Orin Solomoni 1 – YCB & NAV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Orin Solomoni 1:1-17

1Orin àwọn orin tí í ṣe orin Solomoni.

Olólùfẹ́

2Fi ìfẹnukonu ìfẹ́ kò mí ní ẹnu,

nítorí ìfẹ́ rẹ dára ju ọtí wáìnì lọ.

3Òórùn ìkunra rẹ fanimọ́ra.

Orúkọ rẹ rí bí ìkunra tí a tú jáde

abájọ tí àwọn wúńdíá fi fẹ́ ọ.

4Fà mí lọ pẹ̀lú rẹ, kí a lọ kíákíá

ọba ti mú mi wá sínú yàrá rẹ̀.

Ọ̀rẹ́

Àwa yọ̀ inú wa sì dùn sí ọ;

a gbé ìfẹ́ rẹ ga ju ọtí wáìnì lọ.

Olólùfẹ́

Wọ́n fẹ́ ọ nítòótọ́!

5Èmi dúdú mo sì ní ẹwà.

Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu

dúdú bí àgọ́ Kedari,

bí aṣọ títa ti Solomoni

6Má ṣe wò mí nítorí wí pé mo dúdú,

nítorí oòrùn mú mi dúdú,

ọmọkùnrin ìyá mi bínú sí mi

ó sì fi mí ṣe olùtọ́jú ọgbà àjàrà;

ọgbà àjàrà tèmi ni èmi kò tọ́jú.

7Wí fún mi, ìwọ ẹni tí ọkàn mí fẹ́,

níbo ni ìwọ ń da agbo ẹran lọ.

Níbi tí ìwọ mú agbo ẹran rẹ sinmi ní ọ̀sán,

kí ni ìdí tí èmi yóò fi jẹ́ obìnrin asán

ní ẹ̀bá agbo ẹran àwọn ọ̀rẹ́ rẹ.

Ọ̀rẹ́

8Bí ìwọ kò bá mọ̀,

ìwọ arẹwà jùlọ nínú àwọn obìnrin.

Bá ọ̀nà tí agbo ẹran rìn lọ,

kí o sì bọ́ àwọn ọmọ ewúrẹ́ rẹ.

Ní ẹ̀bá àgọ́ àwọn olùṣọ́-àgùntàn.

Olùfẹ́

9Olùfẹ́ mi,

mo fi ọ́ wé ẹṣin mi nínú kẹ̀kẹ́ Farao.

10Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ dára ní ohun ọ̀ṣọ́,

ọrùn rẹ sì yẹ ọ̀ṣọ́ ìlẹ̀kẹ̀

11A ó fi wúrà ṣe òrùka etí fún ọ,

a ó fi fàdákà ṣe ìlẹ̀kẹ̀.

Olólùfẹ́

12Nígbà tí ọba wà ní orí ìjókòó rẹ̀,

òróró ìkunra mi tú òórùn jáde.

13Ìdì òjìá ni olùfẹ́ mi jẹ sí mi,

òun ó sinmi lé àárín ọmú mi.

14Bí ìdì ìtànná Henina ni olùfẹ́ mi rí sí mi

láti inú ọgbà àjàrà ti En-Gedi.

Olólùfẹ́

15Báwo ni o ti lẹ́wà tó, olólùfẹ́ mi!

Háà, Báwo ni o ṣe lẹ́wà tó!

Ìwọ ní ojú ẹyẹlé.

Olólùfẹ́

16Báwo ni o ṣe dára tó, olùfẹ́ mi!

Háà, Báwo ni o ṣe wu ni!

Ibùsùn wa ní ìtura.

Olùfẹ́

17Ìtànṣán ilé wa jẹ́ ti igi kedari

ẹkẹ́ ilé wa jẹ́ ti igi firi.

Ketab El Hayat

نشيد الأنشاد 1:1-17

1هَذَا نَشِيدُ الأَنَاشِيدِ لِسُلَيْمَانَ.

