Onidajọ 1 – YCB & GKY

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Onidajọ 1:1-36

Orílẹ̀-èdè Israẹli bá àwọn ará Kenaani tókù jagun

1Lẹ́yìn ikú Joṣua, ni orílẹ̀-èdè Israẹli béèrè lọ́wọ́ Olúwa pé “Èwo nínú ẹ̀yà wa ni yóò kọ́kọ́ gòkè lọ bá àwọn ará Kenaani jagun fún wa?”

2Olúwa sì dáhùn pé, “Juda ni yóò lọ; nítorí pé èmi ti fi ilẹ̀ náà lé e lọ́wọ́.”

3Nígbà náà ni àwọn olórí ẹ̀yà Juda béèrè ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Simeoni arákùnrin wọn pé, “Ẹ wá bá wa gòkè lọ sí ilẹ̀ tí a ti fi fún wa, láti bá àwọn ará Kenaani jà kí a sì lé wọn kúrò, àwa pẹ̀lú yóò sì bá a yín lọ sí ilẹ̀ tiyín bákan náà láti ràn yín lọ́wọ́.” Àwọn ọmọ-ogun Simeoni sì bá àwọn ọmọ-ogun Juda lọ.

4Nígbà tí àwọn ọmọ-ogun Juda sì kọlu wọ́n, Olúwa sì fi àwọn ará Kenaani àti àwọn ará Peresi lé wọn lọ́wọ́, wọ́n sì pa ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọkùnrin ní Beseki. 5Ní Beseki ni wọ́n ti rí Adoni-Beseki, wọ́n sì bá a jagun, wọ́n sì ṣẹ́gun àwọn ará Kenaani àti Peresi. 6Ọba Adoni-Beseki sá àsálà, ṣùgbọ́n ogun Israẹli lépa rẹ̀ wọ́n sì bá a, wọ́n sì gé àwọn àtàǹpàkò ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀.

7Nígbà náà ni Adoni-Beseki wí pé, “Àádọ́rin ọba ni èmi ti gé àtàǹpàkò wọn tí wọ́n sì ń ṣa èérún oúnjẹ jẹ lábẹ́ tábìlì mi. Báyìí Ọlọ́run ti san án fún mi gẹ́gẹ́ bí ohun tí mo ṣe sí wọn.” Wọ́n sì mú un wá sí Jerusalẹmu, ó sì kú síbẹ̀.

8Àwọn ológun Juda sì ṣẹ́gun Jerusalẹmu, wọ́n sì kó o, wọ́n sì fi ojú idà kọlù ú, wọ́n sì dáná sun ìlú náà.

9Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni àwọn ogun Juda sọ̀kalẹ̀ lọ láti bá àwọn ará Kenaani tí ń gbé ní àwọn ìlú orí òkè ní gúúsù àti ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ òkè lápá ìwọ̀-oòrùn Juda jagun. 101.10: Jo 15.13-19.1.10-15: Jo 15.14-19.Ogun Juda sì tún ṣígun tọ ará Kenaani tí ń gbé Hebroni (tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Kiriati-Arba) ó sì ṣẹ́gun Ṣeṣai, Ahimani àti Talmai. 11Láti ibẹ̀, wọ́n sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).

12Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.” 13Otnieli ọmọ Kenasi, àbúrò Kalebu sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.

14Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà nàà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”

15Aksa sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.

16Àwọn ìran Keni tí wọ́n jẹ́ àna Mose bá àwọn ọmọ Juda gòkè láti ìlú ọ̀pẹ lọ sí aginjù Juda ní gúúsù Aradi; wọ́n sì lọ, orílẹ̀-èdè méjèèjì sì jùmọ̀ ń gbé pọ̀ láti ìgbà náà.

17Ó sì ṣe, àwọn ológun Juda tẹ̀lé àwọn ológun Simeoni arákùnrin wọn, wọ́n sì lọ bá àwọn ará Kenaani tí ń gbé Sefati jagun, wọ́n sì run ìlú náà pátápátá, ní báyìí àwa yóò pe ìlú náà ní Horma (Horma èyí tí ń jẹ́ ìparun). 18Àwọn ogun Juda sì ṣẹ́gun Gasa àti àwọn agbègbè rẹ̀, Aṣkeloni àti Ekroni pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó yí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ká.

