Romu 1 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Romu 1:1-32

Ọ̀rọ̀ ìkíni Paulu sí àwọn àyànfẹ́

11.1: Ap 9.15; 13.2; 1Kọ 1.1; 2Kọ 1.1; Ga 1.15.Paulu, ìránṣẹ́ Jesu Kristi, ẹni tí a ti pè láti jẹ́ aposteli, tí a sì ti yà sọ́tọ̀ láti wàásù ìhìnrere Ọlọ́run, 2ìhìnrere tí ó ti ṣe ìlérí tẹ́lẹ̀ rí láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ nínú ìwé Mímọ́. 3Ní ti Ọmọ rẹ̀, ẹni tí a bí láti inú irú-ọmọ Dafidi nípa ti ara, 4ẹni tí a pinnu rẹ̀ láti jẹ́ Ọmọ Ọlọ́run nínú agbára gẹ́gẹ́ bí Ẹ̀mí ìwà mímọ́, nípa àjíǹde kúrò nínú òkú, àní Jesu Kristi Olúwa wa. 51.5: Ap 26.16-18; Ro 15.18; Ga 2.7,9.Láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwa rí oore-ọ̀fẹ́ àti jíjẹ́ aposteli gbà, fún ìgbọ́ràn ìgbàgbọ́ láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè, nítorí orúkọ rẹ̀. 6Ẹ̀yin pẹ̀lú si wa lára àwọn tí a pè sọ́dọ̀ Jesu Kristi.

71.7: 1Kọ 1.3; 2Kọ 1.2; Ga 1.3; Ef 1.2; Fp 1.2; Kl 1.2; 1Tẹ 1.2; 2Tẹ 1.2; 1Tm 1.2; 2Tm 1.2; Tt 1.4; Fm 3; 2Jh 3.Sí gbogbo àwọn àyànfẹ́ Ọlọ́run tí ó wà ní Romu tí a ti pè láti jẹ́ ènìyàn mímọ́:

Oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà fún yín láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa àti láti ọ̀dọ̀ Olúwa wa Jesu Kristi.

Ìfojúsọ́nà Paulu láti bẹ Romu wò

81.8: Ro 16.19.Ní àkọ́kọ́, mo dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run nípasẹ̀ Jesu Kristi fún gbogbo yín, nítorí a ń ròyìn ìgbàgbọ́ yin káàkiri gbogbo ayé. 9Ọlọ́run ṣá à ni ẹlẹ́rìí mi, ẹni tí èmí ń fi gbogbo ẹ̀mí mi sìn nínú ìhìnrere Ọmọ rẹ̀, bí ó ti ṣe pé ní àìsimi ni èmí ń rántí yín nígbà gbogbo nínú àdúrà mi 101.10: Ro 15.23,32; Ap 19.21.nínú àdúrà mi ìgbà gbogbo; mo tún ń gbàdúrà wí pé nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run kí ọ̀nà ó ṣí fún mi láti wá sọ́dọ̀ yín.

11Nítorí èmi ń fẹ́ gidigidi láti tọ̀ yín wá, kí èmi lè fún yín ní ẹ̀bùn ẹ̀mí díẹ̀, kí a bá a le sọ yín di alágbára nínú Olúwa, 12èyí nì ni pé, kí a lè jẹ́ ìwúrí fún ara wa nípa ìgbàgbọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan wa. 131.13: Ro 15.22.Mo fẹ́ kí ẹ mọ èyí, ẹ̀yin ará mi, pé mo ti gbìyànjú lọ́pọ̀ ìgbà láti tọ̀ yín wá, (ṣùgbọ́n ìdíwọ́ wà fún mi), kí èmi ki ó lè jèrè ọkàn díẹ̀ láàrín yín, gẹ́gẹ́ bí mo ti ní láàrín àwọn aláìkọlà yòókù.

