Romu 1 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Romu 1:1-32

Ọ̀rọ̀ ìkíni Paulu sí àwọn àyànfẹ́

11.1: Ap 9.15; 13.2; 1Kọ 1.1; 2Kọ 1.1; Ga 1.15.Paulu, ìránṣẹ́ Jesu Kristi, ẹni tí a ti pè láti jẹ́ aposteli, tí a sì ti yà sọ́tọ̀ láti wàásù ìhìnrere Ọlọ́run, 2ìhìnrere tí ó ti ṣe ìlérí tẹ́lẹ̀ rí láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ nínú ìwé Mímọ́. 3Ní ti Ọmọ rẹ̀, ẹni tí a bí láti inú irú-ọmọ Dafidi nípa ti ara, 4ẹni tí a pinnu rẹ̀ láti jẹ́ Ọmọ Ọlọ́run nínú agbára gẹ́gẹ́ bí Ẹ̀mí ìwà mímọ́, nípa àjíǹde kúrò nínú òkú, àní Jesu Kristi Olúwa wa. 51.5: Ap 26.16-18; Ro 15.18; Ga 2.7,9.Láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwa rí oore-ọ̀fẹ́ àti jíjẹ́ aposteli gbà, fún ìgbọ́ràn ìgbàgbọ́ láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè, nítorí orúkọ rẹ̀. 6Ẹ̀yin pẹ̀lú si wa lára àwọn tí a pè sọ́dọ̀ Jesu Kristi.

71.7: 1Kọ 1.3; 2Kọ 1.2; Ga 1.3; Ef 1.2; Fp 1.2; Kl 1.2; 1Tẹ 1.2; 2Tẹ 1.2; 1Tm 1.2; 2Tm 1.2; Tt 1.4; Fm 3; 2Jh 3.Sí gbogbo àwọn àyànfẹ́ Ọlọ́run tí ó wà ní Romu tí a ti pè láti jẹ́ ènìyàn mímọ́:

Oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà fún yín láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa àti láti ọ̀dọ̀ Olúwa wa Jesu Kristi.

Ìfojúsọ́nà Paulu láti bẹ Romu wò

81.8: Ro 16.19.Ní àkọ́kọ́, mo dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run nípasẹ̀ Jesu Kristi fún gbogbo yín, nítorí a ń ròyìn ìgbàgbọ́ yin káàkiri gbogbo ayé. 9Ọlọ́run ṣá à ni ẹlẹ́rìí mi, ẹni tí èmí ń fi gbogbo ẹ̀mí mi sìn nínú ìhìnrere Ọmọ rẹ̀, bí ó ti ṣe pé ní àìsimi ni èmí ń rántí yín nígbà gbogbo nínú àdúrà mi 101.10: Ro 15.23,32; Ap 19.21.nínú àdúrà mi ìgbà gbogbo; mo tún ń gbàdúrà wí pé nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run kí ọ̀nà ó ṣí fún mi láti wá sọ́dọ̀ yín.

11Nítorí èmi ń fẹ́ gidigidi láti tọ̀ yín wá, kí èmi lè fún yín ní ẹ̀bùn ẹ̀mí díẹ̀, kí a bá a le sọ yín di alágbára nínú Olúwa, 12èyí nì ni pé, kí a lè jẹ́ ìwúrí fún ara wa nípa ìgbàgbọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan wa. 131.13: Ro 15.22.Mo fẹ́ kí ẹ mọ èyí, ẹ̀yin ará mi, pé mo ti gbìyànjú lọ́pọ̀ ìgbà láti tọ̀ yín wá, (ṣùgbọ́n ìdíwọ́ wà fún mi), kí èmi ki ó lè jèrè ọkàn díẹ̀ láàrín yín, gẹ́gẹ́ bí mo ti ní láàrín àwọn aláìkọlà yòókù.

141.14: 1Kọ 9.16.Nítorí mo jẹ́ ajigbèsè sí Giriki àti sí àwọn aláìgbédè tí kì í ṣe Giriki, sí àwọn ọlọ́gbọ́n àti sí àwọn aṣiwèrè. 15Nítorí ìdí èyí ni mo ṣe ń làkàkà láti wá sí Romu àti láti fi gbogbo agbára mi wàásù ìhìnrere Ọlọ́run sí i yín.

