Always seek him.

5Remember the wonderful things he has done.

Remember his miracles and how he judged our enemies.

6Remember what he has done, you children of his servant Abraham.

Remember it, you people of Jacob, God’s chosen ones.

7He is the Lord our God.

He judges the whole earth.

8He will keep his covenant forever.

He will keep his promise for all time to come.

9He will keep the covenant he made with Abraham.

He will keep the promise he made to Isaac.

10He made it stand as a law for Jacob.

He made it stand as a covenant for Israel that will last forever.

11He said, “I will give you the land of Canaan.

It will belong to you.”

12At first there weren’t very many of God’s people.

There were only a few, and they were strangers in the land.

13They wandered from nation to nation.

They wandered from one kingdom to another.

14But God didn’t allow anyone to treat them badly.

To keep them safe, he gave a command to kings.

15He said to them, “Do not touch my anointed ones.

Do not harm my prophets.”

16He made the people in the land go hungry.

He destroyed all their food supplies.

17He sent a man ahead of them into Egypt.

That man was Joseph. He had been sold as a slave.

18The Egyptians put his feet in chains.

They put an iron collar around his neck.

19He was in prison until what he said would happen came true.

The word of the Lord proved that he was right.

20The king of Egypt sent for Joseph and let him out of prison.

The ruler of many nations set him free.

21He put Joseph in charge of his palace.

He made him ruler over everything he owned.

22Joseph was in charge of teaching the princes.

He taught the elders how to think and live wisely.

23Then the rest of Jacob’s family went to Egypt.

The people of Israel lived as outsiders in the land of Ham.

24The Lord gave his people so many children

that there were too many of them for their enemies.

25He made the Egyptians hate his people.

The Egyptians made evil plans against them.

26The Lord sent his servant Moses to the king of Egypt.

He sent Aaron, his chosen one, along with him.

27The Lord gave them the power to do signs among the Egyptians.

They did his wonders in the land of Ham.

28The Lord sent darkness over the land.

He did it because the Egyptians had refused to obey his words.

29He turned their rivers and streams into blood.

He caused the fish in them to die.

30Their land was covered with frogs.

Frogs even went into the bedrooms of the rulers.

31The Lord spoke, and large numbers of flies came.

Gnats filled the whole country.

32He turned their rain into hail.

Lightning flashed all through their land.

33He destroyed their vines and fig trees.

He broke down the trees in Egypt.

34He spoke, and the locusts came.

There were so many of them they couldn’t be counted.

35They ate up every green thing in the land.

They ate up what the land produced.

36Then he killed the oldest son of every family in Egypt.

He struck down the oldest of all their sons.

37He brought the people of Israel out of Egypt.

The Egyptians loaded them down with silver and gold.

From among the tribes of Israel no one got tired or fell down.

38The Egyptians were glad when the people of Israel left.

They were terrified because of Israel.

39The Lord spread out a cloud to cover his people.

He gave them a fire to light up the night.

40They asked for meat, and he brought them quail.

He fed them well with manna, the bread of heaven.

41He broke open a rock, and streams of water poured out.

They flowed like a river in the desert.

42He remembered the holy promise

he had made to his servant Abraham.

43His chosen people shouted for joy

as he brought them out of Egypt.

44He gave them the lands of other nations.

He let them take over what others had worked for.

45He did it so they might obey his rules

and follow his laws.

Praise the Lord.