Saamu 101 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 101:1-8

Saamu 101

Ti Dafidi. Saamu.

1Èmi yóò kọrin ìfẹ́ àti òdodo;

sí ọ Olúwa, èmi yóò máa kọrin ìyìn.

2Èmi yóò máa rin ìrìn mi pẹ̀lú ọgbọ́n láìlẹ́ṣẹ̀,

ìgbà wo ni ìwọ yóò wá sí ọ̀dọ̀ mi?

Èmi yóò máa rìn ní ilé mi

pẹ̀lú àyà pípé.

3Èmi kì yóò gbé ohun búburú sí iwájú mi:

iṣẹ́ àwọn tí ó yapa ni èmi kórìíra.

Wọn kì yóò rọ̀ mọ́ mi.

4Agídí ọkàn yóò kúrò lọ́dọ̀ mi;

Èmi kì yóò mọ ènìyàn búburú.

5Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń sọ̀rọ̀ ẹnìkejì rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀,

òun ní èmi yóò gé kúrò

ẹni tí ó bá gbé ojú rẹ̀ ga tí ó sì ní ìgbéraga àyà,

òun ní èmi kì yóò faradà fún.

6Ojú mi yóò wà lára àwọn olóòtítọ́ lórí ilẹ̀,

kí wọn kí ó lè máa bá mi gbé;

ẹni tí ó bá n rin ọ̀nà pípé

òun ni yóò máa sìn mí.

7Ẹni tí ó bá ń ṣe ẹ̀tàn, kì yóò gbé ilé mi,

kò sí ẹni tí ń ṣèké tí yóò dúró ní iwájú mi.

8Ní ojoojúmọ́ ní èmi yóò wá máa pa a lẹ́nu mọ

gbogbo àwọn ènìyàn búburú ilẹ̀ náà;

èmi yóò gé àwọn olùṣe búburú

kúrò ní ìlú Olúwa.