161.16: 1Kọ 1.18,24.Èmi kò tijú ìhìnrere Jesu, nítorí agbára Ọlọ́run ní ín ṣe láti gba gbogbo àwọn tí ó bá gbàgbọ́ là, ọ̀rọ̀ yìí ni a kọ́kọ́ wàásù sí àwọn Júù nìkan, ṣùgbọ́n nísinsin yìí fún àwọn Helleni pẹ̀lú. 171.17: Ro 3.21; Ga 3.11; Fp 3.9; Hb 10.38; Hk 2.4.Nítorí nínú ìhìnrere ni òdodo Ọlọ́run ti farahàn, òdodo Ọlọ́run nípa ìgbàgbọ́ láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé Mímọ́ pé, “Olódodo yóò yè nípa ìgbàgbọ́ rẹ̀.”

Ìbínú Ọlọ́run sí orílẹ̀ ayé

181.18: Ef 5.6; Kl 3.6.Ṣùgbọ́n Ọlọ́run fi ìbínú rẹ̀ hàn láti ọ̀run wá sí gbogbo àìwà-bí-Ọlọ́run àti gbogbo àìṣòdodo ènìyàn, àwọn tí ń fi ìwà búburú dènà ìmọ̀ òtítọ́ lọ́dọ̀ ènìyàn. 19Nítorí pé, nǹkan gbogbo tí a lè mọ nípa Ọlọ́run ni a ti fihàn fún wọn, nítorí Ọlọ́run ti fi í hàn fún wọn. 201.20: Sm 19.1-4.Nítorí pé láti ìgbà dídá ayé, gbogbo ohun àìlèfojúrí rẹ̀: bí agbára ayérayé àti ìwà-bí-Ọlọ́run rẹ̀ ni a rí gbangba tí a sì ń fi òye ohun tí a dá mọ̀ ọ́n kí ènìyàn má ba à wá àwáwí.

211.21: Ef 4.17-18.Lóòótọ́, wọn ní òye nípa Ọlọ́run dáradára, ṣùgbọ́n wọn kò yìn ín lógo bí Ọlọ́run, wọ́n kò sí dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀; wọ́n ń ro èrò asán, ọkàn aṣiwèrè wọn sì ṣókùnkùn. 22Níwọ́n bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n pe ara wọn ní ọlọ́gbọ́n ṣùgbọ́n wọ́n di òmùgọ̀ pátápátá, 231.23: Ap 17.29.wọ́n sì yí ògo Ọlọ́run tí kì í díbàjẹ́ sí àwọn àwòrán ère bí i ti ènìyàn tí í díbàjẹ́ àti ti ẹyẹ, àti ti ẹranko ẹlẹ́sẹ̀ mẹ́rin àti ti ẹranko afàyàfà.

24Nítorí náà Ọlọ́run fà wọ́n lé ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ọkàn wọn lọ́wọ́ láti máa ṣe ohun ìríra pẹ̀lú ara wọn èyí tí kò tọ́. 25Wọ́n yí òtítọ́ Ọlọ́run sí èké, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ láti máa sin ẹ̀dá dípò ẹlẹ́dàá—ẹni tí ìyìn tọ́ sí láéláé. Àmín.

26Nítorí èyí yìí ni Ọlọ́run ṣe fi wọ́n fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́: nítorí àwọn obìnrin wọn tilẹ̀ ń yí ìṣẹ̀dá ìbáṣepọ̀ tí ó tọ̀nà, sí èyí tí kò tọ̀nà. 27Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin pẹ̀lú, wọn a máa fi ìbálòpọ̀ obìnrin nípa ti ẹ̀dá sílẹ̀, wọn a máa fẹ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ara wọn, ọkùnrin ń bá ọkùnrin ṣe èyí tí kò yẹ, wọ́n sì ǹ jẹ èrè ìṣìnà wọn nínú ara wọn bí ó ti yẹ sí.