19Olúwa sì wà pẹ̀lú ẹ̀yà Juda, wọ́n gba ilẹ̀ òkè, ṣùgbọ́n wọn kò le lé àwọn ènìyàn tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, nítorí wọ́n ní kẹ̀kẹ́ ogun onírin. 20Gẹ́gẹ́ bí Mose ti ṣèlérí, wọ́n fún Kalebu ní Hebroni, ó sì lé àwọn tí ń gbé ibẹ̀ kúrò; àwọn náà ni ìran àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta. 21Àwọn ẹ̀yà Benjamini ni wọn kò le lé àwọn Jebusi tí wọ́n ń gbé Jerusalẹmu, nítorí náà wọ́n ń gbé àárín àwọn Israẹli títí di òní.

22Àwọn ẹ̀yà Josẹfu sì bá Beteli jagun, Olúwa síwájú pẹ̀lú wọn. 23Nígbà tí ẹ̀yà Josẹfu rán àwọn ènìyàn láti lọ yọ́ Beteli wò (orúkọ ìlú náà tẹ́lẹ̀ rí ni Lusi). 24Àwọn ayọ́lẹ̀wò náà rí ọkùnrin kan tí ń jáde láti inú ìlú náà wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Fi ọ̀nà àtiwọ ìlú yìí hàn wá, àwa ó sì dá ẹ̀mí rẹ sí, a ó sì ṣe àánú fún ọ.” 25Ó sì fi ọ̀nà ìlú náà hàn wọ́n, wọ́n sì fi ojú idà kọlu ìlú náà, ṣùgbọ́n wọ́n dá ọkùnrin náà àti gbogbo ìdílé rẹ̀ si. 26Ọkùnrin náà sí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Hiti, ó sì tẹ ìlú kan dó, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Lusi, èyí sì ni orúkọ rẹ̀ títí di òní.

271.27,28: Jo 17.11-13.Ṣùgbọ́n Manase kò lé àwọn ará Beti-Ṣeani àti ìlú rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì jáde, tàbí àwọn ará Taanaki àti àwọn ìgbèríko rẹ̀, tàbí àwọn ará Dori àti àwọn ìgbèríko rẹ̀, tàbí àwọn ará Ibleamu àti àwọn ìgbèríko rẹ̀, tàbí àwọn ará Megido àti àwọn ìgbèríko tí ó yí i ká, torí pé àwọn ará Kenaani ti pinnu láti máa gbé ìlú náà. 28Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli di alágbára, wọ́n mú àwọn ará Kenaani sìn bí i ẹrú, ṣùgbọ́n wọn kò fi agbára lé wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ náà. 291.29: Jo 16.10.Efraimu náà kò lé àwọn ará Kenaani tí ó ń gbé Geseri jáde, ṣùgbọ́n àwọn ará Kenaani sì ń gbé láàrín àwọn ẹ̀yà Efraimu. 30Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Sebuluni kò lé àwọn ará Kenaani tí ń gbé Kitironi jáde tàbí àwọn ará Nahalali, ṣùgbọ́n wọ́n sọ wọ́n di ẹrú. Wọ́n sì ń sin àwọn ará Sebuluni. 31Bẹ́ẹ̀ ni Aṣeri kò lé àwọn tí ń gbé ní Akko tàbí ní Sidoni tàbí ní Ahlabu tàbí ní Aksibu tàbí ní Helba tàbí ní Afiki tàbí ní Rehobu. 32Ṣùgbọ́n nítorí àwọn ará Aṣeri ń gbé láàrín àwọn ará Kenaani tí wọ́n ni ilẹ̀ náà. 33Àwọn ẹ̀yà Naftali pẹ̀lú kò lé àwọn ará Beti-Ṣemeṣi àti Beti-Anati jáde; ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Naftali náà ń gbé àárín àwọn ará Kenaani tí ó ti ní ilẹ̀ náà rí, ṣùgbọ́n àwọn tí ń gbé Beti-Ṣemeṣi àti Beti-Anati ń sìn ìsìn tipátipá. 34Àwọn ará Amori fi agbára dá àwọn ẹ̀yà Dani dúró sí àwọn ìlú orí òkè, wọn kò sì jẹ́ kí wọn sọ̀kalẹ̀ wá sí pẹ̀tẹ́lẹ̀. 35Àwọn ará Amori ti pinnu láti dúró lórí òkè Heresi àti òkè Aijaloni àti ti Ṣaalbimu, ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yà Josẹfu di alágbára wọ́n borí Amori wọ́n sì mú wọn sìn. 36Ààlà àwọn ará Amori sì bẹ̀rẹ̀ láti ìgòkè Akrabbimu kọjá lọ sí Sela àti síwájú sí i.