141.14: 1Kọ 9.16.Nítorí mo jẹ́ ajigbèsè sí Giriki àti sí àwọn aláìgbédè tí kì í ṣe Giriki, sí àwọn ọlọ́gbọ́n àti sí àwọn aṣiwèrè. 15Nítorí ìdí èyí ni mo ṣe ń làkàkà láti wá sí Romu àti láti fi gbogbo agbára mi wàásù ìhìnrere Ọlọ́run sí i yín.

161.16: 1Kọ 1.18,24.Èmi kò tijú ìhìnrere Jesu, nítorí agbára Ọlọ́run ní ín ṣe láti gba gbogbo àwọn tí ó bá gbàgbọ́ là, ọ̀rọ̀ yìí ni a kọ́kọ́ wàásù sí àwọn Júù nìkan, ṣùgbọ́n nísinsin yìí fún àwọn Helleni pẹ̀lú. 171.17: Ro 3.21; Ga 3.11; Fp 3.9; Hb 10.38; Hk 2.4.Nítorí nínú ìhìnrere ni òdodo Ọlọ́run ti farahàn, òdodo Ọlọ́run nípa ìgbàgbọ́ láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé Mímọ́ pé, “Olódodo yóò yè nípa ìgbàgbọ́ rẹ̀.”

Ìbínú Ọlọ́run sí orílẹ̀ ayé

181.18: Ef 5.6; Kl 3.6.Ṣùgbọ́n Ọlọ́run fi ìbínú rẹ̀ hàn láti ọ̀run wá sí gbogbo àìwà-bí-Ọlọ́run àti gbogbo àìṣòdodo ènìyàn, àwọn tí ń fi ìwà búburú dènà ìmọ̀ òtítọ́ lọ́dọ̀ ènìyàn. 19Nítorí pé, nǹkan gbogbo tí a lè mọ nípa Ọlọ́run ni a ti fihàn fún wọn, nítorí Ọlọ́run ti fi í hàn fún wọn. 201.20: Sm 19.1-4.Nítorí pé láti ìgbà dídá ayé, gbogbo ohun àìlèfojúrí rẹ̀: bí agbára ayérayé àti ìwà-bí-Ọlọ́run rẹ̀ ni a rí gbangba tí a sì ń fi òye ohun tí a dá mọ̀ ọ́n kí ènìyàn má ba à wá àwáwí.

211.21: Ef 4.17-18.Lóòótọ́, wọn ní òye nípa Ọlọ́run dáradára, ṣùgbọ́n wọn kò yìn ín lógo bí Ọlọ́run, wọ́n kò sí dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀; wọ́n ń ro èrò asán, ọkàn aṣiwèrè wọn sì ṣókùnkùn. 22Níwọ́n bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n pe ara wọn ní ọlọ́gbọ́n ṣùgbọ́n wọ́n di òmùgọ̀ pátápátá, 231.23: Ap 17.29.wọ́n sì yí ògo Ọlọ́run tí kì í díbàjẹ́ sí àwọn àwòrán ère bí i ti ènìyàn tí í díbàjẹ́ àti ti ẹyẹ, àti ti ẹranko ẹlẹ́sẹ̀ mẹ́rin àti ti ẹranko afàyàfà.

24Nítorí náà Ọlọ́run fà wọ́n lé ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ọkàn wọn lọ́wọ́ láti máa ṣe ohun ìríra pẹ̀lú ara wọn èyí tí kò tọ́. 25Wọ́n yí òtítọ́ Ọlọ́run sí èké, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ láti máa sin ẹ̀dá dípò ẹlẹ́dàá—ẹni tí ìyìn tọ́ sí láéláé. Àmín.

26Nítorí èyí yìí ni Ọlọ́run ṣe fi wọ́n fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́: nítorí àwọn obìnrin wọn tilẹ̀ ń yí ìṣẹ̀dá ìbáṣepọ̀ tí ó tọ̀nà, sí èyí tí kò tọ̀nà. 27Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin pẹ̀lú, wọn a máa fi ìbálòpọ̀ obìnrin nípa ti ẹ̀dá sílẹ̀, wọn a máa fẹ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ara wọn, ọkùnrin ń bá ọkùnrin ṣe èyí tí kò yẹ, wọ́n sì ǹ jẹ èrè ìṣìnà wọn nínú ara wọn bí ó ti yẹ sí.