28Àti gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti kọ̀ láti gba Ọlọ́run nínú ìmọ̀ tí ó tọ́, Ọlọ́run fi wọ́n fún iyè ríra láti ṣe ohun tí kò tọ́ fún wọn láti ṣe: 29Wọ́n kún fún onírúurú àìṣòdodo gbogbo, àgbèrè, ìkà, ojúkòkòrò, àrankàn; wọ́n kún fún ìlara, ìpànìyàn, ìjà, ìtànjẹ, ìwà búburú; wọ́n jẹ́ a fi-ọ̀rọ̀-kẹ́lẹ́-banijẹ́. 30Asọ̀rọ̀ ẹni lẹ́yìn, akórìíra Ọlọ́run, aláfojúdi, agbéraga, ahalẹ̀, aláròṣe ohun búburú, aṣàìgbọràn sí òbí, 31aláìníyè nínú, ọ̀dàlẹ̀, aláìnígbàgbọ́, ọ̀dájú, aláìláàánú: 32Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n mọ ìlànà Ọlọ́run pé, ẹni tí ó bá ṣe irú nǹkan wọ̀nyí yẹ sí ikú, wọn kò ní inú dídùn sí àwọn nǹkan wọ̀nyí nìkan ṣùgbọ́n wọ́n ní inú dídùn sí àwọn tí ń ṣe wọ́n.

Persian Contemporary Bible

رومیان 1:1-32

سلام و درود از پولس

1من، پولس، كه غلام عيسی مسيح می‌باشم، اين نامه را برای شما می‌نويسم. خدا مرا برگزيده و فرستاده است تا مژدهٔ انجيل او را به همگان برسانم. 2انجيلی كه وعده‌اش را از زمانهای دور توسط انبيای خود در كتاب آسمانی داده بود.

3اين مژده دربارهٔ فرزند خدا، يعنی خداوند ما عيسی مسيح می‌باشد كه همچون انسان از نسل داوود نبی به دنيا آمد؛ 4اما با زنده شدنش پس از مرگ، ثابت كرد كه فرزند نيرومند خدا و دارای ذات مقدس الهی است.

5بوسيلهٔ عيسی مسيح است كه خدا فيض و لطف بی‌پايان خود را شامل حال ما گناهكاران نالايق كرده و ما را به سراسر جهان فرستاده تا به همهٔ اقوام اعلام كنيم كه او چه لطف عظيمی نموده است، تا ايشان نيز به عيسی مسيح ايمان آورند و از او اطاعت كنند.

6‏-7برادران عزيز كه در شهر روم هستيد و اين نامه را می‌خوانيد، شما نيز جزو كسانی هستيد كه مورد مهر و محبت خدا می‌باشند، زيرا شما هم بوسيلهٔ عيسی مسيح دعوت شده‌ايد تا قوم مقدس خدا و از آن او باشيد. پس، از پدرمان خدا و خداوندمان عيسی مسيح، طالب رحمت و آرامش برای شما می‌باشم.

دعای شكرگزاری برای مسيحيان روم

8پيش از هر چيز، بايد بگويم كه خبر ايمانتان به تمام دنيا رسيده و همه جا صحبت از شماست. از این رو، برای اين خبر و برای وجود هر يک از شما، خدا را بوسيلهٔ عيسی مسيح شكر می‌كنم. 9خدا شاهد است كه من پيوسته برای شما دعا می‌كنم، و روز و شب احتياجاتتان را به حضور او می‌برم، به حضور خدايی كه با تمام توانم او را خدمت می‌كنم و مژدهٔ انجيل او را كه دربارهٔ فرزندش عيسی مسيح است، به ديگران اعلام می‌نمايم.

10دعای ديگرم اينست كه اگر خدا بخواهد، پس از اين همه انتظار، سعادت ديدار شما نصيبم شود. 11زيرا بسيار مشتاق ديدارتان هستم تا بتوانم شما را از بركات خدا برخوردار سازم، و باعث تقويت ايمانتان شوم. 12از اين گذشته، من خود نيز نياز به كمک شما دارم تا بوسيلهٔ ايمانتان تقويت شوم. به اين ترتيب، هر يک از ما باعث تقويت ايمان يكديگر می‌گرديم.

13اما برادران عزيز، مايلم بدانيد كه بارها خواسته‌ام نزد شما بيايم، اما هر بار مانعی پيش آمده است. قصد من از آمدن، اين بود كه خدمتی در ميان شما انجام دهم و عده‌ای را به سوی مسيح هدايت كنم، همانطور كه در جاهای ديگر نيز كرده‌ام. 14زيرا من خود را مديون می‌دانم كه اين خبر خوش را به همه برسانم، چه به اشخاص متمدن و چه به اشخاص بی‌تمدن، چه به تحصيلكرده‌ها و چه به بی‌سوادان. 15پس تا آنجا كه در توان دارم، خواهم كوشيد كه به «روم»، نزد شما بيايم و مژدهٔ انجيل را در ميان شما اعلام نمايم. 16زيرا من به انجيل عيسی مسيح افتخار می‌كنم چون قدرت خداست برای نجات تمام كسانی كه ايمان بياورند. پيغام انجيل در ابتدا فقط به يهوديان اعلام می‌شد، اما اكنون همه می‌توانند با ايمان آوردن به آن، به حضور خدا راه يابند. 17اين پيغام اينست كه خدا فقط در يک صورت از سر تقصيرات ما می‌گذرد و به ما شايستگی آن را می‌دهد كه به حضور او برويم؛ و آن وقتی است كه به عيسی مسيح ايمان آوريم. بلی، فقط و فقط ايمان لازم است. همانطور كه كتاب آسمانی می‌فرمايد: «فقط كسی نجات پيدا می‌كند كه به خدا ايمان داشته باشد.»