Holy Bible in Gĩkũyũ

Atiirĩrĩri 1:1-36

Andũ a Isiraeli Kũhũũrana na Andũ a Kaanani arĩa Maatigaire

11:1 Josh 24:29; Atiir 20:18Thuutha wa Joshua gũkua, andũ a Isiraeli makĩũria Jehova atĩrĩ, “Nĩ a mekwambata mathiĩ mbere magatũhũũranĩre kũrĩ andũ a Kaanani?”

21:2 Kĩam 49:10Nake Jehova agĩcookia atĩrĩ, “Andũ a Juda nĩo megũthiĩ, tondũ nĩneanĩte bũrũri ũcio moko-inĩ mao.”

31:3 Atiir 1:17Hĩndĩ ĩyo andũ a Juda makĩĩra andũ a Simeoni, ariũ a ithe wao,1:3 Andũ a Simeoni na a Juda maarĩ a rũciaro rwa Lea. atĩrĩ, “Ũkai mwambatanie na ithuĩ tũtoonye bũrũri ũrĩa twagaĩirwo, tũkahũũrane na andũ a Kaanani, na ithuĩ nĩtũgaacooka tũthiĩ na inyuĩ tũkahũũranĩre igai rĩanyu.” Nĩ ũndũ ũcio andũ a Simeoni magĩthiĩ hamwe nao.

41:4 Kĩam 13:7; 1Sam 11:8Rĩrĩa andũ a Juda maamatharĩkĩire-rĩ, Jehova akĩneana andũ a Kaanani na Aperizi moko-inĩ mao, nao andũ a Juda makĩũraga arũme 10,000 kũu Bezeki. 51:5 Atiir 1:6, 7Kũu nĩkuo maakorire Adoni-Bezeki, makĩhũũrana nake, magĩtooria andũ a Kaanani na Aperizi. 6Adoni-Bezeki akĩũra, no makĩmũtengʼeria, makĩmũnyiita, makĩmũtinia ciara iria nene cia moko na iria nene cia magũrũ.1:6 Mũtugo wa gũtinia ciara iria nene cia moko na iria nene cia magũrũ ma mĩgwate ya mbaara warĩ wa kũmagiria gũthiĩ mbaara.

71:7 Alaw 24:19; Josh 10:1Nake Adoni-Bezeki akiuga atĩrĩ, “Athamaki mĩrongo mũgwanja1:7 Bũrũri wa Kaanani wagayanĩtio tũtũũra tũingĩ tũnini tũrĩa twathiũrũrũkĩirie itũũra inene; o gatũũra kaarĩ na mũthamaki wako. matinĩtio ciara ciao iria nene cia moko na iria nene cia magũrũ, moonganagia rũitĩki rwa irio rungu rwa metha yakwa. Na rĩrĩ, Ngai nĩandĩhĩte nĩ ũndũ wa ũrĩa ndeekire.” Nao makĩmũtwara Jerusalemu, na agĩkuĩra kuo.

81:8 Atiir 1:21; 2Sam 5:6Ningĩ andũ a Juda magĩtharĩkĩra itũũra rĩa Jerusalemu, o narĩo makĩrĩtunyana, makĩũraga andũ a itũũra rĩu na hiũ cia njora, magĩcooka makĩrĩcina na mwaki.

91:9 Ndar 13:17; Kĩam 12:9; Isa 30:6Thuutha wa ũguo, andũ a Juda magĩikũrũka makahũũrane na andũ a Kaanani arĩa maatũũraga bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma wa Negevu na magũrũ-inĩ ma irĩma cia mwena wa ithũĩro. 101:10 Kĩam 13:18; Josh 15:14Ningĩ magĩthiĩ kũhũũrana na andũ a Kaanani arĩa maatũũraga kũu Hebironi (kũrĩa tene gwetagwo Kiriathu-Ariba) maathiĩ makĩhoota Sheshai, na Ahimani, na Talimai.

111:11 Josh 10:38Kuuma kũu magĩthiĩ kũrũa na andũ arĩa maatũũraga Debiri (kũrĩa tene gwetagwo Kiriathu-Sefari.) 12Nake Kalebu akiuga atĩrĩ, “Mũndũ ũrĩa ũgũtharĩkĩra na atunyane Kiriathu-Sefari-rĩ, ũcio nĩwe ngũhe mwarĩ wakwa Akisa, amũhikie.” 13Nake Othinieli, mũrũ wa Kenazu, mũrũ wa ithe na Kalebu ũrĩa mũnini, nĩwe watunyanire itũũra rĩu. Nĩ ũndũ ũcio Kalebu akĩmũhe mwarĩ Akisa atuĩke mũtumia wake.

14Mũthenya ũmwe Akisa nĩathiire kũrĩ Othinieli, nake akĩringĩrĩria Akisa ahooe mũgũnda kũrĩ ithe Kalebu. Aarĩkia kuuma igũrũ rĩa ndigiri yake, Kalebu akĩũria mwarĩ atĩrĩ, “Ũkwenda ngwĩkĩre atĩa?”

151:15 Ndar 13:6Nake akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ndagũthaitha ũndathime. Tondũ nĩũũheete bũrũri wa Negevu, he ithima cia maaĩ o nacio.” Nĩ ũndũ ũcio Kalebu akĩmũhe ithima cia mwena wa rũgongo na cia mwena wa kĩanda.

161:16 Ndar 10:29; Gũcook 34:3Nacio njiaro cia mũthoni-we wa Musa, ũrĩa Mũkeni, ikĩambata ikiuma Itũũra Inene rĩa Mĩkĩndũ irĩ hamwe na andũ a Juda, igĩthiĩ gũtũũrania na andũ a werũ wa Juda ũrĩa ũrĩ Negevu gũkuhĩ na Aradi.

171:17 Ndar 14:45Nao andũ a Juda magĩthiĩ hamwe na andũ a Simeoni ariũ a ithe wao, na magĩtharĩkĩra andũ a Kaanani arĩa maatũũraga Zefathu, nao makĩananga itũũra rĩu inene biũ. Nĩ ũndũ ũcio rĩgĩtwo Horoma. 181:18 Josh 11:22O na ningĩ andũ a Juda magĩtunyana matũũra manene ma Gaza, na Ashikeloni, na Ekironi, o itũũra inene na bũrũri warĩo.

191:19 Ndar 13:17; Josh 17:16Jehova aarĩ hamwe na andũ a Juda. Magĩkĩĩnyiitĩra bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma, no matiahotire kũingata andũ arĩa maatũũraga kũrĩa kwaraganu, nĩgũkorwo maarĩ na ngaari cia ita cia igera. 201:20 Josh 10:36Na o ta ũrĩa Musa eeranĩire, Hebironi kwaheirwo Kalebu, nake akĩingata ariũ atatũ a Anaki kuuma kuo. 211:21 Josh 15:63No rĩrĩ, andũ a Benjamini nĩmaremirwo nĩ kũingata andũ a Jebusi arĩa maatũũraga Jerusalemu. Andũ a Jebusi matũũranagia na andũ a Benjamini kũu Jerusalemu nginya ũmũthĩ.

22Na rĩrĩ, andũ a nyũmba ya Jusufu magĩtharĩkĩra Betheli, nake Jehova aarĩ hamwe nao. 231:23 Kĩam 28:19Rĩrĩa maatũmire andũ magathigaane Betheli (kũrĩa mbere ĩyo gwetagwo Luzu), 24athigaani acio makĩona mũndũ akiuma kũu itũũra-inĩ rĩu inene, makĩmwĩra atĩrĩ, “Tuonie ũrĩa tũngĩtoonya itũũra rĩĩrĩ inene, na nĩtũgaagwĩka maũndũ mega.” 251:25 Josh 6:25Nĩ ũndũ ũcio akĩmoonia, nao makĩũraga andũ a itũũra rĩu inene na rũhiũ rwa njora, no makĩhonokia mũndũ ũcio na nyũmba yake yothe. 261:26 Gũcook 7:1Mũndũ ũcio agĩcooka agĩthiĩ bũrũri wa Ahiti, kũrĩa aakire itũũra inene, na akĩrĩĩta Luzu, na nĩrĩo rĩĩtwa rĩarĩo o na ũmũthĩ.

271:27 1Ath 9:21; Josh 17:11No andũ a Manase matiaingatire andũ a Bethi-Shani, kana andũ a Taanaka, kana andũ a Dori kana andũ a Ibileamu, kana andũ a Megido na matũũra marĩa maamarigiicĩirie, tondũ andũ a Kaanani nĩmatuĩte itua rĩa gũtũũra bũrũri ũcio. 281:28 Josh 14:4; Atiir 5:14Na rĩrĩ, rĩrĩa andũ a Isiraeli maagĩire na hinya, makĩrutithia andũ a Kaanani wĩra wa hinya, no matiigana kũmaingata biũ. 291:29 Atiir 5:14; Josh 16:10O nao andũ a Efiraimu matiigana kũingata andũ a Kaanani arĩa maatũũraga kũu Gezeri, no andũ acio a Kaanani maathiire o na mbere gũtũũrania hamwe nao. 30O nao andũ a Zebuluni matiigana kũingata andũ a Kaanani arĩa maatũũraga kũu Kitironi kana Nahaloli, arĩa maatigaire gatagatĩ kao; no nĩmamarutithirie wĩra na hinya. 31O na andũ a Asheri matiigana kũingata andũ othe arĩa maatũũraga Ako, kana arĩa matũũraga Sidoni, kana arĩa maatũũraga Ahalabu, kana arĩa maatũũraga Akizibu, kana arĩa maatũũraga Heliba, kana arĩa maatũũraga Afeku, kana arĩa maatũũraga Rehobu, 32na tondũ wa ũguo andũ a Asheri magĩtũũrania na andũ a Kaanani arĩa maatũũraga bũrũri ũcio. 33O nao andũ a Nafitali matiigana kũingata andũ arĩa maatũũraga kũu Bethi-Shemeshu, o na kana arĩa maatũũraga Bethi-Anathu; no andũ a Nafitali o nao maatũũranirie na andũ a Kaanani arĩa maatũũraga bũrũri ũcio, nao andũ arĩa maatũũraga Bethi-Shemeshu na Bethi-Anathu magĩtuĩka andũ ao a kũrutithagio wĩra wa hinya. 34Andũ a Aamori makĩhingĩrĩria andũ a Dani kũu bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma, makĩmagirĩrĩria gũikũrũka kũrĩa kwaraganu. 35Ningĩ Aamori nĩmatuĩte itua rĩa gũtũũra Kĩrĩma-inĩ kĩa Herezu, na kĩa Aijaloni, na kĩa Shaalubimu, no rĩrĩa andũ a nyũmba ya Jusufu maagĩire na hinya, o nao Aamori magĩtuĩka a kũrutithio wĩra wa hinya. 361:36 Josh 15:3; Isa 16:1; Thab 106:34Mũhaka wa Aamori woimĩte Ituĩkanĩrio rĩa Akirabimu, ũgakinya Sela na ũkahĩtũka.