Saamu 10 – YCB & KSS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 10:1-18

Saamu 10

1Èéha ti ṣe, Olúwa, tí ìwọ fi dúró ní òkè réré?

Èéha ti ṣe, tí ìwọ fi ara rẹ pamọ́ ní ìgbà ìpọ́njú?

2Nínú àrékérekè ni ènìyàn búburú tí mu aláìlera,

ẹni ti ó mú nínú ìdẹ̀kùn àrékérekè rẹ̀.

3Nítorí ènìyàn búburú ń ṣògo ìfẹ́ inú ọkàn rẹ̀;

Ó bùkún olójúkòkòrò, ó sì ń kẹ́gàn Olúwa

4Ènìyàn búburú kò lè rí nínú ìgbéraga rẹ̀;

kò sí ààyè fún Ọlọ́run nínú gbogbo èrò rẹ̀;

5Ọ̀nà rẹ̀ ń gún régé nígbà gbogbo;

òun ń gbéraga, òfin rẹ̀ sì jìnnà sí i;

òun kẹ́gàn àwọn ọ̀tá rẹ̀.

6O wí fún ara rẹ̀, “Kò sí ohun tí ó lè mì mí;

Inú mi yóò máa dùn nígbà gbogbo, èmi kò sì ní ní wàhálà.”

710.7: Ro 3.14.Ẹnu rẹ̀ kún fún ègún àti irọ́ àti ìtànjẹ;

wàhálà àti ohun búburú wà lábẹ́ ahọ́n rẹ̀.

8Ó lúgọ ní bùba nítòsí ìletò;

Ògo níbi ìkọ̀kọ̀ láti pa aláìṣẹ̀.

Ojú rẹ̀ ń ṣọ́ àwọn tálákà ní ìkọ̀kọ̀.

9Ó ba ní ní bùba bí i kìnnìún nínú pàǹtí;

Ó ba ní bùba láti mú àwọn aláìní ìrànwọ́;

ó mú àwọn aláìlólùrànlọ́wọ́, ó sì wọ́ wọn lọ sínú àwọ̀n rẹ̀.

10Ó ba, ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀;

kí tálákà ba à le bọ́ sí ọwọ́ agbára rẹ̀.

11Ó wí fún ara rẹ̀, “Ọlọ́run ti gbàgbé;

Ó pa ojú rẹ̀ mọ́, òun kì yóò rí i láéláé.”

12Dìde, Olúwa! Gbé ọwọ́ rẹ sókè, Ọlọ́run.

Má ṣe gbàgbé àwọn olùpọ́njú.

13Èéṣe tí ènìyàn búburú ṣe ń kẹ́gàn Ọlọ́run?

Èéṣe tí o fi wí nínú ọkàn ara rẹ̀,

“Kò ní pè mí láti ṣe ìṣirò”?

14Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni ó rí wàhálà àti ìrora;

Ìwọ rò láti fi sí ọwọ́ rẹ.

Tálákà fi ara rẹ̀ jì fún ọ;

Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ àwọn aláìní baba.

15Ṣẹ́ apá àwọn ènìyàn búburú àti ènìyàn ibi;

pè é láti wá ṣírò fún ìwà ìkà rẹ̀

tí a kò le è rí.

16Olúwa ń jẹ ọba láé àti láéláé;

àwọn orílẹ̀-èdè yóò ṣègbé lórí ilé rẹ.

17Ìwọ́ gbọ́, Olúwa, ìfẹ́ àwọn tí a ni lára;

Ìwọ gbà wọ́n níyànjú, ó sì gbọ́ igbe wọn,

18Láti ṣe ìdájọ́ àwọn aláìní baba àti àwọn ti a ni lára,

kí ọkùnrin, tí ó wà ní ayé,

kí ó má ṣe dẹ́rùbà ni mọ́.

Kurdi Sorani Standard

زەبوورەکان 10:1-18

زەبووری 10

1ئەی یەزدان، بۆچی لە دوورەوە وەستاویت؟

بۆچی لە کاتی تەنگانە خۆت دەشاریتەوە؟

2بەدکاران لە لووتبەرزییان ڕاوی هەژار دەکەن،

گرفتاری ئەو پیلانەیان دەکەن کە بۆیان دادەنێن.

3کەسی بەدکار شانازی بە ئارەزووە خراپەکانی دڵییەوە دەکات،

داوای بەرەکەت بۆ چاوبرسی دەکات و کفر بە یەزدان دەکات.

4بەدکار لە لووتبەرزی خۆی باکی بە یەزدان نییە،

هەموو بیرکردنەوەی ئەوەیە کە: «خودا نییە.»

5هەمیشە ڕێگاکانی سەرکەوتووە،

لە حوکمەکانی خودا ناگات،

ناحەزەکانی خۆی بە هیچ دەزانێت.

6لە دڵی خۆیدا دەڵێت: «هیچ شتێک ناملەقێنێت،

هەموو کاتێک دڵخۆش دەبم و هەرگیز تووشی بەڵا نابم.»

7دەمی پڕە لە نەفرەت و درۆ و هەڕەشە،

بەڵا و گوناه لەبن زمانیەتی.

8لە نزیکی گوندەکان بۆسە دادەنێت،

خۆی دەشارێتەوە بۆ کوشتنی بێتاوانان.

9وەک شێر خۆی مات دەکات،

خۆی مات دەکات بۆ گرتنی بەستەزمانان،

بەستەزمانان گرفتاری ئەو داوە دەکات کە بۆی ناونەتەوە و ڕاپێچیان دەکات.

10نێچیرەکانی وردوخاش دەکات، دەڕووخێن،

دەکەونە ژێر هێزی ئەوەوە.

11لە دڵی خۆیدا دەڵێت: «خودا ئاگای لێ نییە،

چاوی خۆی نوقاندووە و هەرگیز نامبینێت.»

12ئەی یەزدان، ڕاپەڕە! ئەی خودایە، دەستت بەرز بکەرەوە،

ستەملێکراوان لەبیر مەکە.

13چۆن دەبێت کەسی بەدکار کفر بە خودا بکات؟

بۆچی لە دڵی خۆیدا بڵێت: «خودا لێم ناپێچێتەوە؟»

14بەڵام تۆ ئەی خودایە، ئازار و تەنگانە دەبینیت،

لێت دیارە و کاردانەوەت هەیە،

ستەملێکراوان خۆیان داوەتە دەستی تۆ،

تۆش هەمیشە یارمەتیدەری هەتیوانیت.

15بازووی بەدکاران و خراپەکاران بشکێنە،

تەنانەت لەسەر ئەو خراپانەش لێیان بپێچەوە کە نابینرێن.

16یەزدان پاشایە هەتاهەتایە،

نەتەوەکان لە خاکەکەی لەناودەچن.

17ئەی یەزدان، تۆ گوێ لە داواکاری ستەملێکراوان دەگریت،

دڵیان دەچەسپێنی و گوێیان لێ دەگریت،

18بۆ پارێزگاری لە هەتیوان و زۆرلێکراوان،

تاکو لەمەولا مرۆڤی سەر زەوی نەیان ترسێنێت.