28Àti gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti kọ̀ láti gba Ọlọ́run nínú ìmọ̀ tí ó tọ́, Ọlọ́run fi wọ́n fún iyè ríra láti ṣe ohun tí kò tọ́ fún wọn láti ṣe: 29Wọ́n kún fún onírúurú àìṣòdodo gbogbo, àgbèrè, ìkà, ojúkòkòrò, àrankàn; wọ́n kún fún ìlara, ìpànìyàn, ìjà, ìtànjẹ, ìwà búburú; wọ́n jẹ́ a fi-ọ̀rọ̀-kẹ́lẹ́-banijẹ́. 30Asọ̀rọ̀ ẹni lẹ́yìn, akórìíra Ọlọ́run, aláfojúdi, agbéraga, ahalẹ̀, aláròṣe ohun búburú, aṣàìgbọràn sí òbí, 31aláìníyè nínú, ọ̀dàlẹ̀, aláìnígbàgbọ́, ọ̀dájú, aláìláàánú: 32Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n mọ ìlànà Ọlọ́run pé, ẹni tí ó bá ṣe irú nǹkan wọ̀nyí yẹ sí ikú, wọn kò ní inú dídùn sí àwọn nǹkan wọ̀nyí nìkan ṣùgbọ́n wọ́n ní inú dídùn sí àwọn tí ń ṣe wọ́n.

Nouă Traducere În Limba Română

Romani 1:1-32

Salutări

1Pavel, rob al lui Cristos Isus, chemat să fie apostol, pus deoparte pentru Evanghelia1 Termenul Evanghelie înseamnă: Vestea Bună [peste tot în carte]. lui Dumnezeu, 2pe care El o promisese mai dinainte prin profeții Săi în Sfintele Scripturi 3și care este despre Fiul Său – născut din sămânța lui David, în ce privește trupul, 4desemnat Fiul lui Dumnezeu în putere4 Sau: desemnat Fiul‑lui‑Dumnezeu‑în putere., în ce privește Duhul4 Sau: duhul, cu referire la caracterul lui Isus Cristos. sfințeniei, prin învierea dintre cei morți – adică despre Isus Cristos, Domnul nostru, 5prin Care noi am primit harul și apostolatul, ca să proclamăm ascultarea credinței, de dragul Numelui Său, între toate neamurile,5 Lit.: apostolatul, spre ascultarea credinței între toate neamurile, de dragul Numelui Său. 6printre care sunteți și voi, cei chemați să fiți ai lui Isus Cristos. 7Deci, tuturor celor care sunt preaiubiți ai lui Dumnezeu în Roma, chemați să fie sfinți: har și pace de la Dumnezeu, Tatăl nostru, și de la Domnul Isus Cristos!

Dorința lui Pavel de a vizita Roma

8Mai întâi, Îi mulțumesc Dumnezeului meu, prin Isus Cristos, pentru voi toți, întrucât credința voastră este vestită în întreaga lume. 9Căci martor îmi este Dumnezeu, Căruia Îi slujesc în duhul meu, în Evanghelia Fiului Său, că îmi aduc aminte neîncetat de voi, 10cerând întotdeauna în rugăciunile mele ca, prin voia lui Dumnezeu, să reușesc poate acum să vin în sfârșit la voi. 11Căci tânjesc să vă văd, ca să vă fac parte de vreun dar duhovnicesc spre întărirea voastră, 12cu alte cuvinte, să ne încurajăm împreună, în mijlocul vostru, unul prin credința celuilalt, atât a voastră cât și a mea. 13Nu vreau să nu știți, fraților, că de multe ori mi‑am propus să vin la voi, ca să am și printre voi vreun rod, tot așa cum am și printre celelalte neamuri, dar până acum am fost împiedicat. 14Eu sunt dator atât grecilor, cât și barbarilor14 Cu referire la popoarele străine, care nu vorbeau limba greacă, între greci și barbari existând o diferență nu numai de natură etnică, ci și culturală., atât celor înțelepți, cât și celor neștiutori, 15astfel că, în ce mă privește, sunt dornic să vă predic Evanghelia și vouă, celor din Roma.