2(الْمَحْبُوبَةُ): لِيَلْثِمْنِي بِقُبْلاتِ فَمِهِ، لأَنَّ حُبَّكَ أَلَذُّ مِنَ الْخَمْرِ. 3رَائِحَةُ عُطُورِكَ شَذِيَّةٌ، وَاسْمُكَ أَرِيجٌ مَسْكُوبٌ؛ لِذَلِكَ أَحَبَّتْكَ الْعَذَارَى. 4اجْذُبْنِي وَرَاءَكَ فَنَجْرِيَ، أَدْخَلَنِي الْمَلِكُ إِلَى مَخَادِعِهِ. نَبْتَهِجُ بِكَ وَنَفْرَحُ، وَنَمْدَحُ حُبَّكَ أَكْثَرَ مِنَ الْخَمْرِ، فَالَّذِينَ أَحَبُّوكَ مُحِقُّونَ.

5سَمْرَاءُ أَنَا، وَلَكِنَّنِي رَائِعَةُ الْجَمَالِ يَا بَنَاتِ أُورُشَلِيمَ. أَنَا سَمْرَاءُ كَخِيَامِ قِيدَارَ. أَوْ كَسُرَادِقِ سُلَيْمَانَ.

6لَا تَنْظُرْنَ إِلَيَّ لأَنَّنِي سَمْرَاءُ، فَإِنَّ الشَّمْسَ قَدْ لَوَّحَتْنِي. إِخْوَتِي قَدْ غَضِبُوا مِنِّي فَأَقَامُونِي حَارِسَةً لِلْكُرُومِ، أَمَّا كَرْمِي فَلَمْ أَنْطُرْهُ. 7قُلْ لِي يَا مَنْ تُحِبُّهُ نَفْسِي، أَيْنَ تَرْعَى قُطْعَانَكَ وَأَيْنَ تُرْبِضُ بِها عِنْدَ الظَّهِيرَةِ؟ فَلِمَاذَا أَكُونُ كَامْرَأَةٍ مُقَنَّعَةٍ، أَتَجَوَّلُ بِجُوَارِ قُطْعَانِ أَصْحَابِكَ؟

8(الْمُحِبُّ): إِنْ كُنْتِ لَا تَعْلَمِينَ يَا أَجْمَلَ النِّسَاءِ، فَاقْتَفِي أَثَرَ الْغَنَمِ، وَارْعَيْ جِدَاءَكِ عِنْدَ مَسَاكِنِ الرُّعَاةِ.

9إِنِّي أُشَبِّهُكِ يَا حَبِيبَتِي بِفَرَسٍ فِي مَرْكَبَاتِ فِرْعَوْنَ. 10مَا أَجْمَلَ خَدَّيْكِ بِالْحُلِيِّ، وَعُنُقَكِ بِالْقَلائِدِ الذَّهَبِيَّةِ. 11سَنَصْنَعُ لَكِ أَقْرَاطاً مِنْ ذَهَبٍ مَعَ جُمَانٍ مِنْ فِضَّةٍ.

12(الْمَحْبُوبَةُ): بَيْنَمَا الْمَلِكُ مُسْتَلْقٍ عَلَى أَرِيكَتِهِ فَاحَ نَارِدِينِي رَائِحَتِهِ. 13حَبِيبِي صُرَّةُ مُرٍّ لِي، هَاجِعٌ بَيْنَ نَهْدَيَّ. 14حَبِيبِي لِي عُنْقُودُ حِنَّاءَ فِي كُرُومِ عَيْنِ جَدْيٍ.

15(المُحِبُّ): كَمْ أَنْتِ جَمِيلَةٌ يَا حَبِيبَتِي، كَمْ أَنْتِ جَمِيلَةٌ! عَيْنَاكِ حَمَامَتَانِ!

16(الْمَحْبُوبَةُ): كَمْ أَنْتَ وَسِيمٌ يَا حَبِيبِي وَجَذَّابٌ حَقّاً! أَنْتَ حُلْوٌ وَأَرِيكَتُنَا مُخْضَرَّةٌ. 17عَوَارِضُ بَيْتِنَا خَشَبُ أَرْزٍ وَرَوَافِدُنَا خَشَبُ سَرْوٍ.