خشم خدا نسبت به گناهان بشر

18اما از سوی ديگر، خدا خشم و غضب خود را بر تمام اشخاص گناهكار و نادرست كه از حقيقت گريزانند، نازل می‌كند. 19برای آنان حقيقت وجود خدا كاملاً روشن است، زيرا خدا وجدانهايشان را از اين حقيقت آگاه ساخته است. 20انسان از ابتدا، آسمان و زمين و چيزهايی را كه خدا آفريده، ديده است و با ديدن آنها می‌تواند به وجود خدا و قدرت ابدی او كه ناديدنی هستند پی ببرد. پس وقتی در روز داوری در حضور خدا می‌ايستد، برای بی‌ايمانی خود هيچ عذر و بهانه‌ای ندارد.

21بلی، درست است كه مردم اين حقايق را می‌دانند، اما هيچگاه حاضر نيستند به آن اعتراف كنند و خدا را عبادت نمايند و يا حتی برای بركاتی كه هر روز عطا می‌كند، او را شكر گويند. در عوض دربارهٔ وجود خدا و ارادهٔ او، عقايد احمقانه‌ای ابداع می‌كنند. به همين علت ذهن نادانشان، تاريک و مغشوش شده است. 22خود را دانا و خردمند می‌پنداشتند، اما همگی، نادان و بی‌خرد شدند. 23به جای اينكه خدای بزرگ و ابدی را بپرستند، بتهايی از چوب و سنگ به شكل انسان فانی، پرندگان، چارپایان و خزندگان ساختند و آنها را پرستيدند.

24بنابراين، خدا نيز ايشان را به حال خود رها كرده تا هر چه می‌خواهند بكنند و در آتش شهوات گناه‌آلود خود بسوزند و با بدنهای خود مرتكب گناهان شرم‌آور شوند. 25ايشان به جای اينكه به حقيقت وجود خدا ايمان بياورند، عمداً عقايد باطل را پذيرفته‌اند و مخلوق خدا را به جای خالقی كه تا ابد مورد ستايش است، می‌پرستند و خدمت می‌كنند.

26به همين دليل است كه خدا مردم را به حال خود رها كرده است تا خويشتن را به گناهان زشت آلوده سازند، به طوری كه حتی زنها به جای روابط جنسی طبيعی، با زنان ديگر مرتكب اعمال قبيح می‌گردند، 27و مردها نيز به جای اينكه با زنان خود روابط طبيعی زناشويی داشته باشند، با مردهای ديگر مرتكب گناهان شرم‌آور می‌شوند. بنابراين، سزای كارهای كثيف خود را در روح و بدن خود می‌بينند.

28پس همانطور كه ايشان خدا را ترک كرده‌اند و حتی حاضر نيستند به وجود او اعتراف كنند، خدا نيز ايشان را به حال خود رها كرده است تا هر آنچه به ذهن ناپاكشان خطور می‌كند، به عمل آورند. 29زندگی آنان پر است از هر نوع شرارت و بدی، طمع و نفرت و حسادت، قتل و جدال، دروغ و كينه و سخن‌چينی. 30غيبت از زبانشان دور نمی‌شود. ايشان دشمنان خدا هستند. با غرور و گستاخی، خودستايی می‌كنند. هميشه به دنبال راههای تازه می‌گردند تا بيشتر گناه ورزند. هرگز مطيع والدين خود نمی‌شوند. 31بی‌احساسند و بدقول و بی‌عاطفه و بی‌رحم. 32با اينكه می‌دانند خدا برای چنين اعمالی، مجازات مرگ تعيين كرده است، نه فقط خودشان مرتكب آنها می‌گردند، بلكه ديگران را نيز به انجام اين كارها تشويق می‌كنند!