Puterea Evangheliei

16Căci mie nu mi‑e rușine de Evanghelie, fiindcă ea este puterea lui Dumnezeu pentru mântuirea fiecăruia care crede, – întâi a iudeului, apoi a grecului –, 17deoarece în ea este descoperită dreptatea lui Dumnezeu, din credință spre credință17 Sau: prin credință pentru credință; sau: prin credință spre credință., așa cum este scris: „Însă cel drept prin credință va trăi.“17 Sau: Însă cel drept va trăi prin credință. Vezi Hab. 2:4.

Mânia lui Dumnezeu împotriva nedreptății

18Căci mânia lui Dumnezeu se descoperă din cer împotriva oricărei neevlavii și împotriva oricărei nedreptăți a oamenilor, care înăbușă adevărul în nedreptate. 19Fiindcă ce se poate cunoaște despre Dumnezeu este vădit în ei, căci Dumnezeu le‑a arătat. 20De la crearea lumii, însușirile Lui nevăzute – puterea Lui veșnică și dumnezeirea Lui – au fost clar arătate, fiind înțelese din ceea ce a fost creat, pentru ca ei să fie fără vreo apărare, 21fiindcă, deși L‑au cunoscut21 Aluzie la cunoașterea lui Dumnezeu prin intermediul creației Sale. pe Dumnezeu, ei nu L‑au slăvit ca Dumnezeu, nici nu I‑au mulțumit, ci au devenit nefolositori în gândurile lor21 Sau: ci s‑au prostit în gândurile lor. și inima lor fără pricepere s‑a întunecat. 22Pretinzând că sunt înțelepți, au înnebunit 23și au schimbat slava Dumnezeului nemuritor într‑o imagine făcută după chipul omului muritor, a păsărilor, a patrupedelor și a târâtoarelor23 Gr.: herpeton (echivalentul termenului ebraic remes) face referire la toate celelalte animale mai mărunte, distincte de vite și de animalele sălbatice mari, care se târăsc sau care mișună. De asemenea, termenul poate include și insectele (vezi Gen. 1:24 și nota)..

24De aceea, Dumnezeu i‑a dat pradă poftelor inimilor lor, spre necurăție, necinstindu‑și astfel trupurile între ei. 25Ei au schimbat adevărul lui Dumnezeu într‑o minciună și s‑au închinat și au slujit creației în locul Creatorului, Care este binecuvântat în veci. Amin!

26Din cauza aceasta, Dumnezeu i‑a dat pradă patimilor rușinoase, căci femeile lor au schimbat întrebuințarea lor firească într‑una care este împotriva firii. 27Tot astfel și bărbații au părăsit întrebuințarea firească a femeii și s‑au aprins în pofta lor unii pentru alții, bărbați cu bărbați înfăptuind lucruri scârboase și primind astfel în ei înșiși răsplata pe care o meritau pentru rătăcirea lor.

28Și fiindcă n‑au găsit potrivit să‑L păstreze pe Dumnezeu în cunoașterea lor, Dumnezeu i‑a dat pradă minții lor corupte, ca să facă lucruri ce nu se cuvin. 29Sunt plini de orice fel de nedreptate, de răutate, de lăcomie, de ticăloșie, plini de invidie, de ucidere, de ceartă, de viclenie, sunt dușmănoși, șoptitori, 30bârfitori, Îl urăsc pe Dumnezeu, sunt obraznici, aroganți, lăudăroși, născocitori de rele, neascultători de părinți, 31fără pricepere, nu‑și țin promisiunile, sunt fără afecțiune, nemiloși. 32Și, deși cunosc hotărârea dreaptă a lui Dumnezeu, potrivit căreia cei ce fac astfel de lucruri sunt vrednici de moarte, ei nu numai că le fac, ci îi și aprobă pe cei ce